Add parallel Print Page Options

Àwọn àlùfáà bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìránṣẹ́

Ní ọjọ́ kẹjọ, Mose pe Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Israẹli. Ó sọ fún Aaroni pé, “Mú akọ ọmọ màlúù kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti àgbò kan fún ẹbọ sísun, kí méjèèjì jẹ́ aláìlábùkù, kí o sì mú wọn wá sí iwájú Olúwa. Kí o sì sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹ mú òbúkọ kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, ọmọ màlúù àti ọ̀dọ́-àgùntàn kan, kí méjèèjì jẹ́ ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan tí kò ní àbùkù fún ẹbọ sísun, àti akọ màlúù kan àti àgbò kan fún ẹbọ àlàáfíà àti ẹbọ ohun jíjẹ tí a fi òróró pò láti fi rú ẹbọ ní iwájú Olúwa. Nítorí pé Olúwa yóò farahàn yín ní òní.’ ”

Wọ́n kó gbogbo àwọn nǹkan tí Mose pàṣẹ wá sí iwájú àgọ́ ìpàdé, gbogbo ìjọ ènìyàn sì súnmọ́ tòsí, wọ́n sì dúró níwájú Olúwa. Nígbà náà ni Mose wí pé, “Ohun tí Olúwa pàṣẹ fún yín láti ṣe nìyìí, kí ògo Olúwa bá à lè farahàn yín.”

Mose sọ fún Aaroni pé, “Wá sí ibi pẹpẹ kí o sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti ẹbọ sísun rẹ, kí o sì ṣe ètùtù fún ara rẹ àti fún àwọn ènìyàn; rú ẹbọ ti àwọn ènìyàn náà, kí o sì ṣe ètùtù fún wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ.”

Aaroni sì wá sí ibi pẹpẹ, ó pa akọ ọmọ màlúù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀. Àwọn ọmọ Aaroni sì mú ẹ̀jẹ̀ náà tọ̀ ọ́ wá, ó sì ti ìka ọwọ́ rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà, ó fi sí orí ìwo pẹpẹ, ó sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ. 10 Ó sun ọ̀rá, kíndìnrín àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, èyí tó mú láti inú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, lórí pẹpẹ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose. 11 Ó sì sun ara ẹran àti awọ rẹ̀ ní ẹ̀yìn ibùdó.

12 Lẹ́yìn èyí ó pa ẹran tó wà fún ẹbọ sísun. Àwọn ọmọ Aaroni sì mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, ó sì wọn yí pẹpẹ náà ká. 13 Wọ́n sì ń mú ẹbọ sísun náà fún un ní ègé kọ̀ọ̀kan, pẹ̀lú orí rẹ̀, ó sun gbogbo rẹ̀ lórí pẹpẹ. 14 Ó fọ nǹkan inú rẹ̀ àti ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sun wọ́n lórí ẹbọ sísun tó wà lórí pẹpẹ.

15 Aaroni mú ẹbọ tó jẹ́ ti àwọn ènìyàn wá. Ó mú òbúkọ èyí tó dúró fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn ó sì pa á, ó fi rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ti àkọ́kọ́.

16 Ó mú ẹbọ sísun wá, ó sì rú u gẹ́gẹ́ bí ìlànà tí a fi lélẹ̀. 17 Ó tún mu ẹbọ ohun jíjẹ wá, ó bu ẹ̀kúnwọ́ kan nínú rẹ̀, ó sì sun ún lórí pẹpẹ ní àfikún ẹbọ sísun tí àárọ̀.

18 (A)Ó pa akọ màlúù àti àgbò bí ẹbọ àlàáfíà fún àwọn ènìyàn. Àwọn ọmọ Aaroni sì mú ẹ̀jẹ̀ ẹran náà tọ̀ ọ́ wá, ó sì wọn yí pẹpẹ náà ká. 19 Ṣùgbọ́n ọ̀rá akọ màlúù àti àgbò náà: ìrù rẹ̀ tí ó lọ́ràá, básí ọ̀rá, ọ̀rá kíndìnrín, àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀: 20 gbogbo rẹ̀ ni wọ́n kó lórí igẹ̀ ẹran náà. Aaroni sì sun ọ̀rá náà lórí pẹpẹ. 21 Aaroni fi igẹ̀ àti itan ọ̀tún ẹran náà níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì bí Mose ṣe pa á láṣẹ.

