Add parallel Print Page Options

Ọjọ́ Olúwa

28 (A)“Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́,
    èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo;
àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀,
    àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá,
àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.
29 Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin,
    àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin,
    ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.
30 Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun
    àti ní ayé,
    ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.
31 (B)A á sọ oòrùn di òkùnkùn,
    àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀,
    kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.
32 (C)Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè
    orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà:
nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu
    ní ìgbàlà yóò gbé wà,
    Olúwa ti wí,
àti nínú àwọn
    ìyókù tí Olúwa yóò pè.

Read full chapter