Add parallel Print Page Options

“Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀
    tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn,
ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá?
    Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí?
Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́,
    ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?”
    ni Olúwa wí.
“Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì,
    kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́?
Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́,
    bí i ará Arabia kan nínú aginjù,
ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́
    pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.
Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn,
    kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò.
Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà,
    ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.
Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé,
    ‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.
Ìwọ yóò ha máa bínú títí?
    Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’
Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀
    ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”

Israẹli aláìṣòótọ́

Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀. Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i. Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè. Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi. 10 Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.

11 Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ. 12 Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá:

“ ‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí.
    ‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́,
nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí.
    Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé
13 Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ,
    ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ,
ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì
    lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀,
ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’ ”
    ni Olúwa wí.

14 “Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni. 15 Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀. 16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa’ kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́. 17 Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́. 18 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.

19 “Èmi fúnra mi sọ wí pé,

“ ‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin
    kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’
Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’
    o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.
20 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi.
Ìwọ ilé Israẹli”
    ni Olúwa wí.

21 A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga,
    ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli,
nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po,
    wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.

22 “Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,
    Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.”

“Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ
    nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.
23 Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè
    kéékèèkéé àti àwọn òkè gíga;
Nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run
    wa ni ìgbàlà Israẹli wà.
24 Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti
    jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run,
ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn,
    ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
25 Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa,
    kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀.
A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa,
    àwa àti àwọn baba wa,
láti ìgbà èwe wa títí di òní
    a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”

“If a man divorces(A) his wife
    and she leaves him and marries another man,
should he return to her again?
    Would not the land be completely defiled?(B)
But you have lived as a prostitute with many lovers(C)
    would you now return to me?”(D)
declares the Lord.
“Look up to the barren heights(E) and see.
    Is there any place where you have not been ravished?
By the roadside(F) you sat waiting for lovers,
    sat like a nomad in the desert.
You have defiled the land(G)
    with your prostitution(H) and wickedness.
Therefore the showers have been withheld,(I)
    and no spring rains(J) have fallen.
Yet you have the brazen(K) look of a prostitute;
    you refuse to blush with shame.(L)
Have you not just called to me:
    ‘My Father,(M) my friend from my youth,(N)
will you always be angry?(O)
    Will your wrath continue forever?’
This is how you talk,
    but you do all the evil you can.”

Unfaithful Israel

During the reign of King Josiah,(P) the Lord said to me, “Have you seen what faithless(Q) Israel has done? She has gone up on every high hill and under every spreading tree(R) and has committed adultery(S) there. I thought that after she had done all this she would return to me but she did not, and her unfaithful sister(T) Judah saw it.(U) I gave faithless Israel(V) her certificate of divorce(W) and sent her away because of all her adulteries. Yet I saw that her unfaithful sister Judah had no fear;(X) she also went out and committed adultery. Because Israel’s immorality mattered so little to her, she defiled the land(Y) and committed adultery(Z) with stone(AA) and wood.(AB) 10 In spite of all this, her unfaithful sister Judah did not return(AC) to me with all her heart, but only in pretense,(AD)” declares the Lord.(AE)

11 The Lord said to me, “Faithless Israel is more righteous(AF) than unfaithful(AG) Judah.(AH) 12 Go, proclaim this message toward the north:(AI)

“‘Return,(AJ) faithless(AK) Israel,’ declares the Lord,
    ‘I will frown on you no longer,
for I am faithful,’(AL) declares the Lord,
    ‘I will not be angry(AM) forever.
13 Only acknowledge(AN) your guilt—
    you have rebelled against the Lord your God,
you have scattered your favors to foreign gods(AO)
    under every spreading tree,(AP)
    and have not obeyed(AQ) me,’”
declares the Lord.

14 “Return,(AR) faithless people,” declares the Lord, “for I am your husband.(AS) I will choose you—one from a town and two from a clan—and bring you to Zion. 15 Then I will give you shepherds(AT) after my own heart,(AU) who will lead you with knowledge and understanding. 16 In those days, when your numbers have increased greatly in the land,” declares the Lord, “people will no longer say, ‘The ark(AV) of the covenant of the Lord.’ It will never enter their minds or be remembered;(AW) it will not be missed, nor will another one be made. 17 At that time they will call Jerusalem The Throne(AX) of the Lord, and all nations(AY) will gather in Jerusalem to honor(AZ) the name of the Lord. No longer will they follow the stubbornness of their evil hearts.(BA) 18 In those days the people of Judah will join the people of Israel,(BB) and together(BC) they will come from a northern(BD) land to the land(BE) I gave your ancestors as an inheritance.

19 “I myself said,

“‘How gladly would I treat you like my children
    and give you a pleasant land,(BF)
    the most beautiful inheritance(BG) of any nation.’
I thought you would call me ‘Father’(BH)
    and not turn away from following me.
20 But like a woman unfaithful to her husband,
    so you, Israel, have been unfaithful(BI) to me,”
declares the Lord.

21 A cry is heard on the barren heights,(BJ)
    the weeping(BK) and pleading of the people of Israel,
because they have perverted their ways
    and have forgotten(BL) the Lord their God.

22 “Return,(BM) faithless people;
    I will cure(BN) you of backsliding.”(BO)

“Yes, we will come to you,
    for you are the Lord our God.
23 Surely the idolatrous commotion on the hills(BP)
    and mountains is a deception;
surely in the Lord our God
    is the salvation(BQ) of Israel.
24 From our youth shameful(BR) gods have consumed
    the fruits of our ancestors’ labor—
their flocks and herds,
    their sons and daughters.
25 Let us lie down in our shame,(BS)
    and let our disgrace cover us.
We have sinned(BT) against the Lord our God,
    both we and our ancestors;(BU)
from our youth(BV) till this day
    we have not obeyed(BW) the Lord our God.”