Add parallel Print Page Options

(A)“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí,
    “tí Èmi yóò gbé ẹ̀ka òdodo dìde fún Dafidi,
ọba tí yóò lo ìjọba pẹ̀lú ọgbọ́n
    tí yóò sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ lórí ilẹ̀ náà.

Read full chapter

Ọba sioni ń bọ̀

(A)Kún fún ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni,
    hó ìhó ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu:
Wo ọba rẹ ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ:
    òdodo ni òun, ó sì ní ìgbàlà;
    ó ní ìrẹ̀lẹ̀, ó sì ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
    àní ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.

Read full chapter

(A)Pilatu sì bi í léèrè, ó ni, “Ṣe ìwọ ni ọba àwọn Júù?”

Jesu sì dáhùn pé, “gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti wí náà ni.”

Read full chapter

49 (A)Nígbà náà ni Natanaeli sọ ọ́ gbangba pé, “Rabbi, ìwọ ni ọmọ Ọlọ́run; Ìwọ ni ọba Israẹli.”

Read full chapter

17 “Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí,
    Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́.
Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu;
    yóò yọ jáde láti Israẹli.
Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu,
    yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.

Read full chapter