Add parallel Print Page Options

Ìṣòtítọ́ Ọlọ́run

Ǹjẹ́ àǹfààní wo ní Júù ní? Tàbí kín ni èrè ilà kíkọ? (A)Púpọ̀ lọ́nà gbogbo; pàtàkì jùlọ ni pé àwọn ni a fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lé lọ́wọ́.

Ǹjẹ́ kí ha ni bí àwọn kan jẹ́ aláìgbàgbọ́? Àìgbàgbọ́ wọn yóò ha sọ òtítọ́ Ọlọ́run di asán bí? (B)Kí a má rí! Kí Ọlọ́run jẹ́ olóòtítọ́, àti olúkúlùkù ènìyàn jẹ́ èké; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé:

“Kí a lè dá ọ láre nínú ọ̀rọ̀ rẹ,
    ṣùgbọ́n kí ìwọ lè borí nígbà tí ìwọ bá wá sí ìdájọ́.”

(C)Ṣùgbọ́n bí àìṣòdodo wa bá fi òdodo Ọlọ́run hàn, kín ni àwa ó wí? Ọlọ́run ha jẹ́ àìṣòdodo bí? Nígbà tí ó bá ń fi ìbínú rẹ̀ hàn (Mo fi ṣe àkàwé bí ènìyàn). Kí a má rí i. Bí bẹ́ẹ̀ bá ni, Ọlọ́run yóò ha ṣe lè dájọ́ aráyé? Nítorí bí òtítọ́ Ọlọ́run bá di púpọ̀ sí ìyìn rẹ̀ nítorí èké mi, èéṣe tí a fi ń dá mi lẹ́jọ́ bí ẹlẹ́ṣẹ̀? (D)Èéṣe tí a kò fi ṣe búburú kí rere lè jáde wá? Bí àwọn kan tí ń fi ẹnu àtẹ́ sọ wí pé a ń sọ bẹ́ẹ̀; ti àwọn kan sì ń tẹnumọ́ ọn pé a sọ; àwọn ẹni tí ìdálẹ́bi wọn tọ́.

Kò sí olóòtítọ́ kan

(E)Ǹjẹ́ kí ha ni? Àwa ha sàn ju wọn lọ bí? Kò rí bẹ́ẹ̀ rárá: nítorí a fihàn ṣáájú pé àti àwọn Júù àti àwọn Giriki, gbogbo wọn ni ó wà lábẹ́ ẹ̀ṣẹ̀; 10 (F)Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé:

“Kò sí ẹni tí í ṣe olódodo, kò sí ẹnìkan
11     Kò sí ẹni tí òye yé,
    kò sí ẹni tí ó ń wá Ọlọ́run.
12 Gbogbo wọn ni ó ti yapa,
    wọ́n jùmọ̀ di aláìlérè;
kò sí ẹni tí ń ṣe rere,
    kò tilẹ̀ sí ẹnìkan.”
13 (G)“Ibojì tí ó ṣí sílẹ̀ ní ọ̀fun wọn:
    ahọ́n wọn n sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.”
“Oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ lábẹ́ ètè wọn.”
14     (H)“Ẹnu ẹni tí ó kún fún èpè àti fún oró kíkorò.”
15 (I)“Ẹsẹ̀ wọn yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀:
16     ìparun àti ìpọ́njú wà lọ́nà wọn.
17 Ọ̀nà àlàáfíà ni wọn kò sì mọ̀:”
18     (J)“Ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí níwájú wọn.”

19 (K)Àwa sì mọ̀ pé ohunkóhun tí òfin bá wí, ó ń wí fún àwọn tí ó wà lábẹ́ òfin: kí gbogbo ẹnu bá à lè dákẹ́ àti kí a lè mú gbogbo aráyé wá sábẹ́ ìdájọ́ Ọlọ́run. 20 (L)Nítorí pé nípa iṣẹ́ òfin, a kì yóò dá ẹnikẹ́ni láre níwájú rẹ̀: nítorí nípa òfin ni ìmọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ ti wá.

Ìṣòdodo nípa ìgbàgbọ́

21 (M)Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, a ti fi òdodo Ọlọ́run hàn láìsí òfin, tí a ti ń jẹ́rìí sí nípa òfin àti nípa àwọn wòlíì; 22 (N)Àní òdodo Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ nínú Jesu Kristi, sí gbogbo ènìyàn àti gbogbo àwọn tí ó gbàgbọ́: nítorí tí kò sí ìyàtọ̀ láàrín Júù àti Helleni. 23 (O)Gbogbo ènìyàn ni ó ṣá ti ṣẹ̀, tí wọ́n sì kùnà ògo Ọlọ́run: 24 (P)Àwọn ẹni tí a ń dá láre lọ́fẹ̀ẹ́ nípa oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀, nípa ìdáǹdè tí ó wà nínú Kristi Jesu: 25 Ẹni tí Ọlọ́run ti gbé kalẹ̀ láti jẹ́ ètùtù nípa ìgbàgbọ́ nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, láti fi òdodo rẹ̀ hàn nítorí ìdáríjì àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti kọjá, nínú ìpamọ́ra Ọlọ́run: 26 (Q)Láti fi òdodo rẹ̀ hàn ní ìgbà ìsinsin yìí: kí ó lè jẹ́ olódodo àti olùdáláre ẹni tí ó gba Jesu gbọ́.

27 Ọ̀nà ìṣògo dà? A ti mú un kúrò. Nípa òfin wo? Nípa iṣẹ́? Bẹ́ẹ̀ kọ́: Ṣùgbọ́n nípa òfin ìgbàgbọ́. 28 (R)Nítorí náà a parí rẹ̀ sí pé nípa ìgbàgbọ́ ni a ń dá ènìyàn láre láìsí iṣẹ́ òfin. 29 (S)Ọlọ́run àwọn Júù nìkan ha ni bí? Kì í ha ṣe ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú? Bẹ́ẹ̀ ni, ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú: 30 (T)Bí ó ti jẹ́ pé Ọlọ́run kan ni, yóò dá àwọn akọlà láre nípa Ìgbàgbọ́ àti àwọn aláìkọlà nípa ìgbàgbọ́ wọn. 31 (U)Àwa ha ń sọ òfin dasán nípa ìgbàgbọ́ bí? Kí a má rí i: ṣùgbọ́n a ń fi òfin múlẹ̀.

God’s Faithfulness

What advantage, then, is there in being a Jew, or what value is there in circumcision? Much in every way!(A) First of all, the Jews have been entrusted with the very words of God.(B)

What if some were unfaithful?(C) Will their unfaithfulness nullify God’s faithfulness?(D) Not at all! Let God be true,(E) and every human being a liar.(F) As it is written:

“So that you may be proved right when you speak
    and prevail when you judge.”[a](G)

But if our unrighteousness brings out God’s righteousness more clearly,(H) what shall we say? That God is unjust in bringing his wrath on us? (I am using a human argument.)(I) Certainly not! If that were so, how could God judge the world?(J) Someone might argue, “If my falsehood enhances God’s truthfulness and so increases his glory,(K) why am I still condemned as a sinner?”(L) Why not say—as some slanderously claim that we say—“Let us do evil that good may result”?(M) Their condemnation is just!

No One Is Righteous

What shall we conclude then? Do we have any advantage?(N) Not at all! For we have already made the charge that Jews and Gentiles alike are all under the power of sin.(O) 10 As it is written:

“There is no one righteous, not even one;
11     there is no one who understands;
    there is no one who seeks God.
12 All have turned away,
    they have together become worthless;
there is no one who does good,
    not even one.”[b](P)
13 “Their throats are open graves;
    their tongues practice deceit.”[c](Q)
“The poison of vipers is on their lips.”[d](R)
14     “Their mouths are full of cursing and bitterness.”[e](S)
15 “Their feet are swift to shed blood;
16     ruin and misery mark their ways,
17 and the way of peace they do not know.”[f](T)
18     “There is no fear of God before their eyes.”[g](U)

19 Now we know that whatever the law says,(V) it says to those who are under the law,(W) so that every mouth may be silenced(X) and the whole world held accountable to God.(Y) 20 Therefore no one will be declared righteous in God’s sight by the works of the law;(Z) rather, through the law we become conscious of our sin.(AA)

Righteousness Through Faith

21 But now apart from the law the righteousness of God(AB) has been made known, to which the Law and the Prophets testify.(AC) 22 This righteousness(AD) is given through faith(AE) in[h] Jesus Christ(AF) to all who believe.(AG) There is no difference between Jew and Gentile,(AH) 23 for all have sinned(AI) and fall short of the glory of God, 24 and all are justified(AJ) freely by his grace(AK) through the redemption(AL) that came by Christ Jesus. 25 God presented Christ as a sacrifice of atonement,[i](AM) through the shedding of his blood(AN)—to be received by faith. He did this to demonstrate his righteousness, because in his forbearance he had left the sins committed beforehand unpunished(AO) 26 he did it to demonstrate his righteousness at the present time, so as to be just and the one who justifies those who have faith in Jesus.

27 Where, then, is boasting?(AP) It is excluded. Because of what law? The law that requires works? No, because of the law that requires faith. 28 For we maintain that a person is justified by faith apart from the works of the law.(AQ) 29 Or is God the God of Jews only? Is he not the God of Gentiles too? Yes, of Gentiles too,(AR) 30 since there is only one God, who will justify the circumcised by faith and the uncircumcised through that same faith.(AS) 31 Do we, then, nullify the law by this faith? Not at all! Rather, we uphold the law.

Footnotes

  1. Romans 3:4 Psalm 51:4
  2. Romans 3:12 Psalms 14:1-3; 53:1-3; Eccles. 7:20
  3. Romans 3:13 Psalm 5:9
  4. Romans 3:13 Psalm 140:3
  5. Romans 3:14 Psalm 10:7 (see Septuagint)
  6. Romans 3:17 Isaiah 59:7,8
  7. Romans 3:18 Psalm 36:1
  8. Romans 3:22 Or through the faithfulness of
  9. Romans 3:25 The Greek for sacrifice of atonement refers to the atonement cover on the ark of the covenant (see Lev. 16:15,16).