22 (B)Aaroni sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí àwọn ènìyàn, ó sì súre fún wọn. Lẹ́yìn tó sì ti rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà, ó sọ̀kalẹ̀.

23 Mose àti Aaroni sì wọ inú àgọ́ ìpàdé. Nígbà tí wọ́n jáde, wọ́n súre fún àwọn ènìyàn, ògo Olúwa sì farahàn sí gbogbo ènìyàn, 24 Iná sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì jó ẹbọ sísun àti ọ̀rá orí pẹpẹ. Nígbà tí gbogbo ènìyàn sì rí èyí wọ́n hó ìhó ayọ̀, wọ́n sì dojúbolẹ̀.

The Priests Begin Their Ministry

On the eighth day(A) Moses summoned Aaron and his sons and the elders(B) of Israel. He said to Aaron, “Take a bull calf for your sin offering[a] and a ram for your burnt offering, both without defect, and present them before the Lord. Then say to the Israelites: ‘Take a male goat(C) for a sin offering,(D) a calf(E) and a lamb(F)—both a year old and without defect—for a burnt offering, and an ox[b](G) and a ram for a fellowship offering(H) to sacrifice before the Lord, together with a grain offering mixed with olive oil. For today the Lord will appear to you.(I)’”

They took the things Moses commanded to the front of the tent of meeting, and the entire assembly came near and stood before the Lord. Then Moses said, “This is what the Lord has commanded you to do, so that the glory of the Lord(J) may appear to you.”

Moses said to Aaron, “Come to the altar and sacrifice your sin offering and your burnt offering and make atonement for yourself and the people;(K) sacrifice the offering that is for the people and make atonement for them, as the Lord has commanded.(L)

So Aaron came to the altar and slaughtered the calf as a sin offering(M) for himself. His sons brought the blood to him,(N) and he dipped his finger into the blood and put it on the horns of the altar; the rest of the blood he poured out at the base of the altar.(O) 10 On the altar he burned the fat, the kidneys and the long lobe of the liver from the sin offering, as the Lord commanded Moses; 11 the flesh and the hide(P) he burned up outside the camp.(Q)

12 Then he slaughtered the burnt offering.(R) His sons handed him the blood,(S) and he splashed it against the sides of the altar. 13 They handed him the burnt offering piece by piece, including the head, and he burned them on the altar.(T) 14 He washed the internal organs and the legs and burned them on top of the burnt offering on the altar.(U)

15 Aaron then brought the offering that was for the people.(V) He took the goat for the people’s sin offering and slaughtered it and offered it for a sin offering as he did with the first one.

16 He brought the burnt offering and offered it in the prescribed way.(W) 17 He also brought the grain offering, took a handful of it and burned it on the altar in addition to the morning’s burnt offering.(X)

18 He slaughtered the ox and the ram as the fellowship offering for the people.(Y) His sons handed him the blood, and he splashed it against the sides of the altar. 19 But the fat portions of the ox and the ram—the fat tail, the layer of fat, the kidneys and the long lobe of the liver— 20 these they laid on the breasts, and then Aaron burned the fat on the altar. 21 Aaron waved the breasts and the right thigh before the Lord as a wave offering,(Z) as Moses commanded.

22 Then Aaron lifted his hands toward the people and blessed them.(AA) And having sacrificed the sin offering, the burnt offering and the fellowship offering, he stepped down.

23 Moses and Aaron then went into the tent of meeting.(AB) When they came out, they blessed the people; and the glory of the Lord(AC) appeared to all the people. 24 Fire(AD) came out from the presence of the Lord and consumed the burnt offering and the fat portions on the altar. And when all the people saw it, they shouted for joy and fell facedown.(AE)

Footnotes

  1. Leviticus 9:2 Or purification offering; here and throughout this chapter
  2. Leviticus 9:4 The Hebrew word can refer to either male or female; also in verses 18 and 19.