Eksodu 31:1-6
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Besaleli àti Oholiabu
31 (A)Olúwa wí fún Mose pé, 2 “Wò ó, èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda, 3 Èmi sì ti fi ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà. 4 Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ, 5 láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà. 6 Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́.
“Bákan náà, èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
Exodus 31:1-6
New International Version
Bezalel and Oholiab(A)
31 Then the Lord said to Moses, 2 “See, I have chosen Bezalel(B) son of Uri, the son of Hur,(C) of the tribe of Judah, 3 and I have filled him with the Spirit of God, with wisdom, with understanding, with knowledge(D) and with all kinds of skills(E)— 4 to make artistic designs for work in gold, silver and bronze, 5 to cut and set stones, to work in wood, and to engage in all kinds of crafts. 6 Moreover, I have appointed Oholiab(F) son of Ahisamak, of the tribe of Dan,(G) to help him. Also I have given ability to all the skilled workers(H) to make everything I have commanded you:
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.