Add parallel Print Page Options

Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ àkọ́kọ́ Balaamu

23 Balaamu wí fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ méje fún mi níbí, kí o sì mú akọ màlúù méje àti àgbò méje wá fún mi.” Balaki ṣe bí Balaamu ti sọ, àwọn méjèèjì fi akọ màlúù kọ̀ọ̀kan àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.

Nígbà náà Balaamu sọ fún Balaki pé, “Dúró ti ẹbọ sísun rẹ kí èmi sì lọ sí ẹ̀gbẹ́ kan. Bóyá Olúwa yóò farahàn mí. Ohunkóhun tí ó bá fihàn mí, èmi yóò wí fún ọ.” Nígbà náà ó sì lọ sí ibi gíga.

Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀, Balaamu sì sọ pé, “Mo tí ṣe pẹpẹ méje, lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan mo ti fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ.”

Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ sí ẹnu Balaamu ó wí pé, “Padà sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jẹ́ iṣẹ́ yìí fún un.”

Ó sì padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì ba tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè Moabu. Nígbà náà ni Balaamu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ jáde wí pé:

“Balaki mú mi láti Aramu wá,
    Ọba Moabu láti òkè ìlà-oòrùn wá
Ó wí pé, ‘Wá fi Jakọbu bú fún mi;
    wá, kí o sì jẹ́rìí sí Israẹli.’
Báwo ní èmi ó ṣe fi bú
    àwọn tí Ọlọ́run kò fi bú?
Báwo ni èmi ó ṣe bá wọn wí
    àwọn tí Olúwa kò bá wí?
Láti ṣóńṣó ibi gíga orí àpáta ni mo ti rí wọn,
    láti orí ibi gíga ni mo ti ń wò wọ́n.
Mo rí àwọn ènìyàn tí ń gbé lọ́tọ̀
    wọn kò sì ka ará wọn kún ara àwọn orílẹ̀-èdè.
10 Ta ni ó lè ka eruku Jakọbu
    tàbí ka ìdámẹ́rin Israẹli?
Jẹ́ kí èmi kú ikú olódodo,
    kí ìgbẹ̀yìn mi kí ó dà bí tirẹ̀!”

11 Balaki sọ fún Balaamu pé, “Kí lo ṣe fún mi? Mo gbé ọ wá láti fi àwọn ọ̀tá mi bú, Ṣùgbọ́n o kò ṣe nǹkan kan Ṣùgbọ́n o bùkún wọn!”

12 Ó sì dáhùn wí pé, “Ṣé kí n má sọ nǹkan tí Olúwa fi sí mi lẹ́nu?”

Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ èkejì Balaamu

13 Nígbà náà Balaki sọ fún un pé, “Wá pẹ̀lú mi sí ibòmíràn tí o ti lè rí wọn; wà á rí díẹ̀ Ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo wọn. Láti ibẹ̀, wá fi wọ́n bú fún mi.” 14 Ó sì lọ sí pápá Ṣofimu ní orí òkè Pisga, ó sì kọ́ pẹpẹ méje síbẹ̀ ó sì fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.

15 Balaamu ṣo fún Balaki pé, “Dúró níbí ti ẹbọ sísun rẹ nígbà tí mo bá lọ pàdé rẹ̀ níbẹ̀.”

16 Olúwa pàdé Balaamu ó sì fi ọ̀rọ̀ sí ní ẹnu wí pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jíṣẹ́ fún un.”

17 Nígbà náà ó lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì bá à tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu. Balaki sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni Olúwa wí?”

18 Nígbà náà ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ:

“Dìde, Balaki;
    kí o sì gbọ́ mi ọmọ Sippori.
19 Ọlọ́run kì í ṣe ènìyàn, tí yóò fi purọ́,
    tàbí ọmọ ènìyàn, tí ó lè yí ọkàn rẹ̀ padà.
Ǹjẹ́ ó sọ̀rọ̀ kí ó má ṣe é?
    Ǹjẹ́ ó ti ṣèlérí kí ó má mu un ṣẹ?
20 Èmi gba àṣẹ láti bùkún;
    Ó sì ti bùkún, èmi kò sì lè yípadà.

21 “Kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan nínú Jakọbu,
    kò sì rí búburú kankan nínú Israẹli.
Olúwa Ọlọ́run wọn sì wà pẹ̀lú wọn.
    Ìhó ọba sì wà pẹ̀lú wọn.
22 Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá,
    wọ́n ní agbára màlúù ẹhànnà.
23 Kò ní àfọ̀ṣẹ sí Jakọbu,
    tàbí àfọ̀ṣẹ sí àwọn Israẹli.
Nísinsin yìí a ó sọ nípa ti Jakọbu
    àti Israẹli, ‘Wo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe!’
24 Àwọn ènìyàn náà yóò dìde bí abo kìnnìún;
    wọ́n yóò sì gbé ara wọn sókè bí i kìnnìún
òun kì yóò sì dùbúlẹ̀ títí yóò fi jẹ ohun ọdẹ
    títí yóò sì fi mu nínú ẹ̀jẹ̀ ohun pípa.”

