Add parallel Print Page Options

Àdúrà olùpọ́njú tí àárẹ̀ mú, tí ó sí ọkàn rẹ̀ payá níwájú Olúwa

102 Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa:
    Jẹ́ kí igbe ẹ̀bẹ̀ mi kí ó wá sí ọ̀dọ̀ rẹ
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi
    ní ọjọ́ tí èmi wà nínú ìpọ́njú.
Dẹ etí rẹ sí mi;
    nígbà tí mo bá pè, dá mi lóhùn kíákíá.

Nítorí tí ọjọ́ mi run bí èéfín;
    egungun mi sì jóná bí ààrò
Àyà mi lù, ó sì rọ bí i koríko;
    mo gbàgbé láti jẹ oúnjẹ mi.
Nítorí ohùn ìkérora mi,
    egungun mi lẹ̀ mọ́ ẹran-ara mi.
Èmi dàbí ẹyẹ igún ní ijù:
    èmi dàbí òwìwí ibi ahoro.
Èmi dìde; èmi dàbí ẹyẹ lórí ilé.
Ní ọjọ́ gbogbo, àwọn ọ̀tá ológoṣẹ́ mi ń gàn mí;
    àwọn tí ń ṣe ìkanra sí mi ń fi orúkọ mi bú.
Èmi jẹ eérú gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ mi, èmi sì da ohun mímu mi pọ̀ pẹ̀lú omijé.
10 Nítorí ìbínú ríru rẹ, nítorí ìwọ ti gbé mi sókè, ìwọ sì gbé mi ṣánlẹ̀.
11 Ọjọ́ mi dàbí òjìji àṣálẹ́
    èmi sì rọ bí koríko.

12 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, ni yóò dúró láéláé;
    ìrántí rẹ láti ìran dé ìran.
13 Ìwọ ó dìde ìwọ ó sì ṣàánú fún Sioni,
    nítorí ìgbà àti ṣe ojúrere sí i;
    àkókò náà ti dé.
14 Nítorí tí àwọn òkúta jẹ́ inú dídùn sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ;
    wọ́n sì káàánú erùpẹ̀ rẹ.
15 Àwọn kèfèrí yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa,
    gbogbo ọba ayé yóò máa bẹ̀rù ògo rẹ.
16 Torí tí Olúwa yóò gbé Sioni ró, yóò farahàn nínú ògo rẹ̀.
17 Yóò dáhùn àdúrà àwọn aláìní;
    kì yóò sì gan ẹ̀bẹ̀ wọn.

18 Jẹ́ kí a kọ èyí fún ìran tí ń bọ̀,
    àwọn ènìyàn tí a kò tí ì dá yóò yin Olúwa:
19 Olúwa wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ rẹ̀ wá
    láti ọ̀run wá ni ó bojú wo ayé,
20 Láti gbọ́ ìrora ará túbú, láti tú
    àwọn tí a yàn sí ikú sílẹ̀.”
21 Kí a lè sọ orúkọ Olúwa ní Sioni
    àti ìyìn rẹ̀ ní Jerusalẹmu.
22 Ní ìgbà tí a kó àwọn ènìyàn àti
    ìjọba pọ̀ láti máa sìn Olúwa.

23 Ní ipa ọ̀nà mi, ó rẹ agbára mi sílẹ̀,
    ó gé ọjọ́ mi kúrú.
24 Èmi sì wí pé;
    “Ọlọ́run mi, má ṣe mú mi kúrò ní agbede-méjì ọjọ́ mi; ọdún rẹ̀ ń lọ láti ìran dé ìran.
25 (A)Ní ìbẹ̀rẹ̀ ní ìwọ fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀,
    ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
26 Wọn yóò ṣègbé, wọn yóò parun, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà;
    gbogbo wọn ni yóò gbó bí aṣọ.
Bí ẹ̀wù ni ìwọ yóò pààrọ̀ wọn
    wọn yóò sì di àpatì.
27 Ṣùgbọ́n ìwọ wà digbí síbẹ̀,
    ọdún rẹ kò sì ní òpin.
28 Àwọn ọmọ ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò dúró ní iwájú rẹ pẹ́;
    a ó sì fi ẹsẹ̀ irú-ọmọ wọn sọlẹ̀ ní iwájú rẹ.”

Psalm 102[a]

A prayer of an afflicted person who has grown weak and pours out a lament before the Lord.

Hear my prayer,(A) Lord;
    let my cry for help(B) come to you.
Do not hide your face(C) from me
    when I am in distress.
Turn your ear(D) to me;
    when I call, answer me quickly.

For my days vanish like smoke;(E)
    my bones(F) burn like glowing embers.
My heart is blighted and withered like grass;(G)
    I forget to eat my food.(H)
In my distress I groan aloud(I)
    and am reduced to skin and bones.
I am like a desert owl,(J)
    like an owl among the ruins.
I lie awake;(K) I have become
    like a bird alone(L) on a roof.
All day long my enemies(M) taunt me;(N)
    those who rail against me use my name as a curse.(O)
For I eat ashes(P) as my food
    and mingle my drink with tears(Q)
10 because of your great wrath,(R)
    for you have taken me up and thrown me aside.
11 My days are like the evening shadow;(S)
    I wither(T) away like grass.

12 But you, Lord, sit enthroned forever;(U)
    your renown endures(V) through all generations.(W)
13 You will arise(X) and have compassion(Y) on Zion,
    for it is time(Z) to show favor(AA) to her;
    the appointed time(AB) has come.
14 For her stones are dear to your servants;
    her very dust moves them to pity.
15 The nations will fear(AC) the name of the Lord,
    all the kings(AD) of the earth will revere your glory.
16 For the Lord will rebuild Zion(AE)
    and appear in his glory.(AF)
17 He will respond to the prayer(AG) of the destitute;
    he will not despise their plea.

18 Let this be written(AH) for a future generation,
    that a people not yet created(AI) may praise the Lord:
19 “The Lord looked down(AJ) from his sanctuary on high,
    from heaven he viewed the earth,
20 to hear the groans of the prisoners(AK)
    and release those condemned to death.”
21 So the name of the Lord will be declared(AL) in Zion
    and his praise(AM) in Jerusalem
22 when the peoples and the kingdoms
    assemble to worship(AN) the Lord.

23 In the course of my life[b] he broke my strength;
    he cut short my days.(AO)
24 So I said:
“Do not take me away, my God, in the midst of my days;
    your years go on(AP) through all generations.
25 In the beginning(AQ) you laid the foundations of the earth,
    and the heavens(AR) are the work of your hands.(AS)
26 They will perish,(AT) but you remain;
    they will all wear out like a garment.
Like clothing you will change them
    and they will be discarded.
27 But you remain the same,(AU)
    and your years will never end.(AV)
28 The children of your servants(AW) will live in your presence;
    their descendants(AX) will be established before you.”

Footnotes

  1. Psalm 102:1 In Hebrew texts 102:1-28 is numbered 102:2-29.
  2. Psalm 102:23 Or By his power