Add parallel Print Page Options

Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi
    kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé!
Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru
    nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
Háà, èmi ìbá ní ni aginjù
    ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò,
kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀
    kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn:
nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà
    àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.

Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀
    bí ọfà láti fi pa irọ́;
kì í ṣe nípa òtítọ́
    ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà.
Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn;
wọn kò sì náání mi,
    Olúwa wí.
Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ;
    má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ.
Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ,
    oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni
    tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn
láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn
    di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn
    wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú
ẹ̀tàn wọn,
    ni Olúwa wí.

Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí:

“Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé
    kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró
    ó ń sọ ẹ̀tàn; oníkálùkù sì ń
fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí
    aládùúgbò rẹ̀; ní inú
    ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?”
ni Olúwa wí.
    “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara
    mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”

10 Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré
    ẹkún fún àwọn òkè; àti ẹkún
ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì.
    Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì
kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe
    ẹran ọ̀sìn, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run
    sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.

11 “Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì
    àlàpà àti ihò àwọn ìkookò.
Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro
    tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”

12 Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?

13 Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi. 14 Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn. 15 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé. 16 Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”

17 Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí:

“Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá;
    sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
18 Jẹ́ kí wọn wá kíákíá,
    kí wọn wá pohùnréré ẹkún
lé wa lórí títí ojú wa yóò
    fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa
19 A gbọ́ igbe ìpohùnréré
    ẹkún ní Sioni:
    ‘Àwa ti ṣègbé tó!
A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀,
    nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’ ”

20 Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́
    ọ̀rọ̀ Olúwa. Ṣí etí yín sí
ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin
    yín ní ìpohùnréré
    ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
21 Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé
    ó sì ti wọ odi alágbára wa
ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní
    àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin
    kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.

22 Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“ ‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú
    bí ààtàn ní oko gbangba
àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè
    láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’ ”

23 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn
    nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára
nítorí rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀
    nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
24 (A)Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń
    ṣògo nípa èyí nì wí pé
òun ní òye, òun sì mọ̀ mí
    wí pé, èmi ni Olúwa tí ń
ṣe òtítọ́ ìdájọ́ àti òdodo
    ní ayé nínú èyí ni mo ní
inú dídùn sí,”
    Olúwa wí.

25 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan. 26 Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”

[a]Oh, that my head were a spring of water
    and my eyes a fountain of tears!(A)
I would weep(B) day and night
    for the slain of my people.(C)
Oh, that I had in the desert(D)
    a lodging place for travelers,
so that I might leave my people
    and go away from them;
for they are all adulterers,(E)
    a crowd of unfaithful(F) people.

“They make ready their tongue
    like a bow, to shoot lies;(G)
it is not by truth
    that they triumph[b] in the land.
They go from one sin to another;
    they do not acknowledge(H) me,”
declares the Lord.
“Beware of your friends;(I)
    do not trust anyone in your clan.(J)
For every one of them is a deceiver,[c](K)
    and every friend a slanderer.(L)
Friend deceives friend,(M)
    and no one speaks the truth.(N)
They have taught their tongues to lie;(O)
    they weary themselves with sinning.
You[d] live in the midst of deception;(P)
    in their deceit they refuse to acknowledge me,”
declares the Lord.

Therefore this is what the Lord Almighty says:

“See, I will refine(Q) and test(R) them,
    for what else can I do
    because of the sin of my people?
Their tongue(S) is a deadly arrow;
    it speaks deceitfully.
With their mouths they all speak cordially to their neighbors,(T)
    but in their hearts they set traps(U) for them.(V)
Should I not punish them for this?”
    declares the Lord.
“Should I not avenge(W) myself
    on such a nation as this?”

10 I will weep and wail for the mountains
    and take up a lament concerning the wilderness grasslands.(X)
They are desolate and untraveled,
    and the lowing of cattle is not heard.
The birds(Y) have all fled
    and the animals are gone.

11 “I will make Jerusalem a heap(Z) of ruins,
    a haunt of jackals;(AA)
and I will lay waste the towns of Judah(AB)
    so no one can live there.”(AC)

12 Who is wise(AD) enough to understand this? Who has been instructed by the Lord and can explain it? Why has the land been ruined and laid waste like a desert that no one can cross?

13 The Lord said, “It is because they have forsaken my law, which I set before them; they have not obeyed me or followed my law.(AE) 14 Instead, they have followed(AF) the stubbornness of their hearts;(AG) they have followed the Baals, as their ancestors taught them.” 15 Therefore this is what the Lord Almighty, the God of Israel, says: “See, I will make this people eat bitter food(AH) and drink poisoned water.(AI) 16 I will scatter them among nations(AJ) that neither they nor their ancestors have known,(AK) and I will pursue them with the sword(AL) until I have made an end of them.”(AM)

17 This is what the Lord Almighty says:

“Consider now! Call for the wailing women(AN) to come;
    send for the most skillful of them.
18 Let them come quickly
    and wail over us
till our eyes overflow with tears
    and water streams from our eyelids.(AO)
19 The sound of wailing is heard from Zion:
    ‘How ruined(AP) we are!
    How great is our shame!
We must leave our land
    because our houses are in ruins.’”

20 Now, you women, hear the word of the Lord;
    open your ears to the words of his mouth.(AQ)
Teach your daughters how to wail;
    teach one another a lament.(AR)
21 Death has climbed in through our windows(AS)
    and has entered our fortresses;
it has removed the children from the streets
    and the young men(AT) from the public squares.

22 Say, “This is what the Lord declares:

“‘Dead bodies will lie
    like dung(AU) on the open field,
like cut grain behind the reaper,
    with no one to gather them.’”

23 This is what the Lord says:

“Let not the wise boast of their wisdom(AV)
    or the strong boast of their strength(AW)
    or the rich boast of their riches,(AX)
24 but let the one who boasts boast(AY) about this:
    that they have the understanding to know(AZ) me,
that I am the Lord,(BA) who exercises kindness,(BB)
    justice and righteousness(BC) on earth,
    for in these I delight,”
declares the Lord.

25 “The days are coming,” declares the Lord, “when I will punish all who are circumcised only in the flesh(BD) 26 Egypt, Judah, Edom, Ammon, Moab and all who live in the wilderness in distant places.[e](BE) For all these nations are really uncircumcised,(BF) and even the whole house of Israel is uncircumcised in heart.(BG)

Footnotes

  1. Jeremiah 9:1 In Hebrew texts 9:1 is numbered 8:23, and 9:2-26 is numbered 9:1-25.
  2. Jeremiah 9:3 Or lies; / they are not valiant for truth
  3. Jeremiah 9:4 Or a deceiving Jacob
  4. Jeremiah 9:6 That is, Jeremiah (the Hebrew is singular)
  5. Jeremiah 9:26 Or wilderness and who clip the hair by their foreheads