Add parallel Print Page Options

Kẹ̀kẹ́ ogun mẹ́rin tí ìdájọ́ Ọlọ́run

(A)Mo sì yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, kẹ̀kẹ́ mẹ́rin jáde wá láti àárín òkè ńlá méjì, àwọn òkè-ńlá náà sì jẹ́ òkè-ńlá idẹ. Àwọn ẹṣin pupa wà ní kẹ̀kẹ́ èkínní; àti àwọn ẹṣin dúdú ní kẹ̀kẹ́ èkejì. Àti àwọn ẹṣin funfun ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹta; àti àwọn adíkálà àti alágbára ẹṣin ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹrin. Mo sì dáhùn, mo sì béèrè lọ́wọ́ angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni ìwọ̀nyí, olúwa mi.”

(B)Angẹli náà si dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀mí mẹ́rin ti ọ̀run, tí wọn ń lọ kúrò lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ara wọn hàn níwájú Olúwa gbogbo ayé. Àwọn ẹṣin dúdú tí ó wà nínú rẹ̀ jáde lọ sí ilẹ̀ àríwá; àwọn funfun sì jáde lọ si ìwọ̀-oòrùn; àwọn adíkálà sì jáde lọ sí ìhà ilẹ̀ gúúsù.”

Àwọn alágbára ẹṣin sì jáde lọ, wọ́n sì ń wá ọ̀nà àti lọ kí wọn bá a lè rìn síhìn-ín sọ́hùn-ún ni ayé; ó sì wí pé, “Ẹ lọ, ẹ lọ rìn síhìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé!” Wọ́n sì rín síhìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé.

Nígbà náà ni ohùn kan sì ké sí mi, ó sì bá mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wò ó, àwọn wọ̀nyí tí ó lọ síhà ilẹ̀ àríwá ti mú ẹ̀mí mi parọ́rọ́ ni ilẹ̀ àríwá.”

Adé fún Joṣua

Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé: 10 “Mú nínú ìgbèkùn, nínú àwọn Heldai, tí Tobiah, àti ti Jedaiah, tí ó ti Babeli dé, kí ìwọ sì wá ní ọjọ́ kan náà, kí o sì wọ ilé Josiah ọmọ Sefaniah lọ. 11 Kí o sì mú fàdákà àti wúrà, kí o sì fi ṣe adé púpọ̀, sì gbé wọn ka orí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà. 12 (C)Sì sọ fún un pé: ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé, wo ọkùnrin náà ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹ̀ka; yóò sì yọ ẹ̀ka láti abẹ́ rẹ̀ wá, yóò si kọ́ tẹmpili Olúwa wa. 13 Òun ni yóò sì kọ́ tẹmpili Olúwa òun ni yóò sì wọ̀ ní ògo, yóò sì jókòó, yóò sì jẹ ọba lórí ìtẹ́ rẹ̀; òun ó sì jẹ́ àlùfáà lórí ìtẹ́ rẹ̀; ìmọ̀ àlàáfíà yóò sì wá láàrín àwọn méjèèjì.’ 14 Adé wọ̀nyí yóò sì wà fún Helemu àti fún Tobiah, àti fún Jedaiah, àti fún Heni ọmọ Sefaniah fún ìrántí ni tẹmpili Olúwa. 15 Àwọn tí ó jìnnà réré yóò wá láti kọ́ tẹmpili Olúwa, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rán mi sí yín. Yóò sì rí bẹ́ẹ̀ bí ẹ̀yin yóò bá gbà ohùn Olúwa, Ọlọ́run yín gbọ́ nítòótọ́.”

Four Chariots

I looked up again, and there before me were four chariots(A) coming out from between two mountains—mountains of bronze. The first chariot had red horses, the second black,(B) the third white,(C) and the fourth dappled—all of them powerful. I asked the angel who was speaking to me, “What are these, my lord?”

The angel answered me, “These are the four spirits[a](D) of heaven, going out from standing in the presence of the Lord of the whole world.(E) The one with the black horses is going toward the north country, the one with the white horses toward the west,[b] and the one with the dappled horses toward the south.”

When the powerful horses went out, they were straining to go throughout the earth.(F) And he said, “Go throughout the earth!” So they went throughout the earth.

Then he called to me, “Look, those going toward the north country have given my Spirit[c] rest(G) in the land of the north.”(H)

A Crown for Joshua

The word of the Lord came to me: 10 “Take silver and gold from the exiles Heldai, Tobijah and Jedaiah, who have arrived from Babylon.(I) Go the same day to the house of Josiah son of Zephaniah. 11 Take the silver and gold and make a crown,(J) and set it on the head of the high priest, Joshua(K) son of Jozadak.[d](L) 12 Tell him this is what the Lord Almighty says: ‘Here is the man whose name is the Branch,(M) and he will branch out from his place and build the temple of the Lord.(N) 13 It is he who will build the temple of the Lord, and he will be clothed with majesty and will sit and rule on his throne. And he[e] will be a priest(O) on his throne. And there will be harmony between the two.’ 14 The crown will be given to Heldai,[f] Tobijah, Jedaiah and Hen[g] son of Zephaniah as a memorial(P) in the temple of the Lord. 15 Those who are far away will come and help to build the temple of the Lord,(Q) and you will know that the Lord Almighty has sent me to you.(R) This will happen if you diligently obey(S) the Lord your God.”

Footnotes

  1. Zechariah 6:5 Or winds
  2. Zechariah 6:6 Or horses after them
  3. Zechariah 6:8 Or spirit
  4. Zechariah 6:11 Hebrew Jehozadak, a variant of Jozadak
  5. Zechariah 6:13 Or there
  6. Zechariah 6:14 Syriac; Hebrew Helem
  7. Zechariah 6:14 Or and the gracious one, the