Add parallel Print Page Options

Ọmọbìnrin Ṣelofehadi

27 (A)Ọmọbìnrin Ṣelofehadi ọmọ Heferi, ọmọ Gileadi, ọmọ Makiri ọmọ Manase tó jẹ́ ìdílé Manase, ọmọ Josẹfu wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Mahila, Noa, Hogla, Milka àti Tirsa. Wọ́n súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mose, àti Eleasari àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé, “Baba wa kú sí aginjù. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kora tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, Ṣùgbọ́n ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀. Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítorí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrín àwọn arákùnrin baba wa.”

Nígbà náà Mose mú ọ̀rọ̀ wọn wá síwájú Olúwa. Olúwa sì wí fún un pé, “Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Ṣelofehadi ń sọ tọ̀nà. Ogbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.

“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀. Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀. 10 Tí kò bá ní arákùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀. 11 Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.’ ”

Joṣua láti rọ́pò Mose

12 (B)Nígbà náà Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sì orí òkè Abarimu yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Israẹli. 13 Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Aaroni arákùnrin rẹ ṣe ṣe, 14 nítorí nígbà tí ìlú ṣọ̀tẹ̀ níbi omi ní Aginjù Sini, tí gbogbo yín ṣe àìgbọ́ràn sí mi láti yà mí sí mímọ́ níwájú wọn.” (Èyí ni omi Meriba ní Kadeṣi ní aginjù Sini.)

15 Mose sọ fún Olúwa wí pé, 16 “Jẹ́ kí Olúwa, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, kí ó yan ọkùnrin kan sí orí ìjọ ènìyàn yìí 17 Láti máa darí wọn, ẹni tí yóò mú wọn jáde, tí yóò sì mú wọn wọlé, gbogbo ènìyàn Olúwa kí yóò dàbí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.”

18 (C)Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú Joṣua ọmọ Nuni, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e. 19 Jẹ́ kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Israẹli kí o sì fi àṣẹ fún un ní ojú wọn. 20 Kí ìwọ kí ó sì fi nínú ọláńlá rẹ sí i lára, kí gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kí ó lè gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu. 21 Kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Urimu níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”

22 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Joṣua ó sì mú kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ. 23 (D)Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

Zelophehad’s Daughters(A)

27 The daughters of Zelophehad(B) son of Hepher,(C) the son of Gilead,(D) the son of Makir,(E) the son of Manasseh, belonged to the clans of Manasseh son of Joseph. The names of the daughters were Mahlah, Noah, Hoglah, Milkah and Tirzah. They came forward and stood before Moses,(F) Eleazar the priest, the leaders(G) and the whole assembly at the entrance to the tent of meeting(H) and said, “Our father died in the wilderness.(I) He was not among Korah’s followers, who banded together against the Lord,(J) but he died for his own sin and left no sons.(K) Why should our father’s name disappear from his clan because he had no son? Give us property among our father’s relatives.”

So Moses brought their case(L) before the Lord,(M) and the Lord said to him, “What Zelophehad’s daughters are saying is right. You must certainly give them property as an inheritance(N) among their father’s relatives and give their father’s inheritance to them.(O)

“Say to the Israelites, ‘If a man dies and leaves no son, give his inheritance to his daughter. If he has no daughter, give his inheritance to his brothers. 10 If he has no brothers, give his inheritance to his father’s brothers. 11 If his father had no brothers, give his inheritance to the nearest relative in his clan, that he may possess it. This is to have the force of law(P) for the Israelites, as the Lord commanded Moses.’”

Joshua to Succeed Moses

12 Then the Lord said to Moses, “Go up this mountain(Q) in the Abarim Range(R) and see the land(S) I have given the Israelites.(T) 13 After you have seen it, you too will be gathered to your people,(U) as your brother Aaron(V) was, 14 for when the community rebelled at the waters in the Desert of Zin,(W) both of you disobeyed my command to honor me as holy(X) before their eyes.” (These were the waters of Meribah(Y) Kadesh, in the Desert of Zin.)

15 Moses said to the Lord, 16 “May the Lord, the God who gives breath to all living things,(Z) appoint someone over this community 17 to go out and come in before them, one who will lead them out and bring them in, so the Lord’s people will not be like sheep without a shepherd.”(AA)

18 So the Lord said to Moses, “Take Joshua son of Nun, a man in whom is the spirit of leadership,[a](AB) and lay your hand on him.(AC) 19 Have him stand before Eleazar the priest and the entire assembly and commission him(AD) in their presence.(AE) 20 Give him some of your authority so the whole Israelite community will obey him.(AF) 21 He is to stand before Eleazar the priest, who will obtain decisions for him by inquiring(AG) of the Urim(AH) before the Lord. At his command he and the entire community of the Israelites will go out, and at his command they will come in.”

22 Moses did as the Lord commanded him. He took Joshua and had him stand before Eleazar the priest and the whole assembly. 23 Then he laid his hands on him and commissioned him,(AI) as the Lord instructed through Moses.

Footnotes

  1. Numbers 27:18 Or the Spirit