Add parallel Print Page Options

Jobu Fún Bilidadi lésì Nípa Ẹ̀kọ́ àti ẹ̀rí Ìdájọ́ Ọlọ́run

Jobu sì dáhùn ó sì wí pé:

“Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́.
    Báwo ní ènìyàn yóò ha ti ṣe jẹ́ aláre níwájú Ọlọ́run?
Bí ó bá ṣe pé yóò bá a jà,
    òun kì yóò lè dalóhùn kan nínú ẹgbẹ̀rún ọ̀rọ̀.
Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òun;
    ta ni ó ṣe agídí sí i tí ó sì gbé fún rí?
Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́:
    tí ó taari wọn ṣubú ní ìbínú rẹ̀.
Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀,
    ọwọ́n rẹ̀ sì mì tìtì.
Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è ràn,
    kí ó sì dí ìmọ́lẹ̀ ìràwọ̀ mọ́.
Òun nìkan ṣoṣo ni ó ta ojú ọ̀run,
    ti ó sì ń rìn lórí ìgbì Òkun.
Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Beari, Orioni
    àti Pleiadesi àti ìràwọ̀ púpọ̀ ti gúúsù.
10 Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwárí lọ,
    àní ohun ìyanu láìní iye.
11 Kíyèsi i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi, èmi kò sì rí i,
    ó sì kọjá síwájú, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.
12 Kíyèsi i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà?
    Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?
13 Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn,
    àwọn onírànlọ́wọ́ ti Rahabu a sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.

14 “Kí ní ṣe tí èmi ti n o fi ba ṣàròyé?
    Tí èmi yóò fi ma ṣe àwáwí?
15 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi, èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn;
    ṣùgbọ́n èmi ó gbàdúrà fún àánú.
16 Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn,
    èmi kì yóò sì gbàgbọ́ pé, Òun ti fetí sí ohùn mi.
17 Nítorí pé òun yóò lọ̀ mí lúúlúú pẹ̀lú ìjì ńlá,
    ó sọ ọgbẹ́ mi di púpọ̀ láìnídìí.
18 Òun kì yóò jẹ́ kí èmi kí ó rí ẹ̀mí mi,
    ṣùgbọ́n ó mú ohun kíkorò kún un fún mi.
19 Bí mo bá sọ ti agbára, wò ó!
    Alágbára ni, tàbí ní ti ìdájọ́, ta ni yóò dá àkókò fún mi láti rò?
20 Bí mo tilẹ̀ dá ara mi láre, ẹnu ara mi yóò dá mi lẹ́bi;
    bí mo wí pé olódodo ni èmi yóò sì fi mí hàn ní ẹni ẹ̀bi.

21 “Olóòótọ́ ni mo ṣe,
    síbẹ̀ èmi kò kíyèsi ara mi,
    ayé mi ní èmi ìbá máa gàn.
22 Ohùn kan náà ni, nítorí náà ni èmi ṣe sọ:
    ‘Òun a pa ẹni òtítọ́ àti ènìyàn búburú pẹ̀lú.’
23 Bí ìjàǹbá bá pa ni lójijì,
    yóò rẹ́rìn-ín nínú ìdààmú aláìṣẹ̀.
24 Nígbà tí a bá fi ayé lé ọwọ́ ènìyàn búburú;
    ó sì bo àwọn onídàájọ́ rẹ̀ lójú;
    bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ ǹjẹ́ ta ni?

25 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí ọjọ́ mi yára ju oníṣẹ́ lọ,
    wọ́n fò lọ, wọn kò rí ayọ̀.
26 Wọ́n kọjá lọ bí ọkọ̀ eèsún papirusi tí ń sáré lọ;
    bí idì tí ń yára si ohùn ọdẹ.
27 Bí èmi bá wí pé, ‘Èmi ó gbàgbé arò ìbìnújẹ́ mi,
    èmi ó fi ọkàn lélẹ̀, èmi ó sì rẹ ara mi lẹ́kún.’
28 Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí,
    èmi mọ̀ pé ìwọ kì yóò mú mi bí aláìṣẹ̀.
29 Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi,
    ǹjẹ́ kí ni èmi ń ṣe làálàá lásán sí?
30 Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ dídì wẹ ara mi,
    tí mo fi omi aró wẹ ọwọ́ mi mọ́,
31 síbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihò
    ọ̀gọ̀dọ̀ aṣọ ara mi yóò sọ mi di ìríra.

