Add parallel Print Page Options

51 Ohùn ti Olúwa wí nìyìí:

“Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè
    sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai
Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli
    láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo;
wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà
    ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀
    jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀;
má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin
    sí, pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Gbogbo wọn ni yóò ṣubú
    ní Babeli tí wọn yóò sì
    fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
Nítorí pé Juda àti Israẹli ni
    Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn
    kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.

(A)“Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà
    fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
Àsìkò àti gbẹ̀san Ọlọ́run ni èyí,
    yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
(B)Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa;
    ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí.
Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀,
    wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́;
    Ẹ hu fun un!
Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ,
bóyá yóò le wo ọ́ sàn.

“ ‘À bá ti wo Babeli sàn,
    ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀,
kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè,
    ó ga àní títí dé òfúrufú.’

10 “ ‘Olúwa ti dá wa láre,
    wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa
    Ọlọ́run wa ti ṣe.’

11 “Ṣe ọfà rẹ ní mímú,
    mú apata!
    Olúwa ti ru ọba Media sókè,
nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run.
    Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
12 Gbé àsíá sókè sí odi Babeli!
    Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí,
ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri,
    ẹ ṣètò àwọn tí yóò sápamọ́
Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde,
    òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
13 (C)Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀,
    tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé,
    àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀,
    Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú,
    wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.

15 “Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀,
    o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀,
    o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
16 Nígbà tí ará omi ọ̀run hó
    ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé.
Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò,
    ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.

17 “Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ
    tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù
alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀.
    Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn wọn kò ní èémí nínú.
18 Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà,
    nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
19 Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí;
    nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo,
àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún,
    Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

20 “Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi,
    ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú,
    èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
21 Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀;
    èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú
    èmi ó pa awakọ̀
22 Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin,
    pẹ̀lú rẹ, mo pa
àgbàlagbà àti ọmọdé,
    Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
23 Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn,
    àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú,
èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú,
    èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.

24 “Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,”

    ni Olúwa wí.
25 “Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun
    ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,”
    ni Olúwa wí.
“Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ,
    èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta,
    Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
26 A kò ní mú òkúta kankan láti
    ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí
fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di
    ahoro títí ayé,”
    Olúwa wí.

27 “Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà!
    Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀,
    pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́:
    Ararati, Minini àti Aṣkenasi.
Yan olùdarí ogun láti kọlù ú,
    rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
28 Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀,
    àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀,
àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
29 Ilẹ̀ wárìrì síhìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé
    ète Olúwa, sí Babeli dúró
láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà
    tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
30 Gbogbo àwọn jagunjagun
    Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn.
Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin.
    Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun,
    gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
31 Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn
    láti sọ fún ọba Babeli pé
    gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
32 Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́
    ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”

33 Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí:

“Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”

34 “Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run,
    ó ti mú kí ìdààmú bá wa,
ó ti sọ wá di àgbá òfìfo.
    Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì.
Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀,
    lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
35 Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,”
    èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí.
“Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,”
    ni Jerusalẹmu wí.

36 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí:

“Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí
    ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san,
    èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
37 Babeli yóò parun pátápátá,
    yóò sì di ihò àwọn akátá,
    ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
38 Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù
    bí ọmọ kìnnìún.
39 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè,
    èmi yóò ṣe àsè fún wọn,
èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó
    tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín,
lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,”
    ni Olúwa wí.
40 “Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn
    tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.

41 “Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé.
    Irú ìpayà wo ni yóò bá
    Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
42 Òkun yóò ru borí Babeli,
    gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
43 Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro,
    ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn
    kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
44 Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli
    àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì.
    Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́.
    Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.

45 “Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀
    ẹ̀yin ènìyàn mi!
Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ!
    Sá fún ìbínú ńlá Ọlọ́run.
46 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú
    tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí
a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa;
    àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí,
òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá
    ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
47 Nítorí ìgbà náà yóò wá
    dandan nígbà tí èmi
yóò fi ìyà jẹ àwọn
    òrìṣà Babeli, gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì
    gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
48 Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn,
    yóò sì kọrin lórí Babeli:
nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,”
    ni Olúwa wí.

