Add parallel Print Page Options

(A)Olúwa sọ fún Mose pé: “Bí ẹnikẹ́ni bá dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe àìṣòótọ́ sí Olúwa nípa títan ẹnìkejì rẹ̀ lórí ohun tí wọ́n fi sí ìkáwọ́ tàbí tí wọ́n fi pamọ́ sí i lọ́wọ́, tàbí bí ó bá jalè, tàbí kí ó yan ẹnìkejì rẹ̀ jẹ, tàbí kí ó rí ohun tó sọnù he tó sì parọ́ tàbí kí ó búra èké, tàbí kí ó tilẹ̀ dẹ́ṣẹ̀ kan, irú èyí tí ènìyàn lè ṣẹ̀. Bí ó bá dẹ́ṣẹ̀ báyìí tó sì jẹ̀bi, ó gbọdọ̀ dá ohun tó jí tàbí ohun tó fi agbára gbà, tàbí ohun tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ̀, tàbí ohun tó sọnù tó rí he, tàbí ohunkóhun tó búra èké lé lórí. Ó gbọdọ̀ dá gbogbo rẹ̀ padà ní pípé, kí ó fi ìdámárùn-ún iye rẹ̀ kún, kí ó sì dá gbogbo rẹ̀ padà fún ẹni tí ó ni í, ní ọjọ́ tó bá ń rú ẹbọ ẹ̀bi rẹ̀. Fún ìtánràn rẹ̀, ó gbọdọ̀ mú àgbò kan láti inú agbo ẹran wá fún àlùfáà, àní síwájú Olúwa, ẹbọ ẹ̀bi, àgbò aláìlábùkù, tó sì níye lórí bí iye owó ibi mímọ́. Báyìí ní àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún un ètùtù ìwẹ̀nùmọ́ níwájú Olúwa, a ó sì dáríjì í nítorí ohun tó ti ṣe tó sì mú un jẹ̀bi.”

Òfin ẹbọ sísun

Olúwa sọ fún Mose pé: “Pàṣẹ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé: ‘Èyí ni ìlànà fún ẹbọ sísun; ẹbọ sísun gbọdọ̀ wà lórí pẹpẹ láti alẹ́ di òwúrọ̀, kí iná sì máa jó lórí pẹpẹ 10 kí àlùfáà sì wọ ẹ̀wù funfun rẹ̀ pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ lára rẹ̀, yóò sì kó eérú tó wà níbi ẹbọ sísun tí iná ti jó lórí pẹpẹ, sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ. 11 Nígbà náà ni yóò bọ́ aṣọ rẹ̀, yóò sì wọ òmíràn, yóò wá gbé eérú náà lọ sí ẹ̀yìn ibùdó níbi tí a kà sí mímọ́. 12 Iná tó wà lórí pẹpẹ gbọdọ̀ máa jó, kò gbọdọ̀ kú, ní àràárọ̀ ni kí àlùfáà máa to igi si, kí ó sì to ẹbọ sísun sórí iná, kí ó sì máa sun ọ̀rá ẹran ẹbọ àlàáfíà níbẹ̀. 13 Iná gbọdọ̀ máa jó lórí pẹpẹ títí, kò gbọdọ̀ kú.

Òfin ẹbọ ohun jíjẹ

14 “ ‘Ìwọ̀nyí ni ìlànà fún ẹbọ ohun jíjẹ, kí àwọn ọmọ Aaroni gbé ẹbọ sísun náà wá síwájú Olúwa níwájú pẹpẹ. 15 Kí àlùfáà bu ẹ̀kúnwọ́ ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára àti òróró pẹ̀lú gbogbo tùràrí tó wà lórí ẹbọ ohun jíjẹ náà kí ó sì sun ẹbọ ìrántí náà lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa. 16 Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóò jẹ ìyókù ṣùgbọ́n wọ́n gbọdọ̀ jẹ ẹ́ láìsí máa wú máa wú ohun tí ń mú àkàrà wú nínú rẹ̀ ní ibi mímọ́, ní àgbàlá àgọ́ ìpàdé ni kí wọn ó ti jẹ ẹ́. 17 Ẹ má ṣe ṣè é pẹ̀lú ìwúkàrà. Èmi ti fún àwọn àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn nínú ẹbọ tí a fi iná sun sí mi. Ó jẹ́ mímọ́ jùlọ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ ẹ̀bi náà ṣe jẹ́. 18 Èyíkéyìí nínú àwọn ọmọkùnrin ìran Aaroni ló le jẹ ẹ́. Èyí ni ìpín rẹ tí ó gbọdọ̀ máa ṣe déédé lára àwọn ẹbọ tí a fi iná sun sí Olúwa láti ìrandíran. Ohunkóhun tí ó bá kàn án yóò di mímọ́.’ ”

