Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Orin. Saamu.

66 Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
    Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀;
    Ẹ kọrin ìyìnsí i,
Ẹ wí fún Ọlọ́run “pé,
    ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ!
    Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá
rẹ yóò fi sìn ọ́.
Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ;
    wọn ń kọrin ìyìn sí ọ,
    wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” Sela.

Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe,
    Iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
Ó yí Òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ,
    wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá,
    níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀,
    ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè
    kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. Sela.

Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn,
    jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa,
    kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò;
    ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n
    o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí
    àwa la iná àti omi kọjá
    ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.

13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun,
    kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ
14 Ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ
    nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ,
    àti ẹbọ ọ̀rá àgbò;
    èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. Sela.

16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run;
    ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i:
    Ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi,
    Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
19 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́
    ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run
    ẹni tí kò kọ àdúrà mi
    tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!

Psalm 66

For the director of music. A song. A psalm.

Shout for joy to God, all the earth!(A)
    Sing the glory of his name;(B)
    make his praise glorious.(C)
Say to God, “How awesome are your deeds!(D)
    So great is your power
    that your enemies cringe(E) before you.
All the earth bows down(F) to you;
    they sing praise(G) to you,
    they sing the praises of your name.”[a]

Come and see what God has done,
    his awesome deeds(H) for mankind!
He turned the sea into dry land,(I)
    they passed through(J) the waters on foot—
    come, let us rejoice(K) in him.
He rules forever(L) by his power,
    his eyes watch(M) the nations—
    let not the rebellious(N) rise up against him.

Praise(O) our God, all peoples,
    let the sound of his praise be heard;
he has preserved our lives(P)
    and kept our feet from slipping.(Q)
10 For you, God, tested(R) us;
    you refined us like silver.(S)
11 You brought us into prison(T)
    and laid burdens(U) on our backs.
12 You let people ride over our heads;(V)
    we went through fire and water,
    but you brought us to a place of abundance.(W)

13 I will come to your temple with burnt offerings(X)
    and fulfill my vows(Y) to you—
14 vows my lips promised and my mouth spoke
    when I was in trouble.
15 I will sacrifice fat animals to you
    and an offering of rams;
    I will offer bulls and goats.(Z)

16 Come and hear,(AA) all you who fear God;
    let me tell(AB) you what he has done for me.
17 I cried out to him with my mouth;
    his praise was on my tongue.
18 If I had cherished sin in my heart,
    the Lord would not have listened;(AC)
19 but God has surely listened
    and has heard(AD) my prayer.
20 Praise be to God,
    who has not rejected(AE) my prayer
    or withheld his love from me!

Footnotes

  1. Psalm 66:4 The Hebrew has Selah (a word of uncertain meaning) here and at the end of verses 7 and 15.