Add parallel Print Page Options

Israẹli kọjá nínú odò Jordani

Ní kùtùkùtù òwúrọ̀, Joṣua àti gbogbo àwọn Israẹli sí kúrò ní Ṣittimu, wọ́n sì lọ sí etí odò Jordani, wọ́n sì pa ibùdó síbẹ̀ kí wọn tó kọjá. Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta àwọn olórí la àárín ibùdó já. Wọ́n sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé: “Nígbà tí ẹ bá rí àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín, tí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi rù ú, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sí kúrò ní ipò yín, ẹ̀yin yóò sì máa tẹ̀lé e. Ẹyin yóò lè mọ ọ̀nà tí ẹ ó gbà, torí pé ẹ̀yin kò gba ọ̀nà yìí tẹ́lẹ̀ rí. Ṣùgbọ́n àlàfo gbọdọ̀ wà ní àárín yín àti àpótí náà, tó bí ìwọ̀n ẹgbàá ìgbọ̀nwọ́.”

Joṣua sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ya ara yín sí mímọ́, nítorí ní ọ̀la, Olúwa yóò ṣe ohun ìyanu ní àárín yín.”

Joṣua sọ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ̀yin, ẹ gbé àpótí ẹ̀rí náà kí ẹ̀yin kí ó sì máa lọ ṣáájú àwọn ènìyàn.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé e sókè, wọ́n sì ń lọ ní iwájú u wọn.

Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Òní yìí ni Èmi yóò bẹ̀rẹ̀ sí í gbé ọ ga ní ojú u gbogbo àwọn ará Israẹli, kí wọn lè mọ̀ pé Èmi wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí mo ṣe wà pẹ̀lú Mose. Sọ fún àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà: ‘Nígbà tí ẹ bá dé etí omi Jordani, ẹ lọ kí ẹ sì dúró nínú odò náà.’ ”

Joṣua sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ súnmọ́ ibí kí ẹ̀yin kí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín. 10 Èyí ni ẹ̀yin yóò fi mọ̀ pé Ọlọ́run alààyè wà ní àárín yín àti pé dájúdájú yóò lé àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, Hifi, Peresi, Girgaṣi, Amori àti Jebusi jáde níwájú u yín. 11 Àpótí májẹ̀mú Olúwa gbogbo ayé ń gòkè lọ sí Jordani ṣáájú u yín. 12 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ mú ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. 13 Bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí Olúwa, Olúwa gbogbo ayé bá ti ẹsẹ̀ bọ odò Jordani, omi tí ń ti òkè sàn wá yóò gé kúrò yóò sì gbá jọ bí òkìtì kan.”

14 Nígbà tí àwọn ènìyàn gbéra láti ibùdó láti kọjá nínú odò Jordani, àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà ń lọ níwájú wọn. 15 Odò Jordani sì máa ń wà ní kíkún ní gbogbo ìgbà ìkórè. Ṣùgbọ́n bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí ti dé odò Jordani tí ẹsẹ̀ wọn sì kan etí omi, 16 omi tí ń ti òkè sàn wá dúró. Ó sì gbá jọ bí òkìtì ní òkèèrè, ní ìlú tí a ń pè ní Adamu, tí ó wà ní tòsí Saretani; nígbà tí omi tí ń sàn lọ sínú Òkun aginjù, (Òkun Iyọ̀) gé kúrò pátápátá. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kọjá sí òdìkejì ní ìdojúkọ Jeriko. 17 Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa sì dúró ṣinṣin lórí ilẹ̀ gbígbẹ ní àárín Jordani, nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ń kọjá títí gbogbo orílẹ̀-èdè náà fi rékọjá nínú odò Jordani lórí ilẹ̀ gbígbẹ.

Crossing the Jordan

Early in the morning Joshua and all the Israelites set out from Shittim(A) and went to the Jordan,(B) where they camped before crossing over. After three days(C) the officers(D) went throughout the camp,(E) giving orders to the people: “When you see the ark of the covenant(F) of the Lord your God, and the Levitical(G) priests(H) carrying it, you are to move out from your positions and follow it. Then you will know which way to go, since you have never been this way before. But keep a distance of about two thousand cubits[a](I) between you and the ark; do not go near it.”

Joshua told the people, “Consecrate yourselves,(J) for tomorrow the Lord will do amazing things(K) among you.”

Joshua said to the priests, “Take up the ark of the covenant and pass on ahead of the people.” So they took it up and went ahead of them.

And the Lord said to Joshua, “Today I will begin to exalt you(L) in the eyes of all Israel, so they may know that I am with you as I was with Moses.(M) Tell the priests(N) who carry the ark of the covenant: ‘When you reach the edge of the Jordan’s waters, go and stand in the river.’”

Joshua said to the Israelites, “Come here and listen to the words of the Lord your God. 10 This is how you will know that the living God(O) is among you(P) and that he will certainly drive out before you the Canaanites, Hittites,(Q) Hivites, Perizzites,(R) Girgashites, Amorites and Jebusites.(S) 11 See, the ark of the covenant of the Lord of all the earth(T) will go into the Jordan ahead of you.(U) 12 Now then, choose twelve men(V) from the tribes of Israel, one from each tribe. 13 And as soon as the priests who carry the ark of the Lord—the Lord of all the earth(W)—set foot in the Jordan, its waters flowing downstream(X) will be cut off(Y) and stand up in a heap.(Z)

14 So when the people broke camp to cross the Jordan, the priests carrying the ark of the covenant(AA) went ahead(AB) of them. 15 Now the Jordan(AC) is at flood stage(AD) all during harvest.(AE) Yet as soon as the priests who carried the ark reached the Jordan and their feet touched the water’s edge, 16 the water from upstream stopped flowing.(AF) It piled up in a heap(AG) a great distance away, at a town called Adam in the vicinity of Zarethan,(AH) while the water flowing down(AI) to the Sea of the Arabah(AJ) (that is, the Dead Sea(AK)) was completely cut off.(AL) So the people crossed over opposite Jericho.(AM) 17 The priests(AN) who carried the ark of the covenant of the Lord stopped in the middle of the Jordan and stood on dry ground,(AO) while all Israel passed by until the whole nation had completed the crossing on dry ground.(AP)

Footnotes

  1. Joshua 3:4 That is, about 3,000 feet or about 900 meters