Add parallel Print Page Options

135 Ẹ yin Olúwa.

Ẹ yin orúkọ Olúwa;
    ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Olúwa.
Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa,
    nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.

Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun;
    ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn.
Nítorí tí Olúwa ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀;
    àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀.

Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi,
    àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.
Olúwa ṣe ohunkóhun tí ó wù ú,
    ní ọ̀run àti ní ayé,
    ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.
Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá:
    ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò:
    ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá.

Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti,
    àti ti ènìyàn àti ti ẹranko.
Ẹni tí ó rán iṣẹ́ ààmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti,
    sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.
10 Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀,
    tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.
11 Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu,
    ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani:
12 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,
    ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀.

13 Olúwa orúkọ rẹ dúró láéláé;
    ìrántí rẹ Olúwa, láti ìrandíran.
14 (A)Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀,
    yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.

15 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà,
    iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
16 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀;
    wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
17 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀;
bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn
18 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn:
    gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.

19 Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa,
    ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún Olúwa.
20 Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún Olúwa;
    ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, fi ìbùkún fún Olúwa.
21 Olùbùkún ni Olúwa, láti Sioni wá,
    tí ń gbé Jerusalẹmu.

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

Psalm 135(A)

Praise the Lord.[a]

Praise the name of the Lord;
    praise him, you servants(B) of the Lord,
you who minister in the house(C) of the Lord,
    in the courts(D) of the house of our God.

Praise the Lord, for the Lord is good;(E)
    sing praise to his name,(F) for that is pleasant.(G)
For the Lord has chosen Jacob(H) to be his own,
    Israel to be his treasured possession.(I)

I know that the Lord is great,(J)
    that our Lord is greater than all gods.(K)
The Lord does whatever pleases him,(L)
    in the heavens and on the earth,(M)
    in the seas and all their depths.
He makes clouds rise from the ends of the earth;
    he sends lightning with the rain(N)
    and brings out the wind(O) from his storehouses.(P)

He struck down the firstborn(Q) of Egypt,
    the firstborn of people and animals.
He sent his signs(R) and wonders into your midst, Egypt,
    against Pharaoh and all his servants.(S)
10 He struck down many(T) nations
    and killed mighty kings—
11 Sihon(U) king of the Amorites,(V)
    Og king of Bashan,(W)
    and all the kings of Canaan(X)
12 and he gave their land as an inheritance,(Y)
    an inheritance to his people Israel.

13 Your name, Lord, endures forever,(Z)
    your renown,(AA) Lord, through all generations.
14 For the Lord will vindicate his people(AB)
    and have compassion on his servants.(AC)

15 The idols of the nations(AD) are silver and gold,
    made by human hands.(AE)
16 They have mouths, but cannot speak,(AF)
    eyes, but cannot see.
17 They have ears, but cannot hear,
    nor is there breath(AG) in their mouths.
18 Those who make them will be like them,
    and so will all who trust in them.

19 All you Israelites, praise the Lord;(AH)
    house of Aaron, praise the Lord;
20 house of Levi, praise the Lord;
    you who fear him, praise the Lord.
21 Praise be to the Lord from Zion,(AI)
    to him who dwells in Jerusalem.(AJ)

Praise the Lord.

Footnotes

  1. Psalm 135:1 Hebrew Hallelu Yah; also in verses 3 and 21