Add parallel Print Page Options

116 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi;
    ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi,
    èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.

Okùn ikú yí mi ká,
    ìrora isà òkú wá sórí mi;
    ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi.
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa:
    Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”

Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo;
    Ọlọ́run wa kún fún àánú.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́
    nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.

Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ,
    nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.

Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi
    kúrò lọ́wọ́ ikú,
ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé,
    àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
Nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa
    ní ilẹ̀ alààyè.

10 (A)Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé,
    “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé
    “Èké ni gbogbo ènìyàn”.

12 Kí ni èmi yóò san fún Olúwa
    nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?

13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè
    èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa
    ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.

15 Iyebíye ní ojú Olúwa
    àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́;
    èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ;
    ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.

17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ
    èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa
18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa
    ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 Nínú àgbàlá ilé Olúwa
    ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu.

Ẹ yin Olúwa.

Psalm 116

I love the Lord,(A) for he heard my voice;
    he heard my cry(B) for mercy.(C)
Because he turned his ear(D) to me,
    I will call on him as long as I live.

The cords of death(E) entangled me,
    the anguish of the grave came over me;
    I was overcome by distress and sorrow.
Then I called on the name(F) of the Lord:
    Lord, save me!(G)

The Lord is gracious and righteous;(H)
    our God is full of compassion.(I)
The Lord protects the unwary;
    when I was brought low,(J) he saved me.(K)

Return to your rest,(L) my soul,
    for the Lord has been good(M) to you.

For you, Lord, have delivered me(N) from death,
    my eyes from tears,
    my feet from stumbling,
that I may walk before the Lord(O)
    in the land of the living.(P)

10 I trusted(Q) in the Lord when I said,
    “I am greatly afflicted”;(R)
11 in my alarm I said,
    “Everyone is a liar.”(S)

12 What shall I return to the Lord
    for all his goodness(T) to me?

13 I will lift up the cup of salvation
    and call on the name(U) of the Lord.
14 I will fulfill my vows(V) to the Lord
    in the presence of all his people.

15 Precious in the sight(W) of the Lord
    is the death of his faithful servants.(X)
16 Truly I am your servant, Lord;(Y)
    I serve you just as my mother did;(Z)
    you have freed me from my chains.(AA)

17 I will sacrifice a thank offering(AB) to you
    and call on the name of the Lord.
18 I will fulfill my vows(AC) to the Lord
    in the presence of all his people,
19 in the courts(AD) of the house of the Lord
    in your midst, Jerusalem.(AE)

Praise the Lord.[a]

Footnotes

  1. Psalm 116:19 Hebrew Hallelu Yah