Add parallel Print Page Options

Ìwẹ̀nùmọ́ kúrò nínú ẹsẹ̀

13 “Ní ọjọ́ náà ìsun kan yóò ṣí sílẹ̀ fún ilé Dafidi àti fún àwọn ará Jerusalẹmu, láti wẹ̀ wọ́n mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àti àìmọ́ wọn.

“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ni èmi ó gé orúkọ àwọn òrìṣà kúrò ni ilẹ̀ náà, a kì yóò sì rántí wọn mọ́: àti pẹ̀lú èmi ó mú àwọn wòlíì èké àti àwọn ẹ̀mí àìmọ́ kúrò ni ilẹ̀ náà. Yóò sì ṣe, nígbà tí ẹnìkan yóò sọtẹ́lẹ̀ síbẹ̀, ni baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí ó bí í yóò wí fún un pé, ‘Ìwọ ki yóò yè: nítorí ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ èké ni orúkọ Olúwa.’ Àti baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí o bí í yóò gun un ni àgúnpa nígbà tí ó bá sọtẹ́lẹ̀.

“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ojú yóò tí àwọn wòlíì èké olúkúlùkù nítorí ìran rẹ̀, nígbà tí òun ba tí sọtẹ́lẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò sì wọ aṣọ wòlíì onírun rẹ̀ tí o fi ń tan ní jẹ. Ṣùgbọ́n òun o wí pé, ‘Èmi kí í ṣe wòlíì, àgbẹ̀ ni èmi; nítorí tí a ti fi mí ṣe ìránṣẹ́ láti ìgbà èwe mi wá.’ Ẹnìkan ó sì wí fún un pé, ‘Ọgbẹ́ kín ní wọ̀nyí ni ẹ̀yìn rẹ?’ Òun o sì dáhùn pé, ‘Wọ̀nyí ni ibi tí a ti sá mi ní ilé àwọn ọ̀rẹ́ mi.’

A lu olùṣọ́-àgùntàn, agbo ẹran fọ́nká

(A)“Dìde, ìwọ idà, sí olùṣọ́-àgùntàn mi,
    àti sí ẹni tí í ṣe ẹnìkejì mi,”
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:
“Kọlu Olùṣọ́-àgùntàn,
    àwọn àgùntàn a sì túká:
    èmi o sì yí ọwọ́ mi sí àwọn kéékèèkéé.
Yóò sì ṣe, ni gbogbo ilẹ̀,” ni Olúwa wí,
    “a ó gé apá méjì nínú rẹ̀ kúrò yóò sì kú;
    ṣùgbọ́n apá kẹta yóò kù nínú rẹ̀.
Èmi ó sì mú apá kẹta náà la àárín iná,
    èmi yóò sì yọ́ wọn bí a ti yọ́ fàdákà,
    èmi yóò sì dán wọn wò, bi a tí ń dán wúrà wò:
wọn yóò sì pé orúkọ mi,
    èmi yóò sì dá wọn lóhùn:
èmi yóò wí pé, ‘Àwọn ènìyàn mi ni,’
    àwọn yóò sì wí pé, ‘Olúwa ni Ọlọ́run wa.’ ”

Cleansing From Sin

13 “On that day a fountain(A) will be opened to the house of David and the inhabitants of Jerusalem, to cleanse(B) them from sin and impurity.

“On that day, I will banish the names of the idols(C) from the land, and they will be remembered no more,”(D) declares the Lord Almighty. “I will remove both the prophets(E) and the spirit of impurity from the land. And if anyone still prophesies, their father and mother, to whom they were born, will say to them, ‘You must die, because you have told lies(F) in the Lord’s name.’ Then their own parents will stab the one who prophesies.(G)

“On that day every prophet will be ashamed(H) of their prophetic vision. They will not put on a prophet’s garment(I) of hair(J) in order to deceive.(K) Each will say, ‘I am not a prophet. I am a farmer; the land has been my livelihood since my youth.[a](L) If someone asks, ‘What are these wounds on your body[b]?’ they will answer, ‘The wounds I was given at the house of my friends.’

The Shepherd Struck, the Sheep Scattered

“Awake, sword,(M) against my shepherd,(N)
    against the man who is close to me!”
    declares the Lord Almighty.
“Strike the shepherd,
    and the sheep will be scattered,(O)
    and I will turn my hand against the little ones.
In the whole land,” declares the Lord,
    “two-thirds will be struck down and perish;
    yet one-third will be left in it.(P)
This third I will put into the fire;(Q)
    I will refine them like silver(R)
    and test them like gold.(S)
They will call(T) on my name(U)
    and I will answer(V) them;
I will say, ‘They are my people,’(W)
    and they will say, ‘The Lord is our God.(X)’”

Footnotes

  1. Zechariah 13:5 Or farmer; a man sold me in my youth
  2. Zechariah 13:6 Or wounds between your hands