Add parallel Print Page Options

Juda yóò sin Nebukadnessari

27 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé: Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ṣe àjàgà àti ọ̀pá irin fún ara rẹ, kí o sì fiwé ọrùn rẹ. Kí o rán ọ̀rọ̀ sí ọba ti Edomu, Moabu, Ammoni, Tire àti Sidoni láti ọwọ́ àwọn ikọ̀ tí ó wá sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ Sedekiah ọba Juda. Kí o sì pàṣẹ fún wọn láti wí fún àwọn olúwa wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Sọ èyí fún àwọn olúwa rẹ: Pẹ̀lú agbára ńlá mi àti ọwọ́ nínà mi ni Èmi dá ayé, ènìyàn àti ẹranko tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Mo sì fún ẹni tí ó wu ọkàn mi. Nísinsin yìí, Èmi yóò fa gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ fún Nebukadnessari ọba Babeli ìránṣẹ́ mi; Èmi yóò sì mú àwọn ẹranko búburú wọ̀n-ọn-nì jẹ́ tirẹ̀. Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóò máa sìn ín àti àwọn ọmọdọ́mọ rẹ̀ títí ilẹ̀ rẹ yóò fi dé; ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá ni yóò tẹríba fún.

“ ‘ “Ṣùgbọ́n tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan kò bá ní sin Nebukadnessari ọba Babeli, tàbí kí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní abẹ́ àjàgà rẹ̀; Èmi yóò fi ìyà jẹ orílẹ̀-èdè náà nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, ni Olúwa wí títí Èmi yóò fi run wọ́n nípa ọwọ́ rẹ̀. Nítorí náà, ẹ má ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí àwọn wòlíì yín, àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, àwọn tí ń rọ́ àlá fún un yín, àwọn oṣó yín, tàbí àwọn àjẹ́ yín tí wọ́n ń sọ fún un yín pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli.’ 10 Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún un yín èyí tí yóò mú u yín jìnnà réré kúrò ní ilẹ̀ yín; kí Èmi kí ó lè lé yín jáde, kí ẹ̀yin ó sì ṣègbé. 11 Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kankan bá tẹ orí rẹ̀ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, tí ó sì sìn ín, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà wà lórí ilẹ̀ rẹ̀ láti máa ro ó, àti láti máa gbé ibẹ̀ ni Olúwa wí.” ’ ”

12 Èmi sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Sedekiah ọba Juda wí pé: “Tẹ orí rẹ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, sìn ín ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ yóò sì yè. 13 Kí ló dé tí ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, èyí tí Olúwa fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bá sin ọba Babeli? 14 Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tí ó ń sọ wí pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli,’ nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín. 15 ‘Èmi kò rán wọn ni Olúwa wí. Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Nítorí náà, Èmi yóò lé wọn, wọn yóò sì ṣègbé, ẹ̀yin pẹ̀lú àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín.’ ”

16 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: Ẹ má ṣe fetí sí nǹkan tí àwọn wòlíì ń sọ pé, ‘Láìpẹ́ ohun èlò ilé Olúwa ni a ó kó padà láti Babeli,’ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ. Ẹ má tẹ́tí sí wọn. 17 Má ṣe tẹ́tí sí wọn, ẹ máa sin ọba Babeli, ẹ̀yin yóò sì yè. Èéṣe tí ìlú yóò fi di ahoro? 18 Tí wọ́n bá jẹ́ wòlíì, tí wọ́n sì ní ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ kí wọ́n bẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun kí a má ṣe kó ohun èlò tí ó kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti Jerusalẹmu lọ sí Babeli. 19 Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ nípa àwọn opó, omi Òkun ní ti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti ní ti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní ìlú náà. 20 Èyí tí Nebukadnessari ọba Babeli kò kó lọ nígbà tí ó mú Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Juda àti Jerusalẹmu. 21 Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti ní Jerusalẹmu: 22 ‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Babeli, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, Èmi yóò mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’ ”

