Add parallel Print Page Options

Ìlérí ìmúpadàbọ̀sípò

33 Nígbà tí Jeremiah wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì: “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀: ‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’ Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn ọba Juda tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà nínú ìjà pẹ̀lú Kaldea: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.

“ ‘Wò ó, èmi ó mú ọ̀já àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọ́pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́. Èmi ó mú Juda àti Israẹli kúrò nínú ìgbèkùn, èmi ó sì tún wọn kọ́ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe wà tẹ́lẹ̀. Èmi ó wẹ̀ wọ́n nù kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ sí mi. Èmi ó sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àìṣedéédéé wọn sí mi jì wọ́n. Nígbà náà ni ìlú yìí ó fún mi ní òkìkí, ayọ̀, ìyìn àti ọlá níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé; tí wọ́n gbọ́ gbogbo rere tí èmi ṣe fún wọn. Wọn ó sì bẹ̀rù, wọn ó wárìrì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore àti àlàáfíà tí èmi pèsè fún wọn.’

10 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ẹ̀yin yóò wí nípa ibí yìí pé, “Ó dahoro, láìsí ènìyàn tàbí ẹran.” Síbẹ̀ ní ìlú Juda àti ní òpópónà Jerusalẹmu tí ó dahoro, láìsí ẹni tó gbé ibẹ̀; ìbá à se ènìyàn tàbí ẹran, tí yóò gbọ́ lẹ́ẹ̀kan sí. 11 Ariwo ayọ̀ àti inú dídùn, ohùn ìyàwó àti ti ọkọ ìyàwó àti ohùn àwọn tí ó ru ẹbọ ọpẹ́ wọn nílé Olúwa wí pé:

“ ‘ “Yin Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    nítorí Olúwa dára,
    ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé.”

Nítorí èmi ó dá ìkólọ ilẹ̀ náà padà sí bí o ṣe wà tẹ́lẹ̀,’ ni Olúwa wí:

12 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ní ilẹ̀ yìí tí ó ti dahoro láìsí ọkùnrin àti àwọn ẹran nínú gbogbo ìlú, kò ní sí pápá oko fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sinmi. 13 Ní ìlú òkè wọ̀n-ọn-nì, nínú ìlú Àfonífojì, àti nínú ìlú ìhà gúúsù, àti ní ilẹ̀ ti Benjamini, ní ibi wọ̀n-ọn-nì tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda ni agbo àgùntàn yóò tún máa kọjá ní ọwọ́ ẹni tí ń kà wọ́n,’ ni Olúwa wí.

14 “ ‘Àwọn ọjọ́ náà ń bọ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí èmi ó mú ìlérí rere tí mo ṣe fún ilé Israẹli àti ilé Juda ṣẹ.

15 (A)‘Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ní àkókò náà,
    Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dafidi.
    Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.
16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Juda yóò di ẹni ìgbàlà.
    Jerusalẹmu yóò sì máa gbé láìséwu
Orúkọ yìí ni a ó máa pè é
    Olúwa wa olódodo.’

17 (B)Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dafidi kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Israẹli. 18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Lefi kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’ ”

19 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá wí pé: 20 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Tí ìwọ bá lè dá májẹ̀mú mi ní òru tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀sán àti òru kò lè sí ní àkókò wọn mọ́. 21 Nígbà náà ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú Dafidi ìránṣẹ́ mi àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi tí ó jẹ́ àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ níwájú mi lè bàjẹ́, tí Dafidi kò sì rí ẹni láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀. 22 Èmi ó mú àwọn ọmọlẹ́yìn Dafidi ìránṣẹ́ mi àti Lefi tí ó jẹ́ oníwàásù níwájú mi di bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí kò ṣe é kà àti bí iyẹ̀pẹ̀ ojú Òkun tí kò ṣe é wọ́n.’ ”

23 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé: 24 “Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan. 25 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀. 26 Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọlẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’ ”

Promise of Restoration

33 While Jeremiah was still confined(A) in the courtyard(B) of the guard, the word of the Lord came to him a second time:(C) “This is what the Lord says, he who made the earth,(D) the Lord who formed it and established it—the Lord is his name:(E) ‘Call(F) to me and I will answer you and tell you great and unsearchable(G) things you do not know.’ For this is what the Lord, the God of Israel, says about the houses in this city and the royal palaces of Judah that have been torn down to be used against the siege(H) ramps(I) and the sword in the fight with the Babylonians[a]: ‘They will be filled with the dead bodies of the people I will slay in my anger and wrath.(J) I will hide my face(K) from this city because of all its wickedness.

