Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Nígbà ti wòlíì Natani tọ wá, lẹ́yìn tí Dafidi dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè rẹ̀ pẹ̀lú Batṣeba.

51 Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí
    ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ̀,
gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ àánú rẹ̀
    kí o sì pa gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.
Wẹ gbogbo àìṣedéédéé mi nù kúrò
    kí o sì wẹ̀ mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi!

Nítorí mo mọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi,
    nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi wà níwájú mi.
(A)Sí ọ, ìwọ nìkan ṣoṣo, ni mo dẹ́ṣẹ̀ sí
    ni mo sì ṣe búburú níwájú rẹ̀,
kí a lè dá ọ láre nígbà tí ìwọ bá ń sọ̀rọ̀,
    kí o sì le wà láìlẹ́bi, nígbà tí ìwọ bá ń ṣe ìdájọ́.
Nítòótọ́, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni a ti bí mi,
    nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mí sì lóyún mi.
Nítòótọ́ ìwọ fẹ́ òtítọ́ ní inú;
    ìwọ kọ́ mi ní ọgbọ́n ní ìhà ìkọ̀kọ̀.

Wẹ̀ mí pẹ̀lú ewé hísópù, èmi yóò sì mọ́;
    fọ̀ mí, èmi yóò sì funfun ju yìnyín lọ.
Jẹ́ kí n gbọ́ ayọ̀ àti inú dídùn;
    jẹ́ kí gbogbo egungun tí ìwọ ti run kí ó máa yọ̀.
Pa ojú rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi
    kí o sì pa gbogbo àwọn àìṣedéédéé mi rẹ́.

10 Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run,
    kí o sì tún ẹ̀mí dídúró ṣinṣin ṣe sínú mi.
11 Má ṣe jù mi nù kúrò níwájú rẹ,
    kí o má ṣe gba ẹ̀mí mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.
12 Mú ayọ̀ ìgbàlà rẹ tọ̀ mí wá,
    kí o sì fún mi ní ẹ̀mí ìfẹ́, tí yóò mú mi dúró.

13 Nígbà náà ni èmi yóò máa kọ́ àwọn olùrékọjá ní ọ̀nà rẹ,
    àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò sì yí padà sí ọ.
14 Gbà mí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀, Ọlọ́run,
    ìwọ Ọlọ́run ìgbàlà mi,
ahọ́n mi yóò sì máa kọrin òdodo rẹ kíkan.
15 Olúwa, ṣí mi ní ètè mi gbogbo,
    àti ẹnu mi yóò sì máa kéde ìyìn rẹ.
16 Nítorí ìwọ kò ní inú dídùn sí ẹbọ, tí èmi kò bá mú wá;
    Ìwọ kò ní inú dídùn sí ọrẹ ẹbọ sísun.
17 Ẹbọ Ọlọ́run ni ìròbìnújẹ́ ọkàn ìròbìnújẹ́ àti ìrora àyà.

18 Ṣe rere ní dídùn inú rẹ sí Sioni,
    ṣe rere; tún odi Jerusalẹmu mọ.
19 Nígbà náà ni inú rẹ yóò dùn sí ẹbọ òdodo,
    pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ọrẹ ẹbọ sísun,
    nígbà náà ni wọn yóò fi akọ màlúù rú ẹbọ lórí pẹpẹ rẹ.

Psalm 51[a]

For the director of music. A psalm of David. When the prophet Nathan came to him after David had committed adultery with Bathsheba.(A)

Have mercy(B) on me, O God,
    according to your unfailing love;(C)
according to your great compassion(D)
    blot out(E) my transgressions.(F)
Wash away(G) all my iniquity
    and cleanse(H) me from my sin.

For I know my transgressions,
    and my sin is always before me.(I)
Against you, you only, have I sinned(J)
    and done what is evil in your sight;(K)
so you are right in your verdict
    and justified when you judge.(L)
Surely I was sinful(M) at birth,(N)
    sinful from the time my mother conceived me.
Yet you desired faithfulness even in the womb;
    you taught me wisdom(O) in that secret place.(P)

Cleanse(Q) me with hyssop,(R) and I will be clean;
    wash me, and I will be whiter than snow.(S)
Let me hear joy and gladness;(T)
    let the bones(U) you have crushed rejoice.
Hide your face from my sins(V)
    and blot out(W) all my iniquity.

10 Create in me a pure heart,(X) O God,
    and renew a steadfast spirit within me.(Y)
11 Do not cast me(Z) from your presence(AA)
    or take your Holy Spirit(AB) from me.
12 Restore to me the joy of your salvation(AC)
    and grant me a willing spirit,(AD) to sustain me.(AE)

13 Then I will teach transgressors your ways,(AF)
    so that sinners(AG) will turn back to you.(AH)
14 Deliver me(AI) from the guilt of bloodshed,(AJ) O God,
    you who are God my Savior,(AK)
    and my tongue will sing of your righteousness.(AL)
15 Open my lips, Lord,(AM)
    and my mouth will declare your praise.
16 You do not delight in sacrifice,(AN) or I would bring it;
    you do not take pleasure in burnt offerings.
17 My sacrifice,(AO) O God, is[b] a broken spirit;
    a broken and contrite heart(AP)
    you, God, will not despise.

18 May it please you to prosper Zion,(AQ)
    to build up the walls of Jerusalem.(AR)
19 Then you will delight in the sacrifices of the righteous,(AS)
    in burnt offerings(AT) offered whole;
    then bulls(AU) will be offered on your altar.

Footnotes

  1. Psalm 51:1 In Hebrew texts 51:1-19 is numbered 51:3-21.
  2. Psalm 51:17 Or The sacrifices of God are