Add parallel Print Page Options

104 Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.

Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ tóbi jọjọ;
    ọlá àti ọláńlá ni ìwọ wọ̀ ní aṣọ.

Ìwọ fi ìmọ́lẹ̀ bo ara rẹ gẹ́gẹ́ bí aṣọ;
    ó tẹ ọ̀run bí títẹ́ ẹní
Ìwọ tí ó fi omi ṣe ìtì igi àjà ìyẹ̀wù rẹ.
    Ìwọ tí o ṣe àwọsánmọ̀ ní kẹ̀kẹ́ ogun rẹ
    ìwọ tí ó ń rìn lórí apá ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
(A)Ó fi ẹ̀fúùfù ṣe àwọn ìránṣẹ́ rẹ,
    Ọ̀wọ́-iná ni àwọn olùránṣẹ́ rẹ.

O fi ayé gúnlẹ̀ lórí àwọn ìpìlẹ̀;
    tí a kò le è mì láéláé.
Ìwọ fi ibú omi bò ó mọ́lẹ̀ bí aṣọ;
    àwọn omi sì dúró lórí àwọn òkè ńlá.
Ṣùgbọ́n nípa ìbáwí rẹ ni àwọn omi lọ,
    nípa ohùn àrá rẹ ni wọ́n sálọ;
Wọ́n sàn kọjá lórí àwọn òkè,
    wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀,
    sí ibi tí ìwọ ti yàn fún wọn.
Ìwọ gbé òpin tí wọn kò lè kọjá rẹ̀ kálẹ̀;
    láéláé ni wọ́n kò ní lè bo ayé mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.

10 Ìwọ mú kí ìsun da omi sí àwọn Àfonífojì;
    tí ó ń sàn láàrín àwọn òkè.
11 Wọ́n fún gbogbo àwọn ẹranko igbó ní omi
    àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ń pa òǹgbẹ wọn.
12 Àwọn ẹyẹ ojú òfúrufú tẹ́ ìtẹ́ wọn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi
    wọ́n ń kọrin láàrín àwọn ẹ̀ka.
13 Ó bu omi rin àwọn òkè láti ìyẹ̀wù rẹ̀ wá;
    a tẹ́ ayé lọ́rùn nípa èso iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
14 Ó mú kí koríko hù jáde fún àwọn ẹranko láti jẹ
    àti àwọn ewébẹ̀ fún ènìyàn láti lò
    kí ó lè mú oúnjẹ jáde láti ilẹ̀ wá:
15 Ọtí wáìnì tí ó ń mú ọkàn ènìyàn yọ̀,
    òróró láti mú ojú rẹ̀ tan,
    àti àkàrà láti ra ọkàn rẹ̀ padà.
16 Àwọn igi Olúwa ni a bu omi rin dáradára,
    kedari ti Lebanoni tí ó gbìn.
17 Níbẹ̀ ní àwọn ẹyẹ ṣe ìtẹ́ wọn
    bí ó ṣe tí àkọ̀ ni, orí igi gíga ni ilé rẹ̀.
18 Àwọn òkè gíga ni ààbò fún àwọn ewúrẹ́ igbó;
    àti àwọn àlàpà jẹ́ ààbò fún àwọn ehoro.

19 Òṣùpá jẹ́ ààmì fún àkókò
    oòrùn sì mọ ìgbà tí yóò wọ̀.
20 Ìwọ mú òkùnkùn wá, ó sì di òru,
    nínú èyí tí gbogbo ẹranko igbó ń rìn kiri.
21 Kìnnìún ń bú ramúramù fún ohun ọdẹ wọn
    wọ́n sì ń wá oúnjẹ wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
22 Oòrùn ràn, wọ́n sì kó ara wọn jọ,
    wọn padà lọ dùbúlẹ̀ sí ihò wọn.
23 Ọkùnrin jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,
    àti sí làálàá rẹ̀ títí di àṣálẹ́.

24 Iṣẹ́ rẹ ti pọ̀ tó, Olúwa!
    Nínú ọgbọ́n ni ìwọ ṣe gbogbo wọn:
    ayé kún fún àwọn ìṣẹ̀dá á rẹ.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Òkun yìí tí ó tóbi, tí ó sì ni ìbú,
    tí ó kún fún àwọn ẹ̀dá alààyè ní ìsàlẹ̀ láìníye
    ohun alààyè tí tóbi àti kékeré.
26 Níbẹ̀ ni ọkọ̀ ń lọ síwá sẹ́yìn,
    àti Lefitani, tí ìwọ dá láti ṣe àríyá nínú rẹ̀.