“‘Nevertheless, I will bring health and healing to it; I will heal(L) my people and will let them enjoy abundant peace(M) and security. I will bring Judah(N) and Israel back from captivity[b](O) and will rebuild(P) them as they were before.(Q) I will cleanse(R) them from all the sin they have committed against me and will forgive(S) all their sins of rebellion against me. Then this city will bring me renown,(T) joy, praise(U) and honor(V) before all nations on earth that hear of all the good things I do for it; and they will be in awe and will tremble(W) at the abundant prosperity and peace I provide for it.’

10 “This is what the Lord says: ‘You say about this place, “It is a desolate waste, without people or animals.”(X) Yet in the towns of Judah and the streets of Jerusalem that are deserted,(Y) inhabited by neither people nor animals, there will be heard once more 11 the sounds of joy and gladness,(Z) the voices of bride and bridegroom, and the voices of those who bring thank offerings(AA) to the house of the Lord, saying,

“Give thanks to the Lord Almighty,
    for the Lord is good;(AB)
    his love endures forever.”(AC)

For I will restore the fortunes(AD) of the land as they were before,(AE)’ says the Lord.

12 “This is what the Lord Almighty says: ‘In this place, desolate(AF) and without people or animals(AG)—in all its towns there will again be pastures for shepherds to rest their flocks.(AH) 13 In the towns of the hill(AI) country, of the western foothills and of the Negev,(AJ) in the territory of Benjamin, in the villages around Jerusalem and in the towns of Judah, flocks will again pass under the hand(AK) of the one who counts them,’ says the Lord.

14 “‘The days are coming,’ declares the Lord, ‘when I will fulfill the good promise(AL) I made to the people of Israel and Judah.

15 “‘In those days and at that time
    I will make a righteous(AM) Branch(AN) sprout from David’s line;(AO)
    he will do what is just and right in the land.
16 In those days Judah will be saved(AP)
    and Jerusalem will live in safety.(AQ)
This is the name by which it[c] will be called:(AR)
    The Lord Our Righteous Savior.’(AS)

17 For this is what the Lord says: ‘David will never fail(AT) to have a man to sit on the throne of Israel, 18 nor will the Levitical(AU) priests(AV) ever fail to have a man to stand before me continually to offer burnt offerings, to burn grain offerings and to present sacrifices.(AW)’”

19 The word of the Lord came to Jeremiah: 20 “This is what the Lord says: ‘If you can break my covenant with the day(AX) and my covenant with the night, so that day and night no longer come at their appointed time,(AY) 21 then my covenant(AZ) with David my servant—and my covenant with the Levites(BA) who are priests ministering before me—can be broken and David will no longer have a descendant to reign on his throne.(BB) 22 I will make the descendants of David my servant and the Levites who minister before me as countless(BC) as the stars in the sky and as measureless as the sand on the seashore.’”

23 The word of the Lord came to Jeremiah: 24 “Have you not noticed that these people are saying, ‘The Lord has rejected the two kingdoms[d](BD) he chose’? So they despise(BE) my people and no longer regard them as a nation.(BF) 25 This is what the Lord says: ‘If I have not made my covenant with day and night(BG) and established the laws(BH) of heaven and earth,(BI) 26 then I will reject(BJ) the descendants of Jacob(BK) and David my servant and will not choose one of his sons to rule over the descendants of Abraham, Isaac and Jacob. For I will restore their fortunes[e](BL) and have compassion(BM) on them.’”

Footnotes

  1. Jeremiah 33:5 Or Chaldeans
  2. Jeremiah 33:7 Or will restore the fortunes of Judah and Israel
  3. Jeremiah 33:16 Or he
  4. Jeremiah 33:24 Or families
  5. Jeremiah 33:26 Or will bring them back from captivity