Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Ti Dafidi ìránṣẹ́ Olúwa tí ó kọ sí Olúwa, ọ̀rọ̀ orin tí ó kọ sí Olúwa fún ìdáǹdè kúrò lọ́wọ́ Saulu ọ̀tá rẹ̀. Ó wí pé

18 (A)Mo fẹ́ ọ, Olúwa, agbára mi.

Olúwa ni àpáta àti odi mi, àti olùgbàlà mi;
    Ọlọ́run mi ni àpáta mi, ẹni tí mo fi ṣe ibi ìsádi mi.
    Òun ni àpáta ààbò àti ìwo ìgbàlà mi àti ibi ìsádi mi.

Mo ké pe Olúwa, ẹni tí ìyìn yẹ fún,
    a ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi.
Ìrora ikú yí mi kà,
    àti ìṣàn omi àwọn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
Okùn isà òkú yí mi ká,
    ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí.

Nínú ìpọ́njú mo ké pe Olúwa;
    Mo sọkún sí Olúwa mi fún ìrànlọ́wọ́.
Láti inú tẹmpili rẹ̀, ó gbọ́ igbe mi;
    ẹkún mi wá sí iwájú rẹ̀, sí inú etí rẹ̀.
Ayé wárìrì, ó sì mì tìtì,
    ìpìlẹ̀ àwọn òkè gíga sì ṣídìí;
    wọ́n wárìrì nítorí tí ó ń bínú.
Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá;
    Iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá,
    ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
Ó pín àwọn ọ̀run, Ó sì jáde wá;
    àwọsánmọ̀ dúdú sì wà ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
10 Ó gun orí kérúbù, ó sì fò;
    ó ń rábàbà lórí ìyẹ́ apá afẹ́fẹ́.
11 Ó fi òkùnkùn ṣe ibojì rẹ̀, ó fi ṣe ìbòrí yí ara rẹ̀ ká
    kurukuru òjò dúdú ní ojú ọ̀run.
12 Nípa ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀, àwọsánmọ̀ ṣíṣú dudu rẹ kọjá lọ
    pẹ̀lú yìnyín àti ẹ̀yín iná
13 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá;
    Ọ̀gá-ògo sì fọ ohun rẹ̀; yìnyín àti ẹ̀yin iná.
14 Ó ta àwọn ọfà rẹ̀, ó sì tú àwọn ọ̀tá náà ká,
    ọfà mọ̀nàmọ́ná ńlá sì dà wọ́n rú.
15 A sì fi ìsàlẹ̀ àwọn Òkun hàn,
    a sì rí àwọn ìpìlẹ̀ ayé
nípa ìbáwí rẹ, Olúwa,
    nípa fífún èémí ihò imú rẹ.

16 Ó sọ̀kalẹ̀ láti ibi gíga, ó sì dì mímú;
    Ó fà mí jáde láti inú omi jíjìn.
17 Ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára,
    láti ọwọ́ àwọn ọ̀tá, ti ó lágbára jù fún mi.
18 Wọ́n dojúkọ mí ní ọjọ́ ìpọ́njú mi;
    ṣùgbọ́n Olúwa ni alátìlẹ́yìn mi.
19 Ó mú mi jáde wá sínú ibi ńlá;
    Ó gbà mí nítorí tí ó ní inú dídùn sí mi.

20 Olúwa ti hùwà sí mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;
    gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi, ó ti fi èrè fún mi
21 Nítorí mo ti pa ọ̀nà Olúwa mọ́;
    èmi kò ṣe búburú nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi
22 Gbogbo òfin rẹ̀ ni ó wà níwájú mi;
    èmi kò sì yípadà kúrò nínú ìlànà rẹ̀.
23 Mo ti jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú rẹ̀;
    mo sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
24 Olúwa san ẹ̀san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;
    gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi níwájú rẹ̀.

25 Fún olóòtítọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní olóòtítọ́,
    sí aláìlẹ́bi, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní aláìlẹ́bi,
26 Sí ọlọ́kàn mímọ́, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní ọlọ́kàn mímọ́,
    ṣùgbọ́n sí ọlọ́kàn-wíwọ́, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní òǹrorò.
27 O pa onírẹ̀lẹ̀ mọ́,
    ṣùgbọ́n ó rẹ àwọn ti ń gbéraga sílẹ̀.
28 Ìwọ, Olúwa, jẹ́ kí fìtílà mi
    kí ó máa tàn; Ọlọ́run mi, yí òkùnkùn mi padà sí ìmọ́lẹ̀.
29 Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ rẹ̀, èmi sáré tọ ogun lọ;
    pẹ̀lú Ọlọ́run mi mo lè fo odi kan.