25 Nígbà náà ni Balaki wí fún Balaamu pé, “O kò kúkú fi wọ́n bú, bẹ́ẹ̀ ni o kò súre fún wọn rárá!”

26 Balaamu dáhùn ó sì wí fún Balaki pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ha ti wí fún ọ pé, gbogbo èyí tí Olúwa bá sọ, òun ni èmi yóò ṣe?”

Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ẹ̀kẹta Balaamu

27 Nígbà náà Balaki sọ fún Balaamu pé, “Wá jẹ́ kí èmi kí ó mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá yóò tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn kí ó fi wọ́n bú láti ibẹ̀ lọ.” 28 Balaki gbé Balaamu wá sí orí òkè Peori, tí ó kọjú sí aginjù.

29 Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Mọ pẹpẹ méje fún mi níbí kí o sì pèsè akọ màlúù àti àgbò fún mi.” 30 Balaki sì ṣe bí Balaamu ti sọ fún un, ó sì gbé akọ màlúù kan àti àgbò lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.

Balaam’s First Message

23 Balaam said, “Build me seven altars here, and prepare seven bulls and seven rams(A) for me.” Balak did as Balaam said, and the two of them offered a bull and a ram on each altar.(B)

Then Balaam said to Balak, “Stay here beside your offering while I go aside. Perhaps the Lord will come to meet with me.(C) Whatever he reveals to me I will tell you.” Then he went off to a barren height.

God met with him,(D) and Balaam said, “I have prepared seven altars, and on each altar I have offered a bull and a ram.”

The Lord put a word in Balaam’s mouth(E) and said, “Go back to Balak and give him this word.”(F)

So he went back to him and found him standing beside his offering, with all the Moabite officials.(G) Then Balaam(H) spoke his message:(I)

“Balak brought me from Aram,(J)
    the king of Moab from the eastern mountains.(K)
‘Come,’ he said, ‘curse Jacob for me;
    come, denounce Israel.’(L)
How can I curse
    those whom God has not cursed?(M)
How can I denounce
    those whom the Lord has not denounced?(N)
From the rocky peaks I see them,
    from the heights I view them.(O)
I see a people who live apart
    and do not consider themselves one of the nations.(P)
10 Who can count the dust of Jacob(Q)
    or number even a fourth of Israel?
Let me die the death of the righteous,(R)
    and may my final end be like theirs!(S)

11 Balak said to Balaam, “What have you done to me? I brought you to curse my enemies,(T) but you have done nothing but bless them!”(U)

12 He answered, “Must I not speak what the Lord puts in my mouth?”(V)

Balaam’s Second Message

13 Then Balak said to him, “Come with me to another place(W) where you can see them; you will not see them all but only the outskirts of their camp.(X) And from there, curse them for me.(Y) 14 So he took him to the field of Zophim on the top of Pisgah,(Z) and there he built seven altars and offered a bull and a ram on each altar.(AA)

15 Balaam said to Balak, “Stay here beside your offering while I meet with him over there.”

16 The Lord met with Balaam and put a word in his mouth(AB) and said, “Go back to Balak and give him this word.”

17 So he went to him and found him standing beside his offering, with the Moabite officials.(AC) Balak asked him, “What did the Lord say?”

18 Then he spoke his message:(AD)

“Arise, Balak, and listen;
    hear me, son of Zippor.(AE)
19 God is not human,(AF) that he should lie,(AG)
    not a human being, that he should change his mind.(AH)
Does he speak and then not act?
    Does he promise(AI) and not fulfill?
20 I have received a command to bless;(AJ)
    he has blessed,(AK) and I cannot change it.(AL)

21 “No misfortune is seen in Jacob,(AM)
    no misery observed[a] in Israel.(AN)
The Lord their God is with them;(AO)
    the shout of the King(AP) is among them.
22 God brought them out of Egypt;(AQ)
    they have the strength of a wild ox.(AR)
23 There is no divination against[b] Jacob,
    no evil omens(AS) against[c] Israel.
It will now be said of Jacob
    and of Israel, ‘See what God has done!’
24 The people rise like a lioness;(AT)
    they rouse themselves like a lion(AU)
that does not rest till it devours its prey
    and drinks the blood(AV) of its victims.”

25 Then Balak said to Balaam, “Neither curse them at all nor bless them at all!”

26 Balaam answered, “Did I not tell you I must do whatever the Lord says?”(AW)

Balaam’s Third Message

27 Then Balak said to Balaam, “Come, let me take you to another place.(AX) Perhaps it will please God to let you curse them for me(AY) from there.” 28 And Balak took Balaam to the top of Peor,(AZ) overlooking the wasteland.

29 Balaam said, “Build me seven altars here, and prepare seven bulls and seven rams for me.” 30 Balak did as Balaam had said, and offered a bull and a ram on each altar.(BA)

Footnotes

  1. Numbers 23:21 Or He has not looked on Jacob’s offenses / or on the wrongs found
  2. Numbers 23:23 Or in
  3. Numbers 23:23 Or in