Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi.

69 Gbà mí, Ọlọ́run,
    nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
Mo ń rì nínú irà jíjìn,
    níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé.
Mo ti wá sínú omi jíjìn;
    ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́;
    ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú,
nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
(A)Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí
    wọ́n ju irun orí mi; lọ
púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí,
    àwọn tí ń wá láti pa mí run
A fi ipá mú mi
    láti san ohun tí èmi kò jí.

Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run;
    ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.

Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ
    nítorí mi,
Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun;
    Má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi,
Ọlọ́run Israẹli.
Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn,
    ìtìjú sì bo ojú mi.
Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi;
    àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
(B)Nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run,
    àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10 Nígbà tí mo sọkún
    tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà
èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11 Nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà,
    àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
12 Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi,
    mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.

13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni
    ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa,
ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà
    Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ,
dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
14 Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀,
    Má ṣe jẹ́ kí n rì;
gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi,
    kúrò nínú ibú omi.
15 Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀
    bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì
kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.

16 Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ;
    nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
17 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ:
    yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
18 Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là;
    rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.

19 Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá;
    Gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
20 Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́
    Mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí,
    mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
21 Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi,
    àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.

22 Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn
    ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ
    fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
23 Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran,
    kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
24 (C)Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn;
    kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
25 (D)Kí ibùjókòó wọn di ahoro;
    kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
26 Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù,
    àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe
27 Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn;
    Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
28 (E)Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè
    kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.

29 Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí,
    Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.

30 Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga
    èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
31 Eléyìí tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ
    ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
32 Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀:
    Ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
33 Olúwa, gbọ́ ti aláìní,
    kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.

34 Kí ọ̀run àti ayé yìn ín,
    Òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
35 Nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là
    yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́.
Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀,
    kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní.
36 Àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀,
    àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.

Psalm 69[a]

For the director of music. To the tune of “Lilies.” Of David.

Save me, O God,
    for the waters(A) have come up to my neck.(B)
I sink in the miry depths,(C)
    where there is no foothold.
I have come into the deep waters;
    the floods engulf me.
I am worn out calling for help;(D)
    my throat is parched.
My eyes fail,(E)
    looking for my God.
Those who hate me(F) without reason(G)
    outnumber the hairs of my head;
many are my enemies without cause,(H)
    those who seek to destroy me.(I)
I am forced to restore
    what I did not steal.

You, God, know my folly;(J)
    my guilt is not hidden from you.(K)

Lord, the Lord Almighty,
    may those who hope in you
    not be disgraced because of me;
God of Israel,
    may those who seek you
    not be put to shame because of me.
For I endure scorn(L) for your sake,(M)
    and shame covers my face.(N)
I am a foreigner to my own family,
    a stranger to my own mother’s children;(O)
for zeal for your house consumes me,(P)
    and the insults of those who insult you fall on me.(Q)
10 When I weep and fast,(R)
    I must endure scorn;
11 when I put on sackcloth,(S)
    people make sport of me.
12 Those who sit at the gate(T) mock me,
    and I am the song of the drunkards.(U)

13 But I pray to you, Lord,
    in the time of your favor;(V)
in your great love,(W) O God,
    answer me with your sure salvation.
14 Rescue me from the mire,
    do not let me sink;
deliver me from those who hate me,
    from the deep waters.(X)
15 Do not let the floodwaters(Y) engulf me
    or the depths swallow me up(Z)
    or the pit close its mouth over me.(AA)

16 Answer me, Lord, out of the goodness of your love;(AB)
    in your great mercy turn to me.
17 Do not hide your face(AC) from your servant;
    answer me quickly,(AD) for I am in trouble.(AE)
18 Come near and rescue me;
    deliver(AF) me because of my foes.

19 You know how I am scorned,(AG) disgraced and shamed;
    all my enemies are before you.
20 Scorn has broken my heart
    and has left me helpless;
I looked for sympathy, but there was none,
    for comforters,(AH) but I found none.(AI)
21 They put gall in my food
    and gave me vinegar(AJ) for my thirst.(AK)

22 May the table set before them become a snare;
    may it become retribution and[b] a trap.(AL)
23 May their eyes be darkened so they cannot see,
    and their backs be bent forever.(AM)
24 Pour out your wrath(AN) on them;
    let your fierce anger overtake them.
25 May their place be deserted;(AO)
    let there be no one to dwell in their tents.(AP)
26 For they persecute those you wound
    and talk about the pain of those you hurt.(AQ)
27 Charge them with crime upon crime;(AR)
    do not let them share in your salvation.(AS)
28 May they be blotted out of the book of life(AT)
    and not be listed with the righteous.(AU)

29 But as for me, afflicted and in pain—
    may your salvation, God, protect me.(AV)

30 I will praise God’s name in song(AW)
    and glorify him(AX) with thanksgiving.
31 This will please the Lord more than an ox,
    more than a bull with its horns and hooves.(AY)
32 The poor will see and be glad(AZ)
    you who seek God, may your hearts live!(BA)
33 The Lord hears the needy(BB)
    and does not despise his captive people.

34 Let heaven and earth praise him,
    the seas and all that move in them,(BC)
35 for God will save Zion(BD)
    and rebuild the cities of Judah.(BE)
Then people will settle there and possess it;
36     the children of his servants will inherit it,(BF)
    and those who love his name will dwell there.(BG)

Footnotes

  1. Psalm 69:1 In Hebrew texts 69:1-36 is numbered 69:2-37.
  2. Psalm 69:22 Or snare / and their fellowship become