Add parallel Print Page Options

Jobu rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀

40 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé:

“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́?
    Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”

Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,

“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà?
    Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́;
    lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”

Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé:

“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin,
    èmi ó bi ọ léèrè,
    kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.

“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán?
    Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run
    tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́,
    tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde;
    kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀
    kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀,
    kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú
14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé,
    ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.

15 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti,
    tí mo dá pẹ̀lú rẹ,
    òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ,
    àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari;
    Iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ;
    Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run;
    síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 Nítòótọ́ òkè ńláńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá,
    níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì,
    lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
22 Igi lótusì ṣíji wọn bò o;
    igi arọrọ odò yí i káàkiri.
23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ;
    ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀,
    tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

40 The Lord said to Job:(A)

“Will the one who contends with the Almighty(B) correct him?(C)
    Let him who accuses God answer him!”(D)

Then Job answered the Lord:

“I am unworthy(E)—how can I reply to you?
    I put my hand over my mouth.(F)
I spoke once, but I have no answer(G)
    twice, but I will say no more.”(H)

Then the Lord spoke to Job out of the storm:(I)

“Brace yourself like a man;
    I will question you,
    and you shall answer me.(J)

“Would you discredit my justice?(K)
    Would you condemn me to justify yourself?(L)
Do you have an arm like God’s,(M)
    and can your voice(N) thunder like his?(O)
10 Then adorn yourself with glory and splendor,
    and clothe yourself in honor and majesty.(P)
11 Unleash the fury of your wrath,(Q)
    look at all who are proud and bring them low,(R)
12 look at all who are proud(S) and humble them,(T)
    crush(U) the wicked where they stand.
13 Bury them all in the dust together;(V)
    shroud their faces in the grave.(W)
14 Then I myself will admit to you
    that your own right hand can save you.(X)

15 “Look at Behemoth,
    which I made(Y) along with you
    and which feeds on grass like an ox.(Z)
16 What strength(AA) it has in its loins,
    what power in the muscles of its belly!(AB)
17 Its tail sways like a cedar;
    the sinews of its thighs are close-knit.(AC)
18 Its bones are tubes of bronze,
    its limbs(AD) like rods of iron.(AE)
19 It ranks first among the works of God,(AF)
    yet its Maker(AG) can approach it with his sword.(AH)
20 The hills bring it their produce,(AI)
    and all the wild animals play(AJ) nearby.(AK)
21 Under the lotus plants it lies,
    hidden among the reeds(AL) in the marsh.(AM)
22 The lotuses conceal it in their shadow;
    the poplars by the stream(AN) surround it.
23 A raging river(AO) does not alarm it;
    it is secure, though the Jordan(AP) should surge against its mouth.
24 Can anyone capture it by the eyes,
    or trap it and pierce its nose?(AQ)