32 “Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi,
    tí èmi ó fi dá a lóhùn tí àwa o fi pàdé ní ìdájọ́.
33 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì wa
    tí ìbá fi ọwọ́ rẹ̀ lé àwa méjèèjì lára.
34 Kí ẹnìkan sá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi,
    kí ìbẹ̀rù rẹ̀ kí ó má sì ṣe dáyà fò mí
35 Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀;
    ṣùgbọ́n bí ó tí dúró tì mí, kò ri bẹ́ẹ̀ fún mi.

Job

Then Job replied:

“Indeed, I know that this is true.
    But how can mere mortals prove their innocence before God?(A)
Though they wished to dispute with him,(B)
    they could not answer him one time out of a thousand.(C)
His wisdom(D) is profound, his power is vast.(E)
    Who has resisted(F) him and come out unscathed?(G)
He moves mountains(H) without their knowing it
    and overturns them in his anger.(I)
He shakes the earth(J) from its place
    and makes its pillars tremble.(K)
He speaks to the sun and it does not shine;(L)
    he seals off the light of the stars.(M)
He alone stretches out the heavens(N)
    and treads on the waves of the sea.(O)
He is the Maker(P) of the Bear[a] and Orion,
    the Pleiades and the constellations of the south.(Q)
10 He performs wonders(R) that cannot be fathomed,
    miracles that cannot be counted.(S)
11 When he passes me, I cannot see him;
    when he goes by, I cannot perceive him.(T)
12 If he snatches away, who can stop him?(U)
    Who can say to him, ‘What are you doing?’(V)
13 God does not restrain his anger;(W)
    even the cohorts of Rahab(X) cowered at his feet.

14 “How then can I dispute with him?
    How can I find words to argue with him?(Y)
15 Though I were innocent, I could not answer him;(Z)
    I could only plead(AA) with my Judge(AB) for mercy.(AC)
16 Even if I summoned him and he responded,
    I do not believe he would give me a hearing.(AD)
17 He would crush me(AE) with a storm(AF)
    and multiply(AG) my wounds for no reason.(AH)
18 He would not let me catch my breath
    but would overwhelm me with misery.(AI)
19 If it is a matter of strength, he is mighty!(AJ)
    And if it is a matter of justice, who can challenge him[b]?(AK)
20 Even if I were innocent, my mouth would condemn me;
    if I were blameless, it would pronounce me guilty.(AL)

21 “Although I am blameless,(AM)
    I have no concern for myself;(AN)
    I despise my own life.(AO)
22 It is all the same; that is why I say,
    ‘He destroys both the blameless and the wicked.’(AP)
23 When a scourge(AQ) brings sudden death,
    he mocks the despair of the innocent.(AR)
24 When a land falls into the hands of the wicked,(AS)
    he blindfolds its judges.(AT)
    If it is not he, then who is it?(AU)

25 “My days are swifter than a runner;(AV)
    they fly away without a glimpse of joy.(AW)
26 They skim past(AX) like boats of papyrus,(AY)
    like eagles swooping down on their prey.(AZ)
27 If I say, ‘I will forget my complaint,(BA)
    I will change my expression, and smile,’
28 I still dread(BB) all my sufferings,
    for I know you will not hold me innocent.(BC)
29 Since I am already found guilty,
    why should I struggle in vain?(BD)
30 Even if I washed myself with soap(BE)
    and my hands(BF) with cleansing powder,(BG)
31 you would plunge me into a slime pit(BH)
    so that even my clothes would detest me.(BI)

32 “He is not a mere mortal(BJ) like me that I might answer him,(BK)
    that we might confront each other in court.(BL)
33 If only there were someone to mediate between us,(BM)
    someone to bring us together,(BN)
34 someone to remove God’s rod from me,(BO)
    so that his terror would frighten me no more.(BP)
35 Then I would speak up without fear of him,(BQ)
    but as it now stands with me, I cannot.(BR)

Footnotes

  1. Job 9:9 Or of Leo
  2. Job 9:19 See Septuagint; Hebrew me.