Add parallel Print Page Options

Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù,
    wúrà dídára di àìdán!
Òkúta ibi mímọ́ wá túká
    sí oríta gbogbo òpópó.

Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye,
    tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe
wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán
    iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!

Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn
    fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn,
ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn
    bí ògòǹgò ní aginjù.

Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́
    lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn;
àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ
    Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.

Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára
    di òtòṣì ní òpópó.
Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀
    ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.

Ìjìyà àwọn ènìyàn mi
    tóbi ju ti Sodomu lọ,
tí a sí ní ipò ní òjijì
    láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.

Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì,
    wọ́n sì funfun ju wàrà lọ
wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa,
    ìrísí wọn dàbí safire.

Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú;
    wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó.
Ara wọn hun mọ́ egungun;
    ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.

Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn
    ju àwọn tí ìyàn pa;
tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò
    fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.

10 Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú
    ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ
tí ó di oúnjẹ fún wọn
    nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.

11 Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀;
    ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde.
Ó da iná ní Sioni
    tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.

12 Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́,
    tàbí àwọn ènìyàn ayé,
wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ
    odi ìlú Jerusalẹmu.

13 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì
    àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà,
tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo
    sílẹ̀ láàrín rẹ̀.

14 Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó
    bí ọkùnrin tí ó fọ́jú.
Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n
    tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.

15 “Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn.
    “Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!”
Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé,
    “Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”

16 Olúwa ti tú wọn ká fúnrarẹ̀;
    kò sí bojútó wọn mọ́.
Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́,
    àti àánú fún àwọn àgbàgbà.

17 Síwájú sí i, ojú wa kùnà
    fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán;
láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò
    fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.

18 Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri,
    àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́.
Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye
    nítorí òpin wa ti dé.

19 Àwọn tí ń lé wa yára
    ju idì ojú ọ̀run lọ;
wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè
    wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.

20 Ẹni ààmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa,
    ni wọ́n fi tàkúté wọn mú.
Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀
    ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.

21 Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu,
    ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi.
Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú;
    ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.

22 Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin;
    kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́.
Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà
    yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.

[a]How the gold has lost its luster,
    the fine gold become dull!
The sacred gems are scattered
    at every street corner.(A)

How the precious children of Zion,(B)
    once worth their weight in gold,
are now considered as pots of clay,
    the work of a potter’s hands!

Even jackals offer their breasts
    to nurse their young,
but my people have become heartless
    like ostriches in the desert.(C)

Because of thirst(D) the infant’s tongue
    sticks to the roof of its mouth;(E)
the children beg for bread,
    but no one gives it to them.(F)

Those who once ate delicacies
    are destitute in the streets.
Those brought up in royal purple(G)
    now lie on ash heaps.(H)

The punishment of my people
    is greater than that of Sodom,(I)
which was overthrown in a moment
    without a hand turned to help her.

Their princes were brighter than snow
    and whiter than milk,
their bodies more ruddy than rubies,
    their appearance like lapis lazuli.

But now they are blacker(J) than soot;
    they are not recognized in the streets.
Their skin has shriveled on their bones;(K)
    it has become as dry as a stick.

Those killed by the sword are better off
    than those who die of famine;(L)
racked with hunger, they waste away
    for lack of food from the field.(M)

10 With their own hands compassionate women
    have cooked their own children,(N)
who became their food
    when my people were destroyed.

11 The Lord has given full vent to his wrath;(O)
    he has poured out(P) his fierce anger.(Q)
He kindled a fire(R) in Zion
    that consumed her foundations.(S)

12 The kings of the earth did not believe,
    nor did any of the peoples of the world,
that enemies and foes could enter
    the gates of Jerusalem.(T)

13 But it happened because of the sins of her prophets
    and the iniquities of her priests,(U)
who shed within her
    the blood(V) of the righteous.

14 Now they grope through the streets
    as if they were blind.(W)
They are so defiled with blood(X)
    that no one dares to touch their garments.

15 “Go away! You are unclean!” people cry to them.
    “Away! Away! Don’t touch us!”
When they flee and wander(Y) about,
    people among the nations say,
    “They can stay here no longer.”(Z)

16 The Lord himself has scattered them;
    he no longer watches over them.(AA)
The priests are shown no honor,
    the elders(AB) no favor.(AC)

17 Moreover, our eyes failed,
    looking in vain(AD) for help;(AE)
from our towers we watched
    for a nation(AF) that could not save us.

18 People stalked us at every step,
    so we could not walk in our streets.
Our end was near, our days were numbered,
    for our end had come.(AG)

19 Our pursuers were swifter
    than eagles(AH) in the sky;
they chased us(AI) over the mountains
    and lay in wait for us in the desert.(AJ)

20 The Lord’s anointed,(AK) our very life breath,
    was caught in their traps.(AL)
We thought that under his shadow(AM)
    we would live among the nations.

21 Rejoice and be glad, Daughter Edom,
    you who live in the land of Uz.(AN)
But to you also the cup(AO) will be passed;
    you will be drunk and stripped naked.(AP)

22 Your punishment will end, Daughter Zion;(AQ)
    he will not prolong your exile.
But he will punish your sin, Daughter Edom,
    and expose your wickedness.(AR)

Footnotes

  1. Lamentations 4:1 This chapter is an acrostic poem, the verses of which begin with the successive letters of the Hebrew alphabet.