27 Àwọn wọ̀nyí ń wò ọ́
    láti fún wọn ní oúnjẹ wọn lákòókò rẹ̀.
28 Nígbà tí ìwọ bá fi fún wọn,
    wọn yóò kó jọ;
nígbà tí ìwọ bá la ọwọ́ rẹ̀,
    a tẹ́ wọn lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere.
29 Nígbà tí ìwọ bá pa ojú rẹ mọ́
    ara kò rọ̀ wọ́n
nígbà tí ìwọ bá mú ẹ̀mí wọn lọ,
    wọn ó kú, wọn ó sì padà sí erùpẹ̀.
30 Nígbà tí ìwọ rán ẹ̀mí rẹ,
    ni a dá wọn,
    ìwọ sì tún ojú ayé ṣe.

31 Jẹ́ kí ògo Olúwa wà pẹ́ títí láé;
    kí inú Olúwa kí ó dùn ní ti iṣẹ́ rẹ̀
32 Ẹni tí ó wo ayé, tí ó sì wárìrì,
    ẹni tí ó fọwọ́ tọ́ àwọn òkè, tí wọ́n yọ èéfín.

33 Ní gbogbo ayé mi ní n ó kọrin sí Olúwa:
    èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa
níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè.
34 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ mi kí ó tẹ́ ọ lọ́rùn
    bí mo ti ń yọ̀ nínú Olúwa.
35 Ṣùgbọ́n kí ẹlẹ́ṣẹ̀ kúrò láyé
    kí ènìyàn búburú má sì sí mọ́.

Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.

Yin Olúwa.

Psalm 104

Praise the Lord, my soul.(A)

Lord my God, you are very great;
    you are clothed with splendor and majesty.(B)

The Lord wraps(C) himself in light(D) as with a garment;
    he stretches(E) out the heavens(F) like a tent(G)
    and lays the beams(H) of his upper chambers on their waters.(I)
He makes the clouds(J) his chariot(K)
    and rides on the wings of the wind.(L)
He makes winds his messengers,[a](M)
    flames of fire(N) his servants.

He set the earth(O) on its foundations;(P)
    it can never be moved.
You covered it(Q) with the watery depths(R) as with a garment;
    the waters stood(S) above the mountains.
But at your rebuke(T) the waters fled,
    at the sound of your thunder(U) they took to flight;
they flowed over the mountains,
    they went down into the valleys,
    to the place you assigned(V) for them.
You set a boundary(W) they cannot cross;
    never again will they cover the earth.

10 He makes springs(X) pour water into the ravines;
    it flows between the mountains.
11 They give water(Y) to all the beasts of the field;
    the wild donkeys(Z) quench their thirst.
12 The birds of the sky(AA) nest by the waters;
    they sing among the branches.(AB)
13 He waters the mountains(AC) from his upper chambers;(AD)
    the land is satisfied by the fruit of his work.(AE)
14 He makes grass grow(AF) for the cattle,
    and plants for people to cultivate—
    bringing forth food(AG) from the earth:
15 wine(AH) that gladdens human hearts,
    oil(AI) to make their faces shine,
    and bread that sustains(AJ) their hearts.
16 The trees of the Lord(AK) are well watered,
    the cedars of Lebanon(AL) that he planted.
17 There the birds(AM) make their nests;
    the stork has its home in the junipers.
18 The high mountains belong to the wild goats;(AN)
    the crags are a refuge for the hyrax.(AO)

19 He made the moon to mark the seasons,(AP)
    and the sun(AQ) knows when to go down.
20 You bring darkness,(AR) it becomes night,(AS)
    and all the beasts of the forest(AT) prowl.
21 The lions roar for their prey(AU)
    and seek their food from God.(AV)
22 The sun rises, and they steal away;
    they return and lie down in their dens.(AW)
23 Then people go out to their work,(AX)
    to their labor until evening.(AY)

24 How many are your works,(AZ) Lord!
    In wisdom you made(BA) them all;
    the earth is full of your creatures.(BB)
25 There is the sea,(BC) vast and spacious,
    teeming with creatures beyond number—
    living things both large and small.(BD)
26 There the ships(BE) go to and fro,
    and Leviathan,(BF) which you formed to frolic(BG) there.(BH)

27 All creatures look to you
    to give them their food(BI) at the proper time.
28 When you give it to them,
    they gather it up;
when you open your hand,
    they are satisfied(BJ) with good things.
29 When you hide your face,(BK)
    they are terrified;
when you take away their breath,
    they die and return to the dust.(BL)
30 When you send your Spirit,(BM)
    they are created,
    and you renew the face of the ground.

31 May the glory of the Lord(BN) endure forever;
    may the Lord rejoice in his works(BO)
32 he who looks at the earth, and it trembles,(BP)
    who touches the mountains,(BQ) and they smoke.(BR)

33 I will sing(BS) to the Lord all my life;
    I will sing praise to my God as long as I live.
34 May my meditation be pleasing to him,
    as I rejoice(BT) in the Lord.
35 But may sinners vanish(BU) from the earth
    and the wicked be no more.(BV)

Praise the Lord, my soul.

Praise the Lord.[b](BW)

Footnotes

  1. Psalm 104:4 Or angels
  2. Psalm 104:35 Hebrew Hallelu Yah; in the Septuagint this line stands at the beginning of Psalm 105.