Add parallel Print Page Options

A fi Ninefe bú

Ègbé ni fún ìlú ẹ̀jẹ̀ nì,
    gbogbo rẹ̀ kún fún èké,
ó kún fún olè,
    ìjẹ kò kúrò!
Ariwo pàṣán àti ariwo
    kíkùn kẹ̀kẹ́ ogun
àti jíjó ẹṣin
    àti gbígbọn kẹ̀kẹ́ ogun jìgìjìgì!
Ológun orí ẹṣin ń fi ìgbónára
    ju idà wọn mọ̀nàmọ́ná
    ọ̀kọ̀ rẹ̀ ti ń dán yanran sí òkè!
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ si ní àwọn ẹni tí a pa,
    àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òkú;
òkú kò sì ni òpin;
    àwọn ènìyàn sì ń kọsẹ̀ lára àwọn òkú.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ panṣágà
    àgbèrè tí ó rójú rere gbà,
Ìyá àjẹ́ tí ó ṣọ́ àwọn orílẹ̀-èdè di ẹrú
    nípa àgbèrè rẹ̀
    àti àwọn ìdílé nípa ìṣe àjẹ́ rẹ̀.

“Èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
    “Èmi ó si ká aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ ní ojú rẹ,
Èmi yóò sì fi ìhòhò rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdè
    àti ìtìjú rẹ̀ han àwọn ilẹ̀ ọba.
Èmi yóò da ẹ̀gbin tí ó ni ìríra sí ọ ní ara,
    èmi yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́,
    èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹlẹ́yà.
Gbogbo àwọn tí ó ba sì wò ọ́ yóò sì káàánú fún ọ, wọn yóò sì wí pé,
    ‘Ninefe ṣòfò: Ta ni yóò kẹ́dùn rẹ?’
    Níbo ni èmi o ti wá olùtùnú fún ọ?”

Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Tebesi lọ,
    èyí tí ó wà ní ibi odò, Naili
    tí omi sì yí káàkiri?
Odò náà sì jẹ́ ààbò rẹ̀,
    omi si jẹ́ odi rẹ̀.
Etiopia àti Ejibiti ni agbára rẹ, kò sí ní òpin;
    Puti àti Libia ni àwọn olùgbèjà rẹ̀.
10 Síbẹ̀síbẹ̀ a kó o ní ìgbèkùn
    o sì lọ sí oko ẹrú.
Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ̀ ni a ó fọ́ mọ́lẹ̀
    ní orí ìta gbogbo ìgboro.
Wọ́n sì di ìbò nítorí àwọn ọlọ́lá rẹ̀ ọkùnrin,
    gbogbo àwọn ọlọ́lá rẹ ni a sì fi ẹ̀wọ̀n dè
11 Ìwọ pẹ̀lú yóò sì mu àmupara;
    a ó sì fi ọ́ pamọ́
    ìwọ pẹ̀lú yóò máa ṣe àfẹ́rí ààbò nítorí ti ọ̀tá náà.

12 Gbogbo ilé ìṣọ́ agbára rẹ yóò dàbí igi ọ̀pọ̀tọ́
    pẹ̀lú àkọ́pọ́n èso wọn;
Nígbà tí wọ́n bá ń gbọ̀n wọ́n,
    ọ̀pọ̀tọ́ yóò sì bọ́ sí ẹnu àwọn ọ̀jẹun.
13 Kíyèsi gbogbo àwọn jagunjagun!
    Obìnrin ni gbogbo wọn.
Ojú ibodè rẹ ní a ó ṣí sílẹ̀ gbagada,
    fún àwọn ọ̀tá rẹ;
    iná yóò jó ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn ibodè rẹ.

