Add parallel Print Page Options

Besaleli àti Oholiabu

31 (A)Olúwa wí fún Mose pé, “Wò ó, èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda, Èmi sì ti fi ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà. Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ, láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà. Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́.

“Bákan náà, èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:

“àgọ́ àjọ náà,

àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀,

àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,

tábìlì àti ohun èlò rẹ̀,

ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀,

pẹpẹ tùràrí,

pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀,

agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,

10 àti aṣọ híhun pẹ̀lú,

papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà

àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,

11 òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún ibi mímọ́.

“Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”

Ọjọ́ ìsinmi

12 (B)Olúwa wí fún Mose pé, 13 “Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ ààmì láàrín èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.

14 “ ‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ. 15 Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́. 16 Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé. 17 Yóò jẹ́ ààmì láàrín èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’ ”

18 Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.

Bezalel and Oholiab(A)

31 Then the Lord said to Moses, “See, I have chosen Bezalel(B) son of Uri, the son of Hur,(C) of the tribe of Judah, and I have filled him with the Spirit of God, with wisdom, with understanding, with knowledge(D) and with all kinds of skills(E) to make artistic designs for work in gold, silver and bronze, to cut and set stones, to work in wood, and to engage in all kinds of crafts. Moreover, I have appointed Oholiab(F) son of Ahisamak, of the tribe of Dan,(G) to help him. Also I have given ability to all the skilled workers(H) to make everything I have commanded you: the tent of meeting,(I) the ark of the covenant law(J) with the atonement cover(K) on it, and all the other furnishings of the tent— the table(L) and its articles, the pure gold lampstand(M) and all its accessories, the altar of incense,(N) the altar of burnt offering(O) and all its utensils, the basin(P) with its stand— 10 and also the woven garments(Q), both the sacred garments for Aaron the priest and the garments for his sons when they serve as priests, 11 and the anointing oil(R) and fragrant incense(S) for the Holy Place. They are to make them just as I commanded(T) you.”

The Sabbath

12 Then the Lord said to Moses, 13 “Say to the Israelites, ‘You must observe my Sabbaths.(U) This will be a sign(V) between me and you for the generations to come,(W) so you may know that I am the Lord, who makes you holy.(X)

14 “‘Observe the Sabbath, because it is holy to you. Anyone who desecrates it is to be put to death;(Y) those who do any work on that day must be cut off from their people. 15 For six days work(Z) is to be done, but the seventh day is a day of sabbath rest,(AA) holy to the Lord. Whoever does any work on the Sabbath day is to be put to death. 16 The Israelites are to observe the Sabbath,(AB) celebrating it for the generations to come as a lasting covenant. 17 It will be a sign(AC) between me and the Israelites forever, for in six days the Lord made the heavens and the earth, and on the seventh day he rested and was refreshed.(AD)’”(AE)

18 When the Lord finished speaking to Moses on Mount Sinai,(AF) he gave him the two tablets of the covenant law, the tablets of stone(AG) inscribed by the finger of God.(AH)