Judah to Serve Nebuchadnezzar

27 Early in the reign of Zedekiah[a](A) son of Josiah king of Judah, this word came to Jeremiah from the Lord: This is what the Lord said to me: “Make a yoke(B) out of straps and crossbars and put it on your neck. Then send(C) word to the kings of Edom, Moab, Ammon,(D) Tyre and Sidon(E) through the envoys who have come to Jerusalem to Zedekiah king of Judah. Give them a message for their masters and say, ‘This is what the Lord Almighty, the God of Israel, says: “Tell this to your masters: With my great power and outstretched arm(F) I made(G) the earth and its people and the animals(H) that are on it, and I give(I) it to anyone I please. Now I will give all your countries into the hands of my servant(J) Nebuchadnezzar(K) king of Babylon; I will make even the wild animals subject to him.(L) All nations will serve(M) him and his son and his grandson until the time(N) for his land comes; then many nations and great kings will subjugate(O) him.

“‘“If, however, any nation or kingdom will not serve Nebuchadnezzar king of Babylon or bow its neck under his yoke, I will punish(P) that nation with the sword,(Q) famine(R) and plague,(S) declares the Lord, until I destroy it by his hand. So do not listen to your prophets,(T) your diviners,(U) your interpreters of dreams,(V) your mediums(W) or your sorcerers(X) who tell you, ‘You will not serve(Y) the king of Babylon.’ 10 They prophesy lies(Z) to you that will only serve to remove(AA) you far from your lands; I will banish you and you will perish. 11 But if any nation will bow its neck under the yoke(AB) of the king of Babylon and serve him, I will let that nation remain in its own land to till it and to live(AC) there, declares the Lord.”’”

12 I gave the same message to Zedekiah king of Judah. I said, “Bow your neck under the yoke(AD) of the king of Babylon; serve him and his people, and you will live.(AE) 13 Why will you and your people die(AF) by the sword, famine and plague(AG) with which the Lord has threatened any nation that will not serve the king of Babylon? 14 Do not listen(AH) to the words of the prophets(AI) who say to you, ‘You will not serve the king of Babylon,’ for they are prophesying lies(AJ) to you. 15 ‘I have not sent(AK) them,’ declares the Lord. ‘They are prophesying lies in my name.(AL) Therefore, I will banish you and you will perish,(AM) both you and the prophets who prophesy to you.’”

16 Then I said to the priests and all these people, “This is what the Lord says: Do not listen to the prophets who say, ‘Very soon now the articles(AN) from the Lord’s house will be brought back from Babylon.’ They are prophesying lies to you. 17 Do not listen(AO) to them. Serve the king of Babylon, and you will live.(AP) Why should this city become a ruin? 18 If they are prophets and have the word of the Lord, let them plead(AQ) with the Lord Almighty that the articles remaining in the house of the Lord and in the palace of the king of Judah and in Jerusalem not be taken to Babylon. 19 For this is what the Lord Almighty says about the pillars, the bronze Sea,(AR) the movable stands and the other articles(AS) that are left in this city, 20 which Nebuchadnezzar king of Babylon did not take away when he carried(AT) Jehoiachin[b](AU) son of Jehoiakim king of Judah into exile from Jerusalem to Babylon, along with all the nobles of Judah and Jerusalem— 21 yes, this is what the Lord Almighty, the God of Israel, says about the things that are left in the house of the Lord and in the palace of the king of Judah and in Jerusalem: 22 ‘They will be taken(AV) to Babylon and there they will remain until the day(AW) I come for them,’ declares the Lord. ‘Then I will bring(AX) them back and restore them to this place.’”

Footnotes

  1. Jeremiah 27:1 A few Hebrew manuscripts and Syriac (see also 27:3,12 and 28:1); most Hebrew manuscripts Jehoiakim (Most Septuagint manuscripts do not have this verse.)
  2. Jeremiah 27:20 Hebrew Jeconiah, a variant of Jehoiachin