Add parallel Print Page Options

Àsè ìpè

29 (A)“ ‘Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù keje, kí ẹ ní àpéjọ mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Ọjọ́ ìfùnpè ni ó jẹ́ fún yín. Gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa, ẹ pèsè ẹgbọrọ akọ màlúù kan, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan aláìlábùkù, kí ẹ fi ẹbọ sísun. Pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ wọn, ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi òróró pò, ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá òṣùwọ̀n fún akọ màlúù kan, àti ìdá méjì nínú mẹ́wàá, òṣùwọ̀n fún àgbò kan, àti ìdámẹ́wàá òṣùwọ̀n fún ọ̀dọ́-àgùntàn kan, àti fún ọ̀dọ́-àgùntàn méje. Àti òbúkọ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣètùtù fún yín. Pẹ̀lú ẹbọ sísun oṣù àti ẹbọ ohun jíjẹ rẹ̀ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo àti ẹbọ mímu wọn gẹ́gẹ́ bí ìlànà wọn. Fún òórùn dídùn, ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.

Ọjọ́ ẹbọ ètùtù

(B)“ ‘Ní ọjọ́ kẹwàá nínú oṣù keje, kí ẹ ṣe àpéjọ mímọ́. Kí ẹ̀yin kí ó sẹ́ ara yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Kí ẹ̀yin kí ó rú ẹbọ sísun olóòórùn dídùn sí Olúwa, ẹgbọrọ akọ màlúù kan, àgbò kan, àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kan, kí wọn kí ó sì jẹ́ aláìlábùkù fún yín. Pẹ̀lú akọ màlúù, pèsè ọrẹ ìdámẹ́wàá mẹ́ta, òṣùwọ̀n ìyẹ̀fun tí a fi òróró pò àti ìdámẹ́wàá méjì òṣùwọ̀n fún àgbò kan, 10 àti fún ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan, ìdámẹ́wàá òṣùwọ̀n. 11 Pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ètùtù àti ẹbọ sísun gbogbo ìgbà àti ẹbọ jíjẹ rẹ̀ àti ẹbọ mímu wọn.

Àpèjẹ Àgọ́

12 (C)“ ‘Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje, kí ẹ̀yin kí ó ní àpéjọ mímọ́, ẹ̀yin kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Kí ẹ̀yin kí ó sì ṣe àjọyọ̀ fún Olúwa fún ọjọ́ méje. 13 Kí ẹ sì rú ẹbọ sísun kan, ẹbọ tí a fi iná ṣe, tí ó ní òórùn dídùn sí Olúwa, ẹbọ tí ẹgbọrọ akọ màlúù mẹ́tàlá, àgbò méjì àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rìnlá tí ó jẹ́ ọdún kan, tí gbogbo rẹ̀ sì jẹ́ aláìlábùkù. 14 Àti ẹbọ ohun jíjẹ wọn, ìyẹ̀fun tí a fi òróró pò, ìdámẹ́wàá mẹ́ta òṣùwọ̀n fún akọ màlúù kan, bẹ́ẹ̀ ni fún akọ màlúù mẹ́tẹ̀ẹ̀tàlá, ìdámẹ́wàá méjì òṣùwọ̀n fún àgbò kan, bẹ́ẹ̀ ni fún àgbò méjèèjì, 15 àti fún ọ̀kọ̀ọ̀kan ọ̀dọ́-àgùntàn kan. Bẹ́ẹ̀ ni fún ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rẹ̀ẹ̀rìnlá. 16 Àti akọ ewúrẹ́ kan gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu rẹ̀.

17 “ ‘Àti ní ọjọ́ kejì ni kí ẹ̀yin kí ó fi ẹgbọrọ akọ màlúù méjìlá, àgbò méjì àti ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rìnlá ọlọ́dún kan aláìlábùkù rú ẹbọ. 18 Pẹ̀lú fún akọ màlúù, fún àgbò, àti fún ọ̀dọ́-àgùntàn kí ẹ pe ẹbọ ohun jíjẹ, àti ẹbọ ohun mímu, kí ó jẹ́ bí iye wọn, gẹ́gẹ́ bí ìlànà. 19 Àti òbúkọ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà pẹ̀lú ẹbọ jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.

