Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Ti Dafidi.

11 Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa.
    Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé:
    “Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.
Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀;
    wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn
láti tafà níbi òjìji
    sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.
Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́
    kí ni olódodo yóò ṣe?”

Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀;
    Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run.
Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn;
    ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.
Olúwa ń yẹ olódodo wò,
    ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá
    ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.
Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò
    ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó;
    àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.

Nítorí, olódodo ní Olúwa,
    o fẹ́ràn òdodo;
    ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.

Psalm 11

For the director of music. Of David.

In the Lord I take refuge.(A)
    How then can you say to me:
    “Flee(B) like a bird to your mountain.(C)
For look, the wicked bend their bows;(D)
    they set their arrows(E) against the strings
to shoot from the shadows(F)
    at the upright in heart.(G)
When the foundations(H) are being destroyed,
    what can the righteous do?”

The Lord is in his holy temple;(I)
    the Lord is on his heavenly throne.(J)
He observes everyone on earth;(K)
    his eyes examine(L) them.
The Lord examines the righteous,(M)
    but the wicked, those who love violence,
    he hates with a passion.(N)
On the wicked he will rain
    fiery coals and burning sulfur;(O)
    a scorching wind(P) will be their lot.

For the Lord is righteous,(Q)
    he loves justice;(R)
    the upright(S) will see his face.(T)