49 “Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli,
    gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
50 Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró:
    Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè,
    ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”

51 “Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn:
    ìtìjú ti bò wá lójú
    nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”

52 “Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí,
    “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀:
    àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀
53 Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run,
    bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ,
síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,”
    Olúwa wí.

54 “Ìró igbe láti Babeli,
    àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
55 Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ,
    ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀;
    àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
56 Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀,
    àní sórí Babeli;
a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn:
    nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa,
    yóò san án nítòótọ́.
57 Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí,
    àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀
àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀,
    wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,”
    ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

58 Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:

“Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá,
    ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun:
tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán,
    àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná,
    tí àárẹ̀ sì mú wọn.”

59 Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó. 60 Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli. 61 Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí. 62 Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’ 63 (D)Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate. 64 Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’ ”

Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.

51 This is what the Lord says:

“See, I will stir(A) up the spirit of a destroyer
    against Babylon(B) and the people of Leb Kamai.[a]
I will send foreigners(C) to Babylon
    to winnow(D) her and to devastate her land;
they will oppose her on every side
    in the day(E) of her disaster.
Let not the archer string his bow,(F)
    nor let him put on his armor.(G)
Do not spare her young men;
    completely destroy[b] her army.
They will fall(H) down slain in Babylon,[c]
    fatally wounded in her streets.(I)
For Israel and Judah have not been forsaken(J)
    by their God, the Lord Almighty,
though their land[d] is full of guilt(K)
    before the Holy One of Israel.

“Flee(L) from Babylon!
    Run for your lives!
    Do not be destroyed because of her sins.(M)
It is time(N) for the Lord’s vengeance;(O)
    he will repay(P) her what she deserves.
Babylon was a gold cup(Q) in the Lord’s hand;
    she made the whole earth drunk.
The nations drank her wine;
    therefore they have now gone mad.
Babylon will suddenly fall(R) and be broken.
    Wail over her!
Get balm(S) for her pain;
    perhaps she can be healed.

“‘We would have healed Babylon,
    but she cannot be healed;
let us leave(T) her and each go to our own land,
    for her judgment(U) reaches to the skies,
    it rises as high as the heavens.’

10 “‘The Lord has vindicated(V) us;
    come, let us tell in Zion
    what the Lord our God has done.’(W)

11 “Sharpen the arrows,(X)
    take up the shields!(Y)
The Lord has stirred up the kings(Z) of the Medes,(AA)
    because his purpose(AB) is to destroy Babylon.
The Lord will take vengeance,(AC)
    vengeance for his temple.(AD)
12 Lift up a banner(AE) against the walls of Babylon!
    Reinforce the guard,
station the watchmen,(AF)
    prepare an ambush!(AG)
The Lord will carry out his purpose,(AH)
    his decree against the people of Babylon.
13 You who live by many waters(AI)
    and are rich in treasures,(AJ)
your end has come,
    the time for you to be destroyed.(AK)
14 The Lord Almighty has sworn by himself:(AL)
    I will surely fill you with troops, as with a swarm of locusts,(AM)
    and they will shout(AN) in triumph over you.

15 “He made the earth by his power;
    he founded the world by his wisdom(AO)
    and stretched(AP) out the heavens by his understanding.(AQ)
16 When he thunders,(AR) the waters in the heavens roar;
    he makes clouds rise from the ends of the earth.
He sends lightning with the rain(AS)
    and brings out the wind from his storehouses.(AT)

17 “Everyone is senseless and without knowledge;
    every goldsmith is shamed by his idols.
The images he makes are a fraud;(AU)
    they have no breath in them.
18 They are worthless,(AV) the objects of mockery;
    when their judgment comes, they will perish.
19 He who is the Portion(AW) of Jacob is not like these,
    for he is the Maker of all things,
including the people of his inheritance(AX)
    the Lord Almighty is his name.