19 Olúwa sọ fún Mose pé, 20 “Èyí ni ọrẹ tí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa ní ọjọ́ tí a bá fi òróró yan ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn; ìdámẹ́wàá òṣùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára fún ẹbọ ohun jíjẹ lójoojúmọ́, ìdajì rẹ̀ ní àárọ̀ àti ìdajì rẹ̀ ní ìrọ̀lẹ́. 21 Ẹ pèsè rẹ̀ pẹ̀lú òróró nínú àwo fífẹ̀, ẹ pò ó pọ̀ dáradára, kí ẹ sì gbé ọrẹ ohun jíjẹ náà wá ní ègé kéékèèkéé bí òórùn dídùn sí Olúwa. 22 Ọmọkùnrin Aaroni tí yóò rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tí a fi òróró yàn ni yóò rú ẹbọ náà. Ó jẹ́ ìpín ti Olúwa títí láé, wọn sì gbọdọ̀ sun ún pátápátá. 23 Gbogbo ọrẹ ohun jíjẹ ti àlùfáà ni wọ́n gbọdọ̀ sun pátápátá, wọn kò gbọdọ̀ jẹ ẹ́.”

Òfin ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀

24 Olúwa sọ fún Mose pé: 25 “Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ Ọkùnrin: ‘Wọ̀nyí ni ìlànà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, kí ẹ sì pa ẹran ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ níwájú Olúwa, níbi tí ẹ ti ń pa ẹran ẹbọ sísun, ó jẹ́ mímọ́ jùlọ. 26 Àlùfáà tó rú ẹbọ náà ni kí ó jẹ ẹ́, ibi mímọ́ ni kí ó ti jẹ ẹ́, ní àgbàlá àgọ́ ìpàdé. 27 Ohunkóhun tí ó bá kàn án yóò di mímọ́, bí ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ bá sì ta sí ara aṣọ kan, ẹ gbọdọ̀ fọ̀ ọ́ ní ibi mímọ́. 28 Ẹ gbọdọ̀ fọ́ ìkòkò amọ̀ tí ẹ fi se ẹran náà, ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe ìkòkò idẹ ni ẹ fi sè é, ẹ gbọdọ̀ bó o, kí ẹ sì fi omi sìn ín dáradára. 29 Gbogbo ọkùnrin ní ìdílé àlùfáà ló lè jẹ ẹ́, ó jẹ́ mímọ́ jùlọ. 30 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ kankan, èyí tí wọ́n bá mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wá sínú àgọ́ ìpàdé láti fi ṣe ètùtù ní ibi mímọ́, sísun ni kí ẹ sun ún.

[a]The Lord said to Moses: “If anyone sins and is unfaithful to the Lord(A) by deceiving a neighbor(B) about something entrusted to them or left in their care(C) or about something stolen, or if they cheat(D) their neighbor, or if they find lost property and lie about it,(E) or if they swear falsely(F) about any such sin that people may commit— when they sin in any of these ways and realize their guilt, they must return(G) what they have stolen or taken by extortion, or what was entrusted to them, or the lost property they found, or whatever it was they swore falsely about. They must make restitution(H) in full, add a fifth of the value to it and give it all to the owner on the day they present their guilt offering.(I) And as a penalty they must bring to the priest, that is, to the Lord, their guilt offering,(J) a ram from the flock, one without defect and of the proper value.(K) In this way the priest will make atonement(L) for them before the Lord, and they will be forgiven for any of the things they did that made them guilty.”

