Add parallel Print Page Options

71 Nínú rẹ, Olúwa, ni mo ní ààbò;
    Má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Gbà mí kí o sì tú mi sílẹ̀ nínú òdodo rẹ;
    dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbà mí.
Jẹ́ àpáta ààbò mi,
    níbi tí èmi lè máa lọ,
pa àṣẹ láti gbà mí,
    nítorí ìwọ ni àpáta àti odi agbára mi.
Gbà mí, Ọlọ́run mi, lọ́wọ́ àwọn olùṣe búburú,
    ní ọwọ́ aláìṣòdodo àti ìkà ọkùnrin.

Nítorí ìwọ jẹ́ ìrètí mi, Olúwa Olódùmarè,
    ìwọ ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi láti ìgbà èwe.
Mo gbẹ́kẹ̀lé ọ láti ìgbà ìbí mi;
    Ìwọ mú mi jáde láti inú ìyá mi wá
èmi ó máa yìn ọ́ títí láé.
Mo di ààmì fún ọ̀pọ̀ ènìyàn,
    ṣùgbọ́n ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.
Ìyìn rẹ̀ kún ẹnu mi,
    ó ń sọ ti ọlá rẹ ní ọjọ́ gbogbo.

Má ṣe ta mí nù ní ọjọ́ ogbó mi
    Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́
10 Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀-òdì sí mi,
    àwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀.
11 Wọ́n wí pé, “Ọlọ́run ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀;
    lépa rẹ̀ kí ẹ sì mu,
    nítorí kò sí ẹni tí yóò gbà á.”
12 Má ṣe jìnnà sí mi, Ọlọ́run;
    wa kánkán, Ọlọ́run mi, láti ràn mí lọ́wọ́.
13 Jẹ́ kí wọn kí ó dààmú,
    kí a sì run àwọn tí ń ṣe ọ̀tá ọkàn mi
kí a sì fi ẹ̀gàn àti àbùkù
    bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.

14 Ṣùgbọ́n ní tèmi, ìgbà gbogbo ní ìrètí mi;
    èmi ó yìn ọ́ síwájú àti síwájú sí i.

15 Ẹnu mi yóò sọ nípa ti òdodo rẹ,
ti ìgbàlà rẹ, ni gbogbo ọjọ́,
lóòtítọ́, èmi kò mọ iye rẹ̀.
16 Èmi ó wá láti wá kéde agbára,
    Olúwa Olódùmarè;
    èmi ó kéde òdodo rẹ̀ nìkan.
17 Láti ìgbà èwe, Ọlọ́run ni ìwọ ti kọ́ mi
    títí di òní ni mo ń sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ.
18 Pẹ̀lúpẹ̀lú, nígbà tí èmi di arúgbó tán tí mo sì hewú,
    Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, Ọlọ́run mi,
títí èmi ó fi ipá rẹ han ìran tí ń bọ̀,
    àti agbára rẹ fún gbogbo àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn.

19 Ọlọ́run, òdodo rẹ dé ọ̀run,
    ìwọ tí o ti ṣe ohun ńlá
    Ta ni ó dàbí rẹ, Ọlọ́run?
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ ti mú mi rí ìdààmú, tí ó pọ̀ tí ó sì korò,
    ìwọ yóò tún sọ ayé mi jí
ìwọ yóò sì tún mú mi sọ sókè
    láti ọ̀gbun ilẹ̀ wá.
Ìwọ yóò sọ ọlá mi di púpọ̀
21 Ìwọ yóò fi kún ọwọ́ mi
    ìwọ yóò tù mí nínú ní ha gbogbo.

22 Èmi yóò fi dùùrù mi yìn
    fún òtítọ́ rẹ, Ọlọ́run mi;
èmi ó kọrin ìyìn sí ọ pẹ̀lú dùùrù
    ìwọ ẹni mímọ́ Israẹli.
23 Ètè mi yóò kígbe fún ìyìn
    nígbà tí mo bá kọrin ìyìn sí ọ:
    èmi, ẹni tí o rà padà.
24 Ahọ́n mi yóò sọ ti òdodo rẹ ní gbogbo ọjọ́,
    fún àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára,
    a sì dójúti àwọn tí ń wá ìdààmú mi.

Psalm 71(A)

In you, Lord, I have taken refuge;(B)
    let me never be put to shame.(C)
In your righteousness, rescue me and deliver me;
    turn your ear(D) to me and save me.
Be my rock of refuge,
    to which I can always go;
give the command to save me,
    for you are my rock and my fortress.(E)
Deliver(F) me, my God, from the hand of the wicked,(G)
    from the grasp of those who are evil and cruel.(H)

For you have been my hope,(I) Sovereign Lord,
    my confidence(J) since my youth.
From birth(K) I have relied on you;
    you brought me forth from my mother’s womb.(L)
    I will ever praise(M) you.
I have become a sign(N) to many;
    you are my strong refuge.(O)
My mouth(P) is filled with your praise,
    declaring your splendor(Q) all day long.

Do not cast(R) me away when I am old;(S)
    do not forsake(T) me when my strength is gone.
10 For my enemies(U) speak against me;
    those who wait to kill(V) me conspire(W) together.
11 They say, “God has forsaken(X) him;
    pursue him and seize him,
    for no one will rescue(Y) him.”
12 Do not be far(Z) from me, my God;
    come quickly, God, to help(AA) me.
13 May my accusers(AB) perish in shame;(AC)
    may those who want to harm me
    be covered with scorn and disgrace.(AD)

14 As for me, I will always have hope;(AE)
    I will praise you more and more.

15 My mouth will tell(AF) of your righteous deeds,(AG)
    of your saving acts all day long—
    though I know not how to relate them all.
16 I will come and proclaim your mighty acts,(AH) Sovereign Lord;
    I will proclaim your righteous deeds, yours alone.
17 Since my youth, God, you have taught(AI) me,
    and to this day I declare your marvelous deeds.(AJ)
18 Even when I am old and gray,(AK)
    do not forsake me, my God,
till I declare your power(AL) to the next generation,
    your mighty acts to all who are to come.(AM)

19 Your righteousness, God, reaches to the heavens,(AN)
    you who have done great things.(AO)
    Who is like you, God?(AP)
20 Though you have made me see troubles,(AQ)
    many and bitter,
    you will restore(AR) my life again;
from the depths of the earth(AS)
    you will again bring me up.
21 You will increase my honor(AT)
    and comfort(AU) me once more.

22 I will praise you with the harp(AV)
    for your faithfulness, my God;
I will sing praise to you with the lyre,(AW)
    Holy One of Israel.(AX)
23 My lips will shout for joy(AY)
    when I sing praise to you—
    I whom you have delivered.(AZ)
24 My tongue will tell of your righteous acts
    all day long,(BA)
for those who wanted to harm me(BB)
    have been put to shame and confusion.(BC)