Add parallel Print Page Options

Paulu, aposteli Jesu Kristi nípa ìfẹ́ Ọlọ́run àti Timotiu arákùnrin wa.

(A)Sí àwọn ẹni mímọ́ àti àwọn arákùnrin àti arábìnrin nínú Kristi tí wọ́n ń gbé ní ìlú Kolose.

Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún un yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa.

Àwọn ọpẹ́ àti àdúrà

(B)Nígbàkúgbà tí a bá ń gbàdúrà fún un yín ni a máa ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run Baba Olúwa wa Jesu Kristi. Nítorí a ti gbúròó ìgbàgbọ́ yín nínú Jesu Kristi, àti bí ẹ ti ṣe fẹ́ràn gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́. Ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ tí ń sàn nínú ìrètí tí a gbé pamọ́ fún un yín ní ọ̀run èyí tí ẹ̀yin sì ti gbọ́ tẹ́lẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ òtítọ́ ìhìnrere náà, èyí tí ó ti dé ọ̀dọ̀ yín. Káàkiri àgbáyé ni ìhìnrere yìí ń so èso tí ó sì ń dàgbà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń ṣe láàrín yín láti ọjọ́ náà tí ẹ ti gbọ́ ọ, tí ẹ sì ní ìmọ̀ oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run nínú gbogbo òtítọ́ rẹ̀. (C)Ẹ̀yin ti kọ́ ọ lọ́dọ̀ Epafira, ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ wa olùfẹ́, ẹni tí ó jẹ́ olóòtítọ́ ìránṣẹ́ Kristi ní ipò wa. Ẹni ti ó sọ fún wa nípa ìfẹ́ yín nínú ẹ̀mí.

(D)Nítorí ìdí èyí, láti ọjọ́ tí a ti gbọ́ nípa yín, a kò sinmi láti máa gbàdúrà fún yin, tí a sì ń gbàdúrà pé kí Ọlọ́run fi ìmọ̀ ìfẹ́ rẹ̀ kún yín nípasẹ̀ ọgbọ́n àti òye gbogbo tí ń ṣe ti Ẹ̀mí. 10 Àwa sì ń gbàdúrà yìí kí ẹ lè gbé irú ìgbé ayé tó yẹ fún Olúwa kí ẹ sì máa wu ú ní gbogbo ọ̀nà, kí ẹ sì máa so èso rere gbogbo, kí ẹ sì máa dàgbà nínú ìmọ̀ Ọlọ́run, 11 pé kí a lè fi ipa gbogbo sọ yín di alágbára gẹ́gẹ́ bí agbára rẹ̀ àti ògo rẹ̀, kí ó lè ṣe é ṣe fún un yín láti máa tẹ̀síwájú nínú sùúrù àti ìpamọ́ra pẹ̀lú ayọ̀. 12 Kí a máa dúpẹ́ nígbà gbogbo lọ́wọ́ Baba, ẹni tí ó kà yín láti jẹ́ alábápín nínú ogún àwọn ẹni mímọ́ nínú ìjọba ìmọ́lẹ̀. 13 (E)Nítorí tí ó ti já wa gbà kúrò nínú agbára òkùnkùn ó sì mú wa wá sí ìjọba Ọmọ tí ó fẹ́ràn. 14 Nínú ẹni tí a ní ìràpadà, àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀.

Títóbi Kristi

15 (F)Kristi ni àwòrán Ọlọ́run tí a kò le rí, àkọ́bí gbogbo ẹ̀dá. 16 Nítorí nípa rẹ̀ ní a dá ohun gbogbo: àwọn ohun tí ń bẹ ní ọ̀run àti ní ayé, ohun tí a rí àti èyí tí a kò rí, wọn ìbá ṣe ìtẹ́, tàbí agbára, tàbí àṣẹ, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo àti fún un. 17 (G)Ó ti wà ṣáájú kí ohunkóhun tó wà, nínú rẹ̀ ni a sì so ohun gbogbo papọ̀ ṣọ̀kan. 18 (H)Òun ni orí fún ara, èyí tí í ṣe ìjọ; òun ni ìbẹ̀rẹ̀ àti àkọ́bí nínú àwọn òkú, pé nínú ohun gbogbo kí òun lè ní ipò tí ó ga jùlọ nínú ohunkóhun. 19 Nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run ni pé kí gbogbo ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ òun tìkára rẹ̀ lè máa gbé nínú rẹ̀. 20 Àti nípasẹ̀ rẹ̀ láti bá ohun gbogbo làjà àwọn nǹkan tí ń bẹ láyé àti èyí tí ń bẹ ní ọ̀run, nípa mímú àlàáfíà wá nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, tí a ta sílẹ̀ lórí igi àgbélébùú.

21 Ẹ̀yin ya ara yín nípá kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run nígbà kan rí, ẹ jẹ́ ọ̀tá nínú ọkàn yín nítorí ìwà búburú yín. 22 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti bá yín làjà nípa ara Kristi nípa ikú láti mú un yín lọ sí iwájú rẹ̀ ní mímọ́, aláìlábàwọ́n àti kúrò nínú ìdálẹ́bi, 23 bí ẹ̀yin bá dúró nínú ìgbàgbọ́ yín, tí ẹ fi ẹsẹ̀ múlẹ̀, tí ẹ sì dúró ṣinṣin, láláìyẹsẹ̀ kúrò nínú ìrètí ti ìhìnrere ti ẹ̀yin ti gbọ́, èyí tí a ti wàásù rẹ̀ fún gbogbo ẹ̀dá lábẹ́ ọ̀run, àti èyí ti èmi Paulu ṣe ìránṣẹ́ fún.