The Burnt Offering

The Lord said to Moses: “Give Aaron and his sons this command: ‘These are the regulations for the burnt offering(M): The burnt offering is to remain on the altar hearth throughout the night, till morning, and the fire must be kept burning on the altar.(N) 10 The priest shall then put on his linen clothes,(O) with linen undergarments next to his body,(P) and shall remove the ashes(Q) of the burnt offering that the fire has consumed on the altar and place them beside the altar. 11 Then he is to take off these clothes and put on others, and carry the ashes outside the camp to a place that is ceremonially clean.(R) 12 The fire on the altar must be kept burning; it must not go out. Every morning the priest is to add firewood(S) and arrange the burnt offering on the fire and burn the fat(T) of the fellowship offerings(U) on it. 13 The fire must be kept burning on the altar continuously; it must not go out.

The Grain Offering

14 “‘These are the regulations for the grain offering:(V) Aaron’s sons are to bring it before the Lord, in front of the altar. 15 The priest is to take a handful of the finest flour and some olive oil, together with all the incense(W) on the grain offering,(X) and burn the memorial[b] portion(Y) on the altar as an aroma pleasing to the Lord. 16 Aaron and his sons(Z) shall eat the rest(AA) of it, but it is to be eaten without yeast(AB) in the sanctuary area;(AC) they are to eat it in the courtyard(AD) of the tent of meeting.(AE) 17 It must not be baked with yeast; I have given it as their share(AF) of the food offerings presented to me.(AG) Like the sin offering[c] and the guilt offering, it is most holy.(AH) 18 Any male descendant of Aaron may eat it.(AI) For all generations to come(AJ) it is his perpetual share(AK) of the food offerings presented to the Lord. Whatever touches them will become holy.[d](AL)’”

19 The Lord also said to Moses, 20 “This is the offering Aaron and his sons are to bring to the Lord on the day he[e] is anointed:(AM) a tenth of an ephah[f](AN) of the finest flour(AO) as a regular grain offering,(AP) half of it in the morning and half in the evening. 21 It must be prepared with oil on a griddle;(AQ) bring it well-mixed and present the grain offering broken[g] in pieces as an aroma pleasing to the Lord. 22 The son who is to succeed him as anointed priest(AR) shall prepare it. It is the Lord’s perpetual share and is to be burned completely.(AS) 23 Every grain offering of a priest shall be burned completely; it must not be eaten.”

The Sin Offering

24 The Lord said to Moses, 25 “Say to Aaron and his sons: ‘These are the regulations for the sin offering:(AT) The sin offering is to be slaughtered before the Lord(AU) in the place(AV) the burnt offering is slaughtered; it is most holy. 26 The priest who offers it shall eat it; it is to be eaten in the sanctuary area,(AW) in the courtyard(AX) of the tent of meeting.(AY) 27 Whatever touches any of the flesh will become holy,(AZ) and if any of the blood is spattered on a garment, you must wash it in the sanctuary area. 28 The clay pot(BA) the meat is cooked in must be broken; but if it is cooked in a bronze pot, the pot is to be scoured and rinsed with water. 29 Any male in a priest’s family may eat it;(BB) it is most holy.(BC) 30 But any sin offering whose blood is brought into the tent of meeting to make atonement(BD) in the Holy Place(BE) must not be eaten; it must be burned up.(BF)

Footnotes

  1. Leviticus 6:1 In Hebrew texts 6:1-7 is numbered 5:20-26, and 6:8-30 is numbered 6:1-23.
  2. Leviticus 6:15 Or representative
  3. Leviticus 6:17 Or purification offering; also in verses 25 and 30
  4. Leviticus 6:18 Or Whoever touches them must be holy; similarly in verse 27
  5. Leviticus 6:20 Or each
  6. Leviticus 6:20 That is, probably about 3 1/2 pounds or about 1.6 kilograms
  7. Leviticus 6:21 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.