Add parallel Print Page Options

ÌWÉ KARÙN-ÚN

Saamu 107–150

107 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun;
    nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.

Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn
    ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
Àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì
    láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn,
    láti àríwá àti Òkun wá.

Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí,
    wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí
    wọn ó máa gbé
Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n,
    ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè
    Olúwa nínú ìdààmú wọn,
ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú
    tí wọn lè máa gbé
Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́
    ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
Nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run
    ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.

10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú,
    a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
11 Nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀
    Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀;
    wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí
    yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe
    Olúwa nínú ìdààmú wọn,
    ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú
    òkùnkùn àti òjìji ikú,
    ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì
    ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.

17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn
    wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn
18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ
    wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú
    ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn
20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá
    ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́
    kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.

23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀
    ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa,
    àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú
25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́
    tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì
    tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú:
    nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi
27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn:
    ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè
    Olúwa nínú ìdààmú wọn,
    ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́
    bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́;
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀,
    ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ,
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún
    Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀
    àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn
    kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.

33 Ó sọ odò di aginjù,
    àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀
    nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀;
35 O sọ aginjù di adágún omi àti
    ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi
36 Níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà,
    wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé
37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà
    tí yóò máa so èso tí ó dára;
38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye
    kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.

39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú,
    ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù
40 Ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé
    ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí
41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira
    ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran
42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn
    ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.

43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí
    kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.

BOOK V

Psalms 107–150

Psalm 107

Give thanks to the Lord,(A) for he is good;(B)
    his love endures forever.

Let the redeemed(C) of the Lord tell their story—
    those he redeemed from the hand of the foe,
those he gathered(D) from the lands,
    from east and west, from north and south.[a]

Some wandered in desert(E) wastelands,
    finding no way to a city(F) where they could settle.
They were hungry(G) and thirsty,(H)
    and their lives ebbed away.
Then they cried out(I) to the Lord in their trouble,
    and he delivered them from their distress.
He led them by a straight way(J)
    to a city(K) where they could settle.
Let them give thanks(L) to the Lord for his unfailing love(M)
    and his wonderful deeds(N) for mankind,
for he satisfies(O) the thirsty
    and fills the hungry with good things.(P)

10 Some sat in darkness,(Q) in utter darkness,
    prisoners suffering(R) in iron chains,(S)
11 because they rebelled(T) against God’s commands
    and despised(U) the plans(V) of the Most High.
12 So he subjected them to bitter labor;
    they stumbled, and there was no one to help.(W)
13 Then they cried to the Lord in their trouble,
    and he saved them(X) from their distress.
14 He brought them out of darkness,(Y) the utter darkness,(Z)
    and broke away their chains.(AA)
15 Let them give thanks(AB) to the Lord for his unfailing love(AC)
    and his wonderful deeds(AD) for mankind,
16 for he breaks down gates of bronze
    and cuts through bars of iron.

17 Some became fools(AE) through their rebellious ways(AF)
    and suffered affliction(AG) because of their iniquities.
18 They loathed all food(AH)
    and drew near the gates of death.(AI)
19 Then they cried(AJ) to the Lord in their trouble,
    and he saved them(AK) from their distress.
20 He sent out his word(AL) and healed them;(AM)
    he rescued(AN) them from the grave.(AO)
21 Let them give thanks(AP) to the Lord for his unfailing love(AQ)
    and his wonderful deeds(AR) for mankind.
22 Let them sacrifice thank offerings(AS)
    and tell of his works(AT) with songs of joy.(AU)

23 Some went out on the sea(AV) in ships;(AW)
    they were merchants on the mighty waters.
24 They saw the works of the Lord,(AX)
    his wonderful deeds in the deep.
25 For he spoke(AY) and stirred up a tempest(AZ)
    that lifted high the waves.(BA)
26 They mounted up to the heavens and went down to the depths;
    in their peril(BB) their courage melted(BC) away.
27 They reeled(BD) and staggered like drunkards;
    they were at their wits’ end.
28 Then they cried(BE) out to the Lord in their trouble,
    and he brought them out of their distress.(BF)
29 He stilled the storm(BG) to a whisper;
    the waves(BH) of the sea[b] were hushed.(BI)
30 They were glad when it grew calm,
    and he guided them(BJ) to their desired haven.
31 Let them give thanks(BK) to the Lord for his unfailing love(BL)
    and his wonderful deeds(BM) for mankind.
32 Let them exalt(BN) him in the assembly(BO) of the people
    and praise him in the council of the elders.

33 He turned rivers into a desert,(BP)
    flowing springs(BQ) into thirsty ground,
34 and fruitful land into a salt waste,(BR)
    because of the wickedness of those who lived there.
35 He turned the desert into pools of water(BS)
    and the parched ground into flowing springs;(BT)
36 there he brought the hungry to live,
    and they founded a city where they could settle.
37 They sowed fields and planted vineyards(BU)
    that yielded a fruitful harvest;
38 he blessed them, and their numbers greatly increased,(BV)
    and he did not let their herds diminish.(BW)

39 Then their numbers decreased,(BX) and they were humbled(BY)
    by oppression, calamity and sorrow;
40 he who pours contempt on nobles(BZ)
    made them wander in a trackless waste.(CA)
41 But he lifted the needy(CB) out of their affliction
    and increased their families like flocks.(CC)
42 The upright see and rejoice,(CD)
    but all the wicked shut their mouths.(CE)

43 Let the one who is wise(CF) heed these things
    and ponder the loving deeds(CG) of the Lord.

Footnotes

  1. Psalm 107:3 Hebrew north and the sea
  2. Psalm 107:29 Dead Sea Scrolls; Masoretic Text / their waves