Iṣẹ́ Paulu ṣíṣe fún àwọn ìjọ

24 Nísinsin yìí èmi ń yọ̀ nínú ìjìyà fún un yín. Inú mi sì dùn, nítorí mo ń ṣe ìrànlọ́wọ́ láti jẹ ìyà tó ṣẹ́kù nínú ìyà Kristi fún ara rẹ̀, èyí tí ì ṣe ìjọ. 25 (I)Nínú èyí tí a fi ṣe ìránṣẹ́ fún gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ìríjú Ọlọ́run tí a fi fún mi fún yín láti mú ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣẹ. 26 (J)Ó ti pa àṣírí ìjìnlẹ̀ yìí mọ́ fún ayérayé àti láti ìrandíran. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ̀, ó ti fihàn fún àwọn ẹni mímọ́. 27 Àwọn ẹni tí Ọlọ́run yàn láti fihàn láàrín àwọn aláìkọlà nípa ọ̀rọ̀ ògo ohun ìjìnlẹ̀ yìí, èyí tí í ṣe Kristi ìrètí ògo nínú yín.

28 Àwa ń wàásù rẹ̀, a ń gbani níyànjú a sì ń kọ olúkúlùkù ènìyàn ní ọgbọ́n gbogbo, kí a lè mú olúkúlùkù dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní pípé nínú Kristi. 29 Sí èyí sì ni èmi ń ṣe làálàá, ti mo sì ń làkàkà pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀, èyí tó ń ṣiṣẹ́ nínú mi.

Paul, an apostle(A) of Christ Jesus by the will of God,(B) and Timothy(C) our brother,

To God’s holy people in Colossae, the faithful brothers and sisters[a] in Christ:

Grace(D) and peace to you from God our Father.[b](E)

Thanksgiving and Prayer

We always thank God,(F) the Father of our Lord Jesus Christ, when we pray for you, because we have heard of your faith in Christ Jesus and of the love(G) you have for all God’s people(H) the faith and love that spring from the hope(I) stored up for you in heaven(J) and about which you have already heard in the true message(K) of the gospel that has come to you. In the same way, the gospel is bearing fruit(L) and growing throughout the whole world(M)—just as it has been doing among you since the day you heard it and truly understood God’s grace. You learned it from Epaphras,(N) our dear fellow servant,[c] who is a faithful minister(O) of Christ on our[d] behalf, and who also told us of your love in the Spirit.(P)

For this reason, since the day we heard about you,(Q) we have not stopped praying for you.(R) We continually ask God to fill you with the knowledge of his will(S) through all the wisdom and understanding that the Spirit gives,[e](T) 10 so that you may live a life worthy(U) of the Lord and please him(V) in every way: bearing fruit in every good work, growing in the knowledge of God,(W) 11 being strengthened with all power(X) according to his glorious might so that you may have great endurance and patience,(Y) 12 and giving joyful thanks to the Father,(Z) who has qualified you[f] to share in the inheritance(AA) of his holy people in the kingdom of light.(AB) 13 For he has rescued us from the dominion of darkness(AC) and brought us into the kingdom(AD) of the Son he loves,(AE) 14 in whom we have redemption,(AF) the forgiveness of sins.(AG)

The Supremacy of the Son of God

15 The Son is the image(AH) of the invisible God,(AI) the firstborn(AJ) over all creation. 16 For in him all things were created:(AK) things in heaven and on earth, visible and invisible, whether thrones or powers or rulers or authorities;(AL) all things have been created through him and for him.(AM) 17 He is before all things,(AN) and in him all things hold together. 18 And he is the head(AO) of the body, the church;(AP) he is the beginning and the firstborn(AQ) from among the dead,(AR) so that in everything he might have the supremacy. 19 For God was pleased(AS) to have all his fullness(AT) dwell in him, 20 and through him to reconcile(AU) to himself all things, whether things on earth or things in heaven,(AV) by making peace(AW) through his blood,(AX) shed on the cross.

21 Once you were alienated from God and were enemies(AY) in your minds(AZ) because of[g] your evil behavior. 22 But now he has reconciled(BA) you by Christ’s physical body(BB) through death to present you(BC) holy in his sight, without blemish and free from accusation(BD) 23 if you continue(BE) in your faith, established(BF) and firm, and do not move from the hope(BG) held out in the gospel. This is the gospel that you heard and that has been proclaimed to every creature under heaven,(BH) and of which I, Paul, have become a servant.(BI)

Paul’s Labor for the Church

24 Now I rejoice(BJ) in what I am suffering for you, and I fill up in my flesh what is still lacking in regard to Christ’s afflictions,(BK) for the sake of his body, which is the church.(BL) 25 I have become its servant(BM) by the commission God gave me(BN) to present to you the word of God(BO) in its fullness— 26 the mystery(BP) that has been kept hidden for ages and generations, but is now disclosed to the Lord’s people. 27 To them God has chosen to make known(BQ) among the Gentiles the glorious riches(BR) of this mystery, which is Christ in you,(BS) the hope of glory.

28 He is the one we proclaim, admonishing(BT) and teaching everyone with all wisdom,(BU) so that we may present everyone fully mature(BV) in Christ. 29 To this end I strenuously(BW) contend(BX) with all the energy Christ so powerfully works in me.(BY)

Footnotes

  1. Colossians 1:2 The Greek word for brothers and sisters (adelphoi) refers here to believers, both men and women, as part of God’s family; also in 4:15.
  2. Colossians 1:2 Some manuscripts Father and the Lord Jesus Christ
  3. Colossians 1:7 Or slave
  4. Colossians 1:7 Some manuscripts your
  5. Colossians 1:9 Or all spiritual wisdom and understanding
  6. Colossians 1:12 Some manuscripts us
  7. Colossians 1:21 Or minds, as shown by