Add parallel Print Page Options

Ṣiggaioni ti Dafidi, èyí tí ó kọ sí Olúwa nípa Kuṣi, ará Benjamini.

Olúwa Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú rẹ;
    gba mí là kí o sì tú mi sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,
kí wọn ó má ba à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìún,
    wọ́n á ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gbà mí.

Olúwa Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyí
    tí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi
Bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mi,
    tí mo ja ọ̀tá mi lólè láìnídìí:
Nígbà náà, jẹ́ kí ọ̀tá mi lé mi kí wọn sì mú mi;
    jẹ́ kí òun kí ó tẹ ọkàn mi mọ́lẹ̀
    kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. Sela.

Dìde, Olúwa, nínú ìbínú rẹ;
    dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀tá mi.
    Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.
Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yíká.
    Jọba lórí wọn láti òkè wá;
    Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.
Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,
    gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.
(A)Ọlọ́run Olódodo,
    Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn,
tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburú
    tí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.

10 Ààbò mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run,
    ẹni tí ń ṣe ìgbàlà òtítọ́ ní àyà.
11 Ọlọ́run ni onídàájọ́ òtítọ́,
    Ọlọ́run tí ń sọ ìrunú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.
12 Bí kò bá yípadà,
    Òun yóò pọ́n idà rẹ̀ mú;
    ó ti fa ọrun rẹ̀ le ná, ó ti múra rẹ̀ sílẹ̀.
13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀;
    ó ti pèsè ọfà iná sílẹ̀.

14 Ẹni tí ó lóyún ohun búburú,
    tí ó sì lóyún wàhálà, ó bí èké jáde.
15 Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jáde
    jì sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.
16 Wàhálà tí ó fà padà sórí rẹ̀;
    Ìwà ipá rẹ̀ padà sórí ara rẹ̀.

17 Èmi ó fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí òdodo rẹ̀,
    Èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa Ọ̀gá-ògo jùlọ.

Psalm 7[a]

A shiggaion[b](A) of David, which he sang to the Lord concerning Cush, a Benjamite.

Lord my God, I take refuge(B) in you;
    save and deliver me(C) from all who pursue me,(D)
or they will tear me apart like a lion(E)
    and rip me to pieces with no one to rescue(F) me.

Lord my God, if I have done this
    and there is guilt on my hands(G)
if I have repaid my ally with evil
    or without cause(H) have robbed my foe—
then let my enemy pursue and overtake(I) me;
    let him trample my life to the ground(J)
    and make me sleep in the dust.[c](K)

Arise,(L) Lord, in your anger;
    rise up against the rage of my enemies.(M)
    Awake,(N) my God; decree justice.
Let the assembled peoples gather around you,
    while you sit enthroned over them on high.(O)
    Let the Lord judge(P) the peoples.
Vindicate me, Lord, according to my righteousness,(Q)
    according to my integrity,(R) O Most High.(S)
Bring to an end the violence of the wicked
    and make the righteous secure—(T)
you, the righteous God(U)
    who probes minds and hearts.(V)

10 My shield[d](W) is God Most High,
    who saves the upright in heart.(X)
11 God is a righteous judge,(Y)
    a God who displays his wrath(Z) every day.
12 If he does not relent,(AA)
    he[e] will sharpen his sword;(AB)
    he will bend and string his bow.(AC)
13 He has prepared his deadly weapons;
    he makes ready his flaming arrows.(AD)

14 Whoever is pregnant with evil
    conceives trouble and gives birth(AE) to disillusionment.
15 Whoever digs a hole and scoops it out
    falls into the pit(AF) they have made.(AG)
16 The trouble they cause recoils on them;
    their violence comes down on their own heads.

17 I will give thanks to the Lord because of his righteousness;(AH)
    I will sing the praises(AI) of the name of the Lord Most High.(AJ)

Footnotes

  1. Psalm 7:1 In Hebrew texts 7:1-17 is numbered 7:2-18.
  2. Psalm 7:1 Title: Probably a literary or musical term
  3. Psalm 7:5 The Hebrew has Selah (a word of uncertain meaning) here.
  4. Psalm 7:10 Or sovereign
  5. Psalm 7:12 Or If anyone does not repent, / God