30 Bí ó ṣe ti Ọlọ́run mi, ọ̀nà rẹ̀ pé,
    a ti rídìí ọ̀rọ̀ Olúwa
    òun ni àpáta ààbò fún gbogbo àwọn tí ó fi ṣe ààbò.
31 Nítorí ta ni ṣe Ọlọ́run bí kò ṣe Olúwa?
    Ta ní àpáta bí kò ṣe Olúwa wa?
32 Ọlọ́run ni ẹni tí ó fi agbára dì mí ní àmùrè
    ó sì mú ọ̀nà mi pé.
33 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi gẹ́gẹ́ bi ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín;
    ó jẹ́ ki n lè dúró lórí ibi gíga.
34 Ó kọ́ ọwọ́ mi ni ogun jíjà;
    apá mi lè tẹ ọrùn idẹ
35 Ìwọ fi asà ìṣẹ́gun rẹ̀ fún mi,
    ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ gbé mí dúró;
    àti ìwà pẹ̀lẹ́ rẹ̀ sọ mí di ńlá.
36 Ìwọ sọ ìrìn ẹsẹ̀ mi di ńlá ní ìsàlẹ̀ mi,
    kí kókó-ẹsẹ̀ mi má ṣe yẹ̀.

37 Èmi lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì bá wọn
    èmi kò sì padà lẹ́yìn wọn títí a fi run wọ́n.
38 Èmi sá wọn ní ọgbẹ́ tí wọn ko fi le è dìde;
    Wọ́n ṣubú ní abẹ́ ẹsẹ̀ mi.
39 Nítorí ìwọ fi agbára dì mí ní àmùrè fún ogun náà;
    ìwọ ti mú àwọn tí ó dìde si mí tẹríba ní abẹ́ ẹsẹ̀ mi
40 Ìwọ yí ẹ̀yìn àwọn ọ̀tá mí padà sí mi
    èmi sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
41 Wọ́n kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbà wọ́n,
    àní sí Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá wọn lóhùn.
42 Mo lù wọ́n gẹ́gẹ́ bí eruku níwájú afẹ́fẹ́;
    mo dà wọ́n síta gẹ́gẹ́ bí ẹrọ̀fọ̀.
43 Ìwọ ti gbà mí lọ́wọ́ ìkọlù àwọn ènìyàn;
    Ìwọ ti fi mí ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè.
Àwọn ènìyàn ti èmi kò mọ, yóò sì máa sìn mí,
44     ni wéré ti wọ́n gbọ́ ohùn mi, wọ́n pa àṣẹ mi mọ́;
    àwọn ọmọ àjèjì yóò tẹríba fún mi.
45 Àyà yóò pá àlejò;
    wọn yóò sì fi ìbẹ̀rù jáde láti ibi kọ́lọ́fín wọn.

46 Olúwa wà láààyè! Olùbùkún ni àpáta mi!
    Gbígbéga ní Ọlọ́run Olùgbàlà mi.
47 Òun ni Ọlọ́run tí ó ń gbẹ̀san mi,
    tí ó sì ń ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní abẹ́ mi,
48     tí ó pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mí.
Ìwọ gbé mi ga ju àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí mi lọ;
    lọ́wọ́ àwọn ènìyàn alágbára ni ìwọ ti gbà mí.
49 (B)Títí láéláé, èmi yóò máa yìn ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ Olúwa;
    Èmi yóò sì máa kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ.

50 Ó fún ọba rẹ̀ ni ìṣẹ́gun ńlá;
    ó fi ìkáàánú àìṣẹ̀tàn fún ẹni ààmì òróró rẹ̀,
    fún Dafidi àti ìran rẹ̀ títí láé.

Psalm 18[a](A)

For the director of music. Of David the servant of the Lord. He sang to the Lord the words of this song when the Lord delivered him from the hand of all his enemies and from the hand of Saul. He said:

I love you, Lord, my strength.(B)

The Lord is my rock,(C) my fortress(D) and my deliverer;(E)
    my God is my rock, in whom I take refuge,(F)
    my shield[b](G) and the horn[c] of my salvation,(H) my stronghold.

I called to the Lord, who is worthy of praise,(I)
    and I have been saved from my enemies.(J)
The cords of death(K) entangled me;
    the torrents(L) of destruction overwhelmed me.
The cords of the grave coiled around me;
    the snares of death(M) confronted me.