20 “You are my war club,(AY)
    my weapon for battle—
with you I shatter(AZ) nations,(BA)
    with you I destroy kingdoms,
21 with you I shatter horse and rider,(BB)
    with you I shatter chariot(BC) and driver,
22 with you I shatter man and woman,
    with you I shatter old man and youth,
    with you I shatter young man and young woman,(BD)
23 with you I shatter shepherd and flock,
    with you I shatter farmer and oxen,
    with you I shatter governors and officials.(BE)

24 “Before your eyes I will repay(BF) Babylon(BG) and all who live in Babylonia[e] for all the wrong they have done in Zion,” declares the Lord.

25 “I am against(BH) you, you destroying mountain,
    you who destroy the whole earth,”(BI)
declares the Lord.
“I will stretch out my hand(BJ) against you,
    roll you off the cliffs,
    and make you a burned-out mountain.(BK)
26 No rock will be taken from you for a cornerstone,
    nor any stone for a foundation,
    for you will be desolate(BL) forever,”
declares the Lord.

27 “Lift up a banner(BM) in the land!
    Blow the trumpet among the nations!
Prepare the nations for battle against her;
    summon against her these kingdoms:(BN)
    Ararat,(BO) Minni and Ashkenaz.(BP)
Appoint a commander against her;
    send up horses like a swarm of locusts.(BQ)
28 Prepare the nations for battle against her—
    the kings of the Medes,(BR)
their governors and all their officials,
    and all the countries they rule.(BS)
29 The land trembles(BT) and writhes,
    for the Lord’s purposes(BU) against Babylon stand—
to lay waste(BV) the land of Babylon
    so that no one will live there.(BW)
30 Babylon’s warriors(BX) have stopped fighting;
    they remain in their strongholds.
Their strength is exhausted;
    they have become weaklings.(BY)
Her dwellings are set on fire;(BZ)
    the bars(CA) of her gates are broken.
31 One courier(CB) follows another
    and messenger follows messenger
to announce to the king of Babylon
    that his entire city is captured,(CC)
32 the river crossings seized,
    the marshes set on fire,(CD)
    and the soldiers terrified.(CE)

33 This is what the Lord Almighty, the God of Israel, says:

“Daughter Babylon(CF) is like a threshing floor(CG)
    at the time it is trampled;
    the time to harvest(CH) her will soon come.(CI)

34 “Nebuchadnezzar(CJ) king of Babylon has devoured(CK) us,(CL)
    he has thrown us into confusion,
    he has made us an empty jar.
Like a serpent he has swallowed us
    and filled his stomach with our delicacies,
    and then has spewed(CM) us out.
35 May the violence(CN) done to our flesh[f] be on Babylon,”
    say the inhabitants of Zion.
“May our blood be on those who live in Babylonia,”
    says Jerusalem.(CO)

36 Therefore this is what the Lord says:

“See, I will defend your cause(CP)
    and avenge(CQ) you;
I will dry up(CR) her sea
    and make her springs dry.
37 Babylon will be a heap of ruins,
    a haunt(CS) of jackals,
an object of horror and scorn,(CT)
    a place where no one lives.(CU)
38 Her people all roar like young lions,(CV)
    they growl like lion cubs.
39 But while they are aroused,
    I will set out a feast for them
    and make them drunk,(CW)
so that they shout with laughter—
    then sleep forever(CX) and not awake,”
declares the Lord.(CY)
40 “I will bring them down
    like lambs to the slaughter,
    like rams and goats.(CZ)

41 “How Sheshak[g](DA) will be captured,(DB)
    the boast of the whole earth seized!
How desolate(DC) Babylon will be
    among the nations!
42 The sea will rise over Babylon;
    its roaring waves(DD) will cover her.
43 Her towns will be desolate,
    a dry and desert(DE) land,
a land where no one lives,
    through which no one travels.(DF)
44 I will punish Bel(DG) in Babylon
    and make him spew out(DH) what he has swallowed.
The nations will no longer stream to him.
    And the wall(DI) of Babylon will fall.