20 “ ‘Ní ọjọ́ kẹta, pèsè akọ màlúù mọ́kànlá, àgbò méjì, akọ àgùntàn mẹ́rìnlá ti ọdún kan tí kò ní àbùkù. 21 Pẹ̀lú akọ màlúù, àgbò, àti akọ àgùntàn, pèsè ọrẹ ohun jíjẹ àti ohun mímu gẹ́gẹ́ bí iye wọn. 22 Pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo pẹ̀lú ẹbọ jíjẹ àti ẹbọ mímu.

23 “ ‘Ní ọjọ́ kẹrin, pèsè akọ màlúù mẹ́wàá, àgbò méjì, àti ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rìnlá ti ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan tí kò ní àbùkù. 24 Àti akọ màlúù, àgbò àti àgùntàn, pèsè ẹbọ jíjẹ àti ẹbọ mímu gẹ́gẹ́ bí iye wọn, gẹ́gẹ́ bí ìlànà. 25 Àti akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà, pẹ̀lú ẹbọ jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.

26 “ ‘Àti ní ọjọ́ karùn-ún, pèsè akọ màlúù mẹ́sàn-án, àgbò méjì àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rìnlá ti ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan, tí gbogbo rẹ̀ kò ní àbùkù. 27 Pẹ̀lú akọ màlúù, àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, pèsè ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí iye wọn sí ìlànà. 28 Àti akọ ewúrẹ́ kan gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun ìgbà gbogbo pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.

29 “ ‘Ní ọjọ́ kẹfà, pèsè akọ màlúù mẹ́jọ, àgbò ọlọ́dún kan tí gbogbo rẹ̀ kò ní àbùkù. 30 Pẹ̀lú akọ màlúù, àgbò, àti ọ̀dọ́-àgùntàn, pèsè ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí iye wọn. 31 Pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ kan gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.

32 “ ‘Àti ní ọjọ́ keje, pèsè akọ màlúù méje, àgbò méjì, àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rìnlá ti ọlọ́dún kan, tí gbogbo rẹ̀ kò sì ní àbùkù. 33 Pẹ̀lú akọ màlúù, àgbò, àti ọ̀dọ́-àgùntàn, pèsè ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu fún wọn gẹ́gẹ́ bí iye wọn. 34 Pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà, pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.

35 (D)“ ‘Àti ní ọjọ́ kẹjọ kí ẹ̀yin kó ní àpéjọ, kí ẹ má sì ṣe iṣẹ́ kankan. 36 Kí ẹ̀yin ṣe ìgbékalẹ̀ ẹbọ tí a fi iná ṣe tí ó ní òórùn dídùn sí Olúwa, ẹbọ sísun ti akọ màlúù kan, àgbò ọlọ́dún kan àti ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan méje, gbogbo rẹ̀ tí kò ní àbùkù. 37 Pẹ̀lú akọ màlúù, àgbò, àti ọ̀dọ́-àgùntàn, pèsè fún wọn ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí iye wọn. 38 Àti akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà àti ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.

39 “ ‘Pẹ̀lú ẹ̀jẹ́ yín, àti ẹbọ àtinúwá yín, kí ẹ̀yin kí o pèsè fún Olúwa ní àjọ̀dún tí a yàn yín, ẹbọ sísun, ẹbọ ohun jíjẹ, ẹbọ ohun mímu àti ẹbọ ìkẹ́gbẹ́ yín.’ ”

40 Mose sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli gbogbo ohun tí Olúwa ti pàṣẹ fún un.

The Festival of Trumpets(A)

29 “‘On the first day of the seventh month hold a sacred assembly and do no regular work.(B) It is a day for you to sound the trumpets. As an aroma pleasing to the Lord,(C) offer a burnt offering(D) of one young bull, one ram and seven male lambs a year old,(E) all without defect.(F) With the bull offer a grain offering(G) of three-tenths of an ephah[a] of the finest flour mixed with olive oil; with the ram, two-tenths[b]; and with each of the seven lambs, one-tenth.[c](H) Include one male goat(I) as a sin offering[d] to make atonement for you. These are in addition to the monthly(J) and daily burnt offerings(K) with their grain offerings(L) and drink offerings(M) as specified. They are food offerings presented to the Lord, a pleasing aroma.(N)

The Day of Atonement(O)