14 Pọn omi nítorí ìhámọ́,
    mú ilé ìṣọ́ rẹ lágbára sí i
wọ inú amọ̀
    kí o sì tẹ erùpẹ̀,
    kí ó sì tún ibi tí a ti ń sun bíríkì-amọ̀ ṣe kí ó le.
15 Níbẹ̀ ni iná yóò ti jó ọ́ run;
    idà yóò sì ké ọ kúrò,
    yóò sì jẹ ọ́ bí i kòkòrò,
yóò sì sọ ara rẹ̀ di púpọ̀ bí i tata,
    àní, di púpọ̀ bí eṣú!
16 Ìwọ ti sọ àwọn oníṣòwò rẹ di púpọ̀
    títí wọn yóò fi pọ̀ ju ìràwọ̀ ojú ọ̀run lọ
Ṣùgbọ́n bi eṣú ni wọn yóò sọ ilẹ̀ náà di ahoro, wọn yóò sì fò lọ.
17 Àwọn aládé rẹ̀ dàbí eṣú,
    àwọn ọ̀gágun rẹ dàbí ẹlẹ́ǹgà ńlá,
    èyí tí ń dó sínú ọgbà ni ọjọ́ òtútù,
ṣùgbọ́n nígbà tí oòrùn jáde, wọ́n sálọ
    ẹnìkan kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé wà.

18 Ìwọ ọba Asiria,
    àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ ń tòògbé;
àwọn ọlọ́lá rẹ dùbúlẹ̀ láti sinmi.
    Àwọn ènìyàn rẹ fọ́nká lórí àwọn òkè ńlá,
    tí ẹnikẹ́ni kò sì kó wọn jọ.
19 Kò sì sí ohun tí ó lè wo ọgbẹ́ ẹ̀ rẹ sàn;
    ọgbẹ́ rẹ kún fún ìrora
Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ ìròyìn rẹ
    yóò pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí,
nítorí ta ni kò ní pín nínú
    ìwà búburú rẹ ti kò ti lópin.

Woe to Nineveh

Woe to the city of blood,(A)
    full of lies,(B)
full of plunder,
    never without victims!
The crack of whips,
    the clatter of wheels,
galloping horses
    and jolting chariots!
Charging cavalry,
    flashing swords
    and glittering spears!
Many casualties,
    piles of dead,
bodies without number,
    people stumbling over the corpses(C)
all because of the wanton lust of a prostitute,
    alluring, the mistress of sorceries,(D)
who enslaved nations by her prostitution(E)
    and peoples by her witchcraft.

“I am against(F) you,” declares the Lord Almighty.
    “I will lift your skirts(G) over your face.
I will show the nations your nakedness(H)
    and the kingdoms your shame.
I will pelt you with filth,(I)
    I will treat you with contempt(J)
    and make you a spectacle.(K)
All who see you will flee(L) from you and say,
    ‘Nineveh(M) is in ruins(N)—who will mourn for her?’(O)
    Where can I find anyone to comfort(P) you?”

Are you better than(Q) Thebes,(R)
    situated on the Nile,(S)
    with water around her?
The river was her defense,
    the waters her wall.
Cush[a](T) and Egypt were her boundless strength;
    Put(U) and Libya(V) were among her allies.
10 Yet she was taken captive(W)
    and went into exile.
Her infants were dashed(X) to pieces
    at every street corner.
Lots(Y) were cast for her nobles,
    and all her great men were put in chains.(Z)
11 You too will become drunk;(AA)
    you will go into hiding(AB)
    and seek refuge from the enemy.

12 All your fortresses are like fig trees
    with their first ripe fruit;(AC)
when they are shaken,
    the figs(AD) fall into the mouth of the eater.
13 Look at your troops—
    they are all weaklings.(AE)
The gates(AF) of your land
    are wide open to your enemies;
    fire has consumed the bars of your gates.(AG)

14 Draw water for the siege,(AH)
    strengthen your defenses!(AI)
Work the clay,
    tread the mortar,
    repair the brickwork!
15 There the fire(AJ) will consume you;
    the sword(AK) will cut you down—
    they will devour you like a swarm of locusts.
Multiply like grasshoppers,
    multiply like locusts!(AL)
16 You have increased the number of your merchants
    till they are more numerous than the stars in the sky,
but like locusts(AM) they strip the land
    and then fly away.
17 Your guards are like locusts,(AN)
    your officials like swarms of locusts
    that settle in the walls on a cold day—
but when the sun appears they fly away,
    and no one knows where.

18 King of Assyria, your shepherds[b] slumber;(AO)
    your nobles lie down to rest.(AP)
Your people are scattered(AQ) on the mountains
    with no one to gather them.
19 Nothing can heal you;(AR)
    your wound is fatal.
All who hear the news about you
    clap their hands(AS) at your fall,
for who has not felt
    your endless cruelty?(AT)

Footnotes

  1. Nahum 3:9 That is, the upper Nile region
  2. Nahum 3:18 That is, rulers