45 “Come out(DJ) of her, my people!
    Run(DK) for your lives!
    Run from the fierce anger(DL) of the Lord.
46 Do not lose heart(DM) or be afraid(DN)
    when rumors(DO) are heard in the land;
one rumor comes this year, another the next,
    rumors of violence in the land
    and of ruler against ruler.
47 For the time will surely come
    when I will punish the idols(DP) of Babylon;
her whole land will be disgraced(DQ)
    and her slain will all lie fallen within her.(DR)
48 Then heaven and earth and all that is in them
    will shout(DS) for joy over Babylon,
for out of the north(DT)
    destroyers(DU) will attack her,”
declares the Lord.

49 “Babylon must fall because of Israel’s slain,
    just as the slain in all the earth
    have fallen because of Babylon.(DV)
50 You who have escaped the sword,
    leave(DW) and do not linger!
Remember(DX) the Lord in a distant land,(DY)
    and call to mind Jerusalem.”

51 “We are disgraced,(DZ)
    for we have been insulted
    and shame covers our faces,
because foreigners have entered
    the holy places of the Lord’s house.”(EA)

52 “But days are coming,” declares the Lord,
    “when I will punish her idols,(EB)
and throughout her land
    the wounded will groan.(EC)
53 Even if Babylon ascends to the heavens(ED)
    and fortifies her lofty stronghold,
    I will send destroyers(EE) against her,”
declares the Lord.

54 “The sound of a cry(EF) comes from Babylon,
    the sound of great destruction(EG)
    from the land of the Babylonians.[h]
55 The Lord will destroy Babylon;
    he will silence(EH) her noisy din.
Waves(EI) of enemies will rage like great waters;
    the roar of their voices will resound.
56 A destroyer(EJ) will come against Babylon;
    her warriors will be captured,
    and their bows will be broken.(EK)
For the Lord is a God of retribution;
    he will repay(EL) in full.
57 I will make her officials(EM) and wise(EN) men drunk,(EO)
    her governors, officers and warriors as well;
they will sleep(EP) forever and not awake,”
    declares the King,(EQ) whose name is the Lord Almighty.

58 This is what the Lord Almighty says:

“Babylon’s thick wall(ER) will be leveled
    and her high gates(ES) set on fire;
the peoples(ET) exhaust(EU) themselves for nothing,
    the nations’ labor is only fuel for the flames.”(EV)

59 This is the message Jeremiah the prophet gave to the staff officer Seraiah son of Neriah,(EW) the son of Mahseiah, when he went to Babylon with Zedekiah(EX) king of Judah in the fourth(EY) year of his reign. 60 Jeremiah had written on a scroll(EZ) about all the disasters that would come upon Babylon—all that had been recorded concerning Babylon. 61 He said to Seraiah, “When you get to Babylon, see that you read all these words aloud. 62 Then say, ‘Lord, you have said you will destroy this place, so that neither people nor animals will live in it; it will be desolate(FA) forever.’ 63 When you finish reading this scroll, tie a stone to it and throw it into the Euphrates.(FB) 64 Then say, ‘So will Babylon sink to rise no more(FC) because of the disaster I will bring on her. And her people(FD) will fall.’”(FE)

The words of Jeremiah end(FF) here.

Footnotes

  1. Jeremiah 51:1 Leb Kamai is a cryptogram for Chaldea, that is, Babylonia.
  2. Jeremiah 51:3 The Hebrew term refers to the irrevocable giving over of things or persons to the Lord, often by totally destroying them.
  3. Jeremiah 51:4 Or Chaldea
  4. Jeremiah 51:5 Or Almighty, / and the land of the Babylonians
  5. Jeremiah 51:24 Or Chaldea; also in verse 35
  6. Jeremiah 51:35 Or done to us and to our children
  7. Jeremiah 51:41 Sheshak is a cryptogram for Babylon.
  8. Jeremiah 51:54 Or Chaldeans