“‘On the tenth day of this seventh month hold a sacred assembly. You must deny yourselves[e](P) and do no work.(Q) Present as an aroma pleasing to the Lord a burnt offering of one young bull, one ram and seven male lambs a year old, all without defect.(R) With the bull offer a grain offering(S) of three-tenths of an ephah of the finest flour mixed with oil; with the ram, two-tenths;(T) 10 and with each of the seven lambs, one-tenth.(U) 11 Include one male goat(V) as a sin offering, in addition to the sin offering for atonement and the regular burnt offering(W) with its grain offering, and their drink offerings.(X)

The Festival of Tabernacles(Y)

12 “‘On the fifteenth day of the seventh(Z) month,(AA) hold a sacred assembly and do no regular work. Celebrate a festival to the Lord for seven days. 13 Present as an aroma pleasing to the Lord(AB) a food offering consisting of a burnt offering of thirteen young bulls, two rams and fourteen male lambs a year old, all without defect.(AC) 14 With each of the thirteen bulls offer a grain offering(AD) of three-tenths of an ephah of the finest flour mixed with oil; with each of the two rams, two-tenths; 15 and with each of the fourteen lambs, one-tenth.(AE) 16 Include one male goat as a sin offering,(AF) in addition to the regular burnt offering with its grain offering and drink offering.(AG)

17 “‘On the second day(AH) offer twelve young bulls, two rams and fourteen male lambs a year old, all without defect.(AI) 18 With the bulls, rams and lambs, offer their grain offerings(AJ) and drink offerings(AK) according to the number specified.(AL) 19 Include one male goat as a sin offering,(AM) in addition to the regular burnt offering(AN) with its grain offering, and their drink offerings.(AO)

20 “‘On the third day offer eleven bulls, two rams and fourteen male lambs a year old, all without defect.(AP) 21 With the bulls, rams and lambs, offer their grain offerings and drink offerings according to the number specified.(AQ) 22 Include one male goat as a sin offering, in addition to the regular burnt offering with its grain offering and drink offering.

23 “‘On the fourth day offer ten bulls, two rams and fourteen male lambs a year old, all without defect. 24 With the bulls, rams and lambs, offer their grain offerings and drink offerings according to the number specified. 25 Include one male goat as a sin offering, in addition to the regular burnt offering with its grain offering and drink offering.

26 “‘On the fifth day offer nine bulls, two rams and fourteen male lambs a year old, all without defect. 27 With the bulls, rams and lambs, offer their grain offerings and drink offerings according to the number specified. 28 Include one male goat as a sin offering, in addition to the regular burnt offering with its grain offering and drink offering.

29 “‘On the sixth day offer eight bulls, two rams and fourteen male lambs a year old, all without defect. 30 With the bulls, rams and lambs, offer their grain offerings and drink offerings according to the number specified. 31 Include one male goat as a sin offering, in addition to the regular burnt offering with its grain offering and drink offering.

32 “‘On the seventh day offer seven bulls, two rams and fourteen male lambs a year old, all without defect. 33 With the bulls, rams and lambs, offer their grain offerings and drink offerings according to the number specified. 34 Include one male goat as a sin offering, in addition to the regular burnt offering with its grain offering and drink offering.

35 “‘On the eighth day hold a closing special assembly(AR) and do no regular work. 36 Present as an aroma pleasing to the Lord(AS) a food offering consisting of a burnt offering of one bull, one ram and seven male lambs a year old,(AT) all without defect. 37 With the bull, the ram and the lambs, offer their grain offerings and drink offerings according to the number specified. 38 Include one male goat as a sin offering, in addition to the regular burnt offering with its grain offering and drink offering.

39 “‘In addition to what you vow(AU) and your freewill offerings,(AV) offer these to the Lord at your appointed festivals:(AW) your burnt offerings,(AX) grain offerings, drink offerings and fellowship offerings.(AY)’”

40 Moses told the Israelites all that the Lord commanded him.[f]

Footnotes

  1. Numbers 29:3 That is, probably about 11 pounds or about 5 kilograms; also in verses 9 and 14
  2. Numbers 29:3 That is, probably about 7 pounds or about 3.2 kilograms; also in verses 9 and 14
  3. Numbers 29:4 That is, probably about 3 1/2 pounds or about 1.6 kilograms; also in verses 10 and 15
  4. Numbers 29:5 Or purification offering; also elsewhere in this chapter
  5. Numbers 29:7 Or must fast
  6. Numbers 29:40 In Hebrew texts this verse (29:40) is numbered 30:1.