Jeremiah 17:11
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
11 Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni
ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni
ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀
ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní
òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
Jobu 27:8
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
8 Nítorí kí ni ìrètí àgàbàgebè,
nígbà tí Ọlọ́run bá ké ẹ̀mí rẹ̀ kúrò, nígbà tí ó sì fà á jáde?
Saamu 39:6
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
6 “Nítòótọ́ ni olúkúlùkù ń rìn kiri bí òjìji.
Nítòótọ́ ni wọ́n ń yọ ara wọn lẹ́nu lórí asán;
wọ́n ń kó ọrọ̀ jọ,
wọn kò sì mọ ẹni tí yóò ko lọ.
Luku 12:33-34
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
33 (A)Ẹ ta ohun tí ẹ̀yin ní, kí ẹ sì tọrẹ àánú kí ẹ sì pèsè àpò fún ara yín, tí kì í gbó, ìṣúra ní ọ̀run tí kì í tán, ní ibi tí olè kò lè súnmọ́, àti ibi tí kòkòrò kì í bà á jẹ́. 34 Nítorí ní ibi tí ìṣúra yín gbé wà, níbẹ̀ ni ọkàn yín yóò gbé wà pẹ̀lú.
Read full chapterCopyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.