Add parallel Print Page Options

Ìmúpadà sípò Israẹli

30 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé: “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan. Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”

Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda: “Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“ ‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́
    láìṣe igbe àlàáfíà.
Béèrè kí o sì rí:
    Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí?
Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin
    tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí,
    tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó!
    Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀,
Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu
    ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.

“ ‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé;
    ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn,
Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù.
    Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́
Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn
    àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn,
    ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.

10 “ ‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, Ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi,
    má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, Ìwọ Israẹli,’
    ni Olúwa wí.
    ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá,
àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn.
    Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà,
    kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
11 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’
    ni Olúwa wí.
‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run,
    nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká,
síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
    Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan;
    Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’

12 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“ ‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn,
    bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
13 Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín,
    kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín,
    a kò sì mú yín láradá.
14 Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ,
    wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú.
Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ,
    mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà,
nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀,
    ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
15 Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín,
    ìrora yín èyí tí kò ní oògùn?
Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga
    ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.

16 “ ‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá,
    àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì;
    gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
17 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín,
    èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’
    ni Olúwa wí,
    ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri
    Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’

18 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“ ‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà,
    èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀;
ìlú náà yóò sì di títúnṣe
    tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
19 Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti
    ìyìn yóò sì ti máa jáde.
Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀,
    wọn kì yóò sì dínkù ní iye,
Èmi yóò fi ọlá fún wọn,
    wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
20 Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì
    níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí.
Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára,
    ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
21 Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn,
    ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn.
Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi,
    nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’
    ni Olúwa wí.
22 ‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi,
    èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’ ”

23 Wò ó, ìbínú Ọlọ́run yóò tú jáde,
    ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
24 Ìbínú ńlá Ọlọ́run kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn
    àwọn ìkà títí yóò fi mú
    èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ.
Ní àìpẹ́ ọjọ́,
    òye rẹ̀ yóò yé e yín.

Restoration of Israel

30 This is the word that came to Jeremiah from the Lord: “This is what the Lord, the God of Israel, says: ‘Write(A) in a book all the words I have spoken to you. The days(B) are coming,’ declares the Lord, ‘when I will bring(C) my people Israel and Judah back from captivity[a] and restore(D) them to the land I gave their ancestors to possess,’ says the Lord.”

These are the words the Lord spoke concerning Israel and Judah: “This is what the Lord says:

“‘Cries of fear(E) are heard—
    terror, not peace.
Ask and see:
    Can a man bear children?
Then why do I see every strong man
    with his hands on his stomach like a woman in labor,(F)
    every face turned deathly pale?(G)
How awful that day(H) will be!
    No other will be like it.
It will be a time of trouble(I) for Jacob,
    but he will be saved(J) out of it.

“‘In that day,’ declares the Lord Almighty,
    ‘I will break the yoke(K) off their necks
and will tear off their bonds;(L)
    no longer will foreigners enslave them.(M)
Instead, they will serve the Lord their God
    and David(N) their king,(O)
    whom I will raise up for them.

10 “‘So do not be afraid,(P) Jacob my servant;(Q)
    do not be dismayed, Israel,’
declares the Lord.
‘I will surely save(R) you out of a distant place,
    your descendants from the land of their exile.
Jacob will again have peace and security,(S)
    and no one will make him afraid.(T)
11 I am with you(U) and will save you,’
    declares the Lord.
‘Though I completely destroy all the nations
    among which I scatter you,
    I will not completely destroy(V) you.
I will discipline(W) you but only in due measure;
    I will not let you go entirely unpunished.’(X)

12 “This is what the Lord says:

“‘Your wound(Y) is incurable,
    your injury beyond healing.(Z)
13 There is no one to plead your cause,(AA)
    no remedy for your sore,
    no healing(AB) for you.
14 All your allies(AC) have forgotten you;
    they care nothing for you.
I have struck you as an enemy(AD) would
    and punished you as would the cruel,(AE)
because your guilt is so great
    and your sins(AF) so many.
15 Why do you cry out over your wound,
    your pain that has no cure?(AG)
Because of your great guilt and many sins
    I have done these things to you.(AH)

16 “‘But all who devour(AI) you will be devoured;
    all your enemies will go into exile.(AJ)
Those who plunder(AK) you will be plundered;
    all who make spoil of you I will despoil.
17 But I will restore you to health
    and heal(AL) your wounds,’
declares the Lord,
‘because you are called an outcast,(AM)
    Zion for whom no one cares.’(AN)

18 “This is what the Lord says:

“‘I will restore the fortunes(AO) of Jacob’s tents(AP)
    and have compassion(AQ) on his dwellings;
the city will be rebuilt(AR) on her ruins,
    and the palace will stand in its proper place.
19 From them will come songs(AS) of thanksgiving(AT)
    and the sound of rejoicing.(AU)
I will add to their numbers,(AV)
    and they will not be decreased;
I will bring them honor,(AW)
    and they will not be disdained.
20 Their children(AX) will be as in days of old,
    and their community will be established(AY) before me;
    I will punish(AZ) all who oppress them.
21 Their leader(BA) will be one of their own;
    their ruler will arise from among them.(BB)
I will bring him near(BC) and he will come close to me—
    for who is he who will devote himself
    to be close to me?’
declares the Lord.
22 “‘So you will be my people,(BD)
    and I will be your God.(BE)’”

23 See, the storm(BF) of the Lord
    will burst out in wrath,
a driving wind swirling down
    on the heads of the wicked.
24 The fierce anger(BG) of the Lord will not turn back(BH)
    until he fully accomplishes
    the purposes of his heart.
In days to come
    you will understand(BI) this.

Footnotes

  1. Jeremiah 30:3 Or will restore the fortunes of my people Israel and Judah