Add parallel Print Page Options

31 (A)(B) “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí,
    “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli
àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
32 Kò ní dàbí májẹ̀mú
    tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá,
nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́,
    tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti
nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi.
    Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,”
    ni Olúwa wí.
33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá
    lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé:
“Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn,
    èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn.
Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn;
    àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀
    tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’
nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí
    láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,”
    ni Olúwa wí.
“Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì,
    èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”

Read full chapter