In my distress(N) I called to the Lord;(O)
    I cried to my God for help.
From his temple he heard my voice;(P)
    my cry came(Q) before him, into his ears.
The earth trembled(R) and quaked,(S)
    and the foundations of the mountains shook;(T)
    they trembled because he was angry.(U)
Smoke rose from his nostrils;(V)
    consuming fire(W) came from his mouth,
    burning coals(X) blazed out of it.
He parted the heavens and came down;(Y)
    dark clouds(Z) were under his feet.
10 He mounted the cherubim(AA) and flew;
    he soared(AB) on the wings of the wind.(AC)
11 He made darkness his covering,(AD) his canopy(AE) around him—
    the dark rain clouds of the sky.
12 Out of the brightness of his presence(AF) clouds advanced,
    with hailstones(AG) and bolts of lightning.(AH)
13 The Lord thundered(AI) from heaven;
    the voice of the Most High resounded.[d]
14 He shot his arrows(AJ) and scattered the enemy,
    with great bolts of lightning(AK) he routed them.(AL)
15 The valleys of the sea were exposed
    and the foundations(AM) of the earth laid bare
at your rebuke,(AN) Lord,
    at the blast of breath from your nostrils.(AO)

16 He reached down from on high and took hold of me;
    he drew me out of deep waters.(AP)
17 He rescued me from my powerful enemy,(AQ)
    from my foes, who were too strong for me.(AR)
18 They confronted me in the day of my disaster,(AS)
    but the Lord was my support.(AT)
19 He brought me out into a spacious place;(AU)
    he rescued me because he delighted in me.(AV)

20 The Lord has dealt with me according to my righteousness;(AW)
    according to the cleanness of my hands(AX) he has rewarded me.(AY)
21 For I have kept the ways of the Lord;(AZ)
    I am not guilty of turning(BA) from my God.
22 All his laws are before me;(BB)
    I have not turned away from his decrees.
23 I have been blameless(BC) before him
    and have kept myself from sin.
24 The Lord has rewarded me according to my righteousness,(BD)
    according to the cleanness of my hands in his sight.

25 To the faithful(BE) you show yourself faithful,(BF)
    to the blameless you show yourself blameless,
26 to the pure(BG) you show yourself pure,
    but to the devious you show yourself shrewd.(BH)
27 You save the humble(BI)
    but bring low those whose eyes are haughty.(BJ)
28 You, Lord, keep my lamp(BK) burning;
    my God turns my darkness into light.(BL)
29 With your help(BM) I can advance against a troop[e];
    with my God I can scale a wall.

30 As for God, his way is perfect:(BN)
    The Lord’s word is flawless;(BO)
    he shields(BP) all who take refuge(BQ) in him.
31 For who is God besides the Lord?(BR)
    And who is the Rock(BS) except our God?
32 It is God who arms me with strength(BT)
    and keeps my way secure.(BU)
33 He makes my feet like the feet of a deer;(BV)
    he causes me to stand on the heights.(BW)
34 He trains my hands for battle;(BX)
    my arms can bend a bow of bronze.
35 You make your saving help my shield,
    and your right hand sustains(BY) me;
    your help has made me great.
36 You provide a broad path(BZ) for my feet,
    so that my ankles do not give way.(CA)

37 I pursued my enemies(CB) and overtook them;
    I did not turn back till they were destroyed.
38 I crushed them(CC) so that they could not rise;(CD)
    they fell beneath my feet.(CE)
39 You armed me with strength(CF) for battle;
    you humbled my adversaries(CG) before me.
40 You made my enemies turn their backs(CH) in flight,
    and I destroyed(CI) my foes.
41 They cried for help, but there was no one to save them(CJ)
    to the Lord, but he did not answer.(CK)
42 I beat them as fine as windblown dust;(CL)
    I trampled them[f] like mud in the streets.
43 You have delivered me from the attacks of the people;
    you have made me the head of nations.(CM)
People I did not know(CN) now serve me,
44     foreigners(CO) cower before me;
    as soon as they hear of me, they obey me.
45 They all lose heart;(CP)
    they come trembling(CQ) from their strongholds.(CR)

46 The Lord lives!(CS) Praise be to my Rock!(CT)
    Exalted be God(CU) my Savior!(CV)
47 He is the God who avenges(CW) me,
    who subdues nations(CX) under me,
48     who saves(CY) me from my enemies.(CZ)
You exalted me above my foes;
    from a violent man(DA) you rescued me.
49 Therefore I will praise you, Lord, among the nations;(DB)
    I will sing(DC) the praises of your name.(DD)

50 He gives his king great victories;
    he shows unfailing love to his anointed,(DE)
    to David(DF) and to his descendants forever.(DG)

Footnotes

  1. Psalm 18:1 In Hebrew texts 18:1-50 is numbered 18:2-51.
  2. Psalm 18:2 Or sovereign
  3. Psalm 18:2 Horn here symbolizes strength.
  4. Psalm 18:13 Some Hebrew manuscripts and Septuagint (see also 2 Samuel 22:14); most Hebrew manuscripts resounded, / amid hailstones and bolts of lightning
  5. Psalm 18:29 Or can run through a barricade
  6. Psalm 18:42 Many Hebrew manuscripts, Septuagint, Syriac and Targum (see also 2 Samuel 22:43); Masoretic Text I poured them out