Add parallel Print Page Options

Owe aṣọ funfun

13 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ kí o sì ra àmùrè aṣọ ọ̀gbọ̀, kí o sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o má sì ṣe jẹ́ kí omi kí ó kàn án.” Bẹ́ẹ̀ ni mo ra àmùrè gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí, mo sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ mi.

Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá nígbà kejì: Mú àmùrè tí o rà, kí o sì fiwé ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o sì lọ sí Perati, kí o lọ pa á mọ́ sí pàlàpálá òkúta. Nígbà náà ni mo lọ pa á mọ́ ní Perati gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí fún mi.

Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, Olúwa sọ fún mi: Lọ sí Perati kí o lọ mú àmùrè tí mo ní kí o pamọ́ síbẹ̀. Nígbà náà ni mo lọ sí Perati mo lọ wá àmùrè mi níbi tí mo pa á mọ́ sí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àmùrè náà ti bàjẹ́, kò sì wúlò fún ohunkóhun mọ́.

Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé: “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Bákan náà ni èmi yóò run ìgbéraga Juda àti ìgbéraga ńlá ti Jerusalẹmu. 10 Àwọn ènìyàn búburú tí ó kùnà láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí wọ́n ń lo agídí ọkàn wọn, tí ó sì ń rìn tọ àwọn òrìṣà láti sìn wọ́n, àti láti foríbalẹ̀ fún wọn, yóò sì dàbí àmùrè yìí tí kò wúlò fún ohunkóhun. 11 Nítorí bí a ti lẹ àmùrè mọ́ ẹ̀gbẹ́ ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni a lẹ agbo ilé Israẹli àti gbogbo ilé Juda mọ́ mi,’ ni Olúwa wí, ‘kí wọn kí ó lè jẹ́ ènìyàn ògo àti ìyìn fún mi, ṣùgbọ́n wọn kò fẹ́ gbọ́.’

Ọtí Wáìnì

12 “Sọ fún wọn, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí: Gbogbo ìgò ni à ó fi ọtí wáìnì kún.’ Bí wọ́n bá sì sọ fún ọ pé, ‘Ṣé a kò mọ̀ pé gbogbo ìgò ni ó yẹ láti bu ọtí wáìnì kún?’ 13 Nítorí náà sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò fi ìmutípara kún gbogbo olùgbé ilẹ̀ yìí pẹ̀lú ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì gbogbo àwọn tó ń gbé ní Jerusalẹmu. 14 Èmi yóò ti èkínní lu èkejì, àwọn baba àti ọmọkùnrin pọ̀ ni Olúwa wí: Èmi kì yóò dáríjì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú, èmi kì yóò ṣe ìyọ́nú láti máa pa wọ́n run.’ ”

Ìkìlọ̀ oko ẹrú

15 Gbọ́ kí o sì fetísílẹ̀,
    ẹ má ṣe gbéraga,
    nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
16 Ẹ fi ògo fún Olúwa Ọlọ́run yín,
    kí ó tó mú òkùnkùn wá,
àti kí ó tó mú ẹsẹ̀ yín tàsé
    lórí òkè tí ó ṣókùnkùn,
Nígbà tí ẹ̀yin sì ń retí ìmọ́lẹ̀,
    òun yóò sọ ọ́ di òjìji yóò sì ṣe bi òkùnkùn biribiri.
17 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fetísílẹ̀,
    Èmi yóò sọkún ní ìkọ̀kọ̀
nítorí ìgbéraga yín;
    Ojú mi yóò sun ẹkún kíkorò,
tí omi ẹkún, yóò sì máa sàn jáde,
    nítorí a kó agbo Olúwa lọ ìgbèkùn.

18 Sọ fún ọba àti ayaba pé,
    “Ẹ rẹ ara yín sílẹ̀,
ẹ sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ yín,
    adé ògo yín bọ́ sí ilẹ̀ láti orí yín.”
19 Àwọn ìlú tí ó wà ní gúúsù ni à ó tì pa,
    kò sì ní sí ẹnikẹ́ni láti ṣí wọn.
Gbogbo Juda ni a ó kó lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn,
    gbogbo wọn ni a ó kó lọ ní ìgbèkùn pátápátá.

20 Gbé ojú rẹ sókè,
    kí o sì wo àwọn tí ó ń bọ̀ láti àríwá.
Níbo ni agbo ẹran tí a fi sí abẹ́ àkóso rẹ wà;
    àgùntàn tí ò ń mú yangàn.
21 Kí ni ìwọ yóò wí nígbà tí Olúwa bá dúró lórí rẹ
    àwọn tí o mú bí ọ̀rẹ́ àtàtà.
Ǹjẹ́ kò ní jẹ́ ìrora fún ọ
    bí aboyún tó ń rọbí?
22 Tí o bá sì bi ara rẹ léèrè
    “Kí ni ìdí rẹ̀ tí èyí fