Add parallel Print Page Options

Tola

10 Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé. Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.

Jairi

Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún. Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní. Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.

Jefta

Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́, ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà. Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjì-dínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi). Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára. 10 Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”

11 Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini, 12 àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn? 13 Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́. 14 Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”

15 Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ nání àsìkò yìí.” 16 Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.

17 Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa. 18 Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”

Tola

10 After the time of Abimelek,(A) a man of Issachar(B) named Tola son of Puah,(C) the son of Dodo, rose to save(D) Israel. He lived in Shamir,(E) in the hill country of Ephraim. He led[a] Israel twenty-three years; then he died, and was buried in Shamir.

Jair

He was followed by Jair(F) of Gilead, who led Israel twenty-two years. He had thirty sons, who rode thirty donkeys.(G) They controlled thirty towns in Gilead, which to this day are called Havvoth Jair.[b](H) When Jair(I) died, he was buried in Kamon.

Jephthah

Again the Israelites did evil in the eyes of the Lord.(J) They served the Baals and the Ashtoreths,(K) and the gods of Aram,(L) the gods of Sidon,(M) the gods of Moab, the gods of the Ammonites(N) and the gods of the Philistines.(O) And because the Israelites forsook the Lord(P) and no longer served him, he became angry(Q) with them. He sold them(R) into the hands of the Philistines and the Ammonites, who that year shattered and crushed them. For eighteen years they oppressed all the Israelites on the east side of the Jordan in Gilead,(S) the land of the Amorites. The Ammonites also crossed the Jordan to fight against Judah,(T) Benjamin and Ephraim;(U) Israel was in great distress. 10 Then the Israelites cried(V) out to the Lord, “We have sinned(W) against you, forsaking our God and serving the Baals.”(X)

11 The Lord replied, “When the Egyptians,(Y) the Amorites,(Z) the Ammonites,(AA) the Philistines,(AB) 12 the Sidonians, the Amalekites(AC) and the Maonites[c](AD) oppressed you(AE) and you cried to me for help, did I not save you from their hands? 13 But you have forsaken(AF) me and served other gods,(AG) so I will no longer save you. 14 Go and cry out to the gods you have chosen. Let them save(AH) you when you are in trouble!(AI)

15 But the Israelites said to the Lord, “We have sinned. Do with us whatever you think best,(AJ) but please rescue us now.” 16 Then they got rid of the foreign gods among them and served the Lord.(AK) And he could bear Israel’s misery(AL) no longer.(AM)

17 When the Ammonites were called to arms and camped in Gilead, the Israelites assembled and camped at Mizpah.(AN) 18 The leaders of the people of Gilead said to each other, “Whoever will take the lead in attacking the Ammonites will be head(AO) over all who live in Gilead.”

Footnotes

  1. Judges 10:2 Traditionally judged; also in verse 3
  2. Judges 10:4 Or called the settlements of Jair
  3. Judges 10:12 Hebrew; some Septuagint manuscripts Midianites