Add parallel Print Page Options

Maskili ti Etani ará Esra.

89 Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé;
    pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé,
    pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnrarẹ̀.
(A)Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi
    mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé
    èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’ ”

Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa,
    òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa?
    Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi;
    ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ
    ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.

Ìwọ ń darí ríru omi Òkun;
    nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
10 Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ
    bí ẹni tí a pa;
ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ
    tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
11 Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ:
    ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀:
ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
12 Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn;
    Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
13 Ìwọ ní apá agbára;
    agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.

14 Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ:
    ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì,
    Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
16 Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́,
    wọn ń yin òdodo rẹ.
17 Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn;
    nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
18 Nítorí ti Olúwa ni asà wa,
    ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.

19 Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé:
    “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára,
    èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
20 (B)Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi;
    pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án;
21 Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀
    apá mí yóò sì fi agbára fún un.
22 Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀,
    àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀
23 Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ
    èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀
24 Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ
    àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
25 Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí Òkun
    àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá
26 Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
27 (C)Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi,
    Ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
28 Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un,
    àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
29 Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé,
    àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.

30 “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀
    tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
31 Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́
    tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
32 Nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò;
    àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán:
33 Ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ,
    bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
34 Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi,
    bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
35 Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra;
èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
36 Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé,
    àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
37 (D)A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá,
    àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run”. Sela.

38 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra;
    ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni ààmì òróró rẹ.
39 Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo;
    ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku
40 Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀
    ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
41 Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ;
    ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
42 Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè;
    ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
43 Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà,
    ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
44 Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà,
    ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
45 Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú;
    ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.

46 Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa?
    Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé?
    Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
47 Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó
    nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
48 Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀?
    Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú?
49 Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà,
    tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
50 Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ;
    bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
51 Ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa,
    tí wọn gan ipasẹ̀ Ẹni ààmì òróró rẹ.

52 Olùbùkún ní Olúwa títí láé.
Àmín àti Àmín.

Psalm 89[a]

A maskil[b] of Ethan the Ezrahite.

I will sing(A) of the Lord’s great love forever;
    with my mouth I will make your faithfulness known(B)
    through all generations.
I will declare that your love stands firm forever,
    that you have established your faithfulness in heaven itself.(C)
You said, “I have made a covenant with my chosen one,
    I have sworn to David my servant,
‘I will establish your line forever
    and make your throne firm through all generations.’”[c](D)

The heavens(E) praise your wonders, Lord,
    your faithfulness too, in the assembly(F) of the holy ones.
For who in the skies above can compare with the Lord?
    Who is like the Lord among the heavenly beings?(G)
In the council(H) of the holy ones(I) God is greatly feared;
    he is more awesome than all who surround him.(J)
Who is like you,(K) Lord God Almighty?(L)
    You, Lord, are mighty, and your faithfulness surrounds you.

You rule over the surging sea;
    when its waves mount up, you still them.(M)
10 You crushed Rahab(N) like one of the slain;
    with your strong arm you scattered(O) your enemies.
11 The heavens are yours,(P) and yours also the earth;(Q)
    you founded the world and all that is in it.(R)
12 You created the north and the south;
    Tabor(S) and Hermon(T) sing for joy(U) at your name.
13 Your arm is endowed with power;
    your hand is strong, your right hand exalted.(V)

14 Righteousness and justice are the foundation of your throne;(W)
    love and faithfulness go before you.(X)
15 Blessed are those who have learned to acclaim you,
    who walk(Y) in the light(Z) of your presence, Lord.
16 They rejoice in your name(AA) all day long;
    they celebrate your righteousness.
17 For you are their glory and strength,(AB)
    and by your favor you exalt our horn.[d](AC)
18 Indeed, our shield[e](AD) belongs to the Lord,
    our king(AE) to the Holy One of Israel.

19 Once you spoke in a vision,
    to your faithful people you said:
“I have bestowed strength on a warrior;
    I have raised up a young man from among the people.
20 I have found David(AF) my servant;(AG)
    with my sacred oil(AH) I have anointed(AI) him.
21 My hand will sustain him;
    surely my arm will strengthen him.(AJ)
22 The enemy will not get the better of him;(AK)
    the wicked will not oppress(AL) him.
23 I will crush his foes before him(AM)
    and strike down his adversaries.(AN)
24 My faithful love will be with him,(AO)
    and through my name his horn[f] will be exalted.
25 I will set his hand over the sea,
    his right hand over the rivers.(AP)
26 He will call out to me, ‘You are my Father,(AQ)
    my God, the Rock(AR) my Savior.’(AS)
27 And I will appoint him to be my firstborn,(AT)
    the most exalted(AU) of the kings(AV) of the earth.
28 I will maintain my love to him forever,
    and my covenant with him will never fail.(AW)
29 I will establish his line forever,
    his throne as long as the heavens endure.(AX)

30 “If his sons forsake my law
    and do not follow my statutes,
31 if they violate my decrees
    and fail to keep my commands,
32 I will punish their sin with the rod,
    their iniquity with flogging;(AY)
33 but I will not take my love from him,(AZ)
    nor will I ever betray my faithfulness.
34 I will not violate my covenant
    or alter what my lips have uttered.(BA)
35 Once for all, I have sworn by my holiness—
    and I will not lie to David—
36 that his line will continue forever
    and his throne endure before me like the sun;(BB)
37 it will be established forever like the moon,
    the faithful witness in the sky.”(BC)

38 But you have rejected,(BD) you have spurned,
    you have been very angry with your anointed one.
39 You have renounced the covenant with your servant
    and have defiled his crown in the dust.(BE)
40 You have broken through all his walls(BF)
    and reduced his strongholds(BG) to ruins.
41 All who pass by have plundered(BH) him;
    he has become the scorn of his neighbors.(BI)
42 You have exalted the right hand of his foes;
    you have made all his enemies rejoice.(BJ)
43 Indeed, you have turned back the edge of his sword
    and have not supported him in battle.(BK)
44 You have put an end to his splendor
    and cast his throne to the ground.
45 You have cut short(BL) the days of his youth;
    you have covered him with a mantle of shame.(BM)

46 How long, Lord? Will you hide yourself forever?
    How long will your wrath burn like fire?(BN)
47 Remember how fleeting is my life.(BO)
    For what futility you have created all humanity!
48 Who can live and not see death,
    or who can escape the power of the grave?(BP)
49 Lord, where is your former great love,
    which in your faithfulness you swore to David?
50 Remember, Lord, how your servant has[g] been mocked,(BQ)
    how I bear in my heart the taunts of all the nations,
51 the taunts with which your enemies, Lord, have mocked,
    with which they have mocked every step of your anointed one.(BR)

52 Praise be to the Lord forever!
Amen and Amen.(BS)

Footnotes

  1. Psalm 89:1 In Hebrew texts 89:1-52 is numbered 89:2-53.
  2. Psalm 89:1 Title: Probably a literary or musical term
  3. Psalm 89:4 The Hebrew has Selah (a word of uncertain meaning) here and at the end of verses 37, 45 and 48.
  4. Psalm 89:17 Horn here symbolizes strong one.
  5. Psalm 89:18 Or sovereign
  6. Psalm 89:24 Horn here symbolizes strength.
  7. Psalm 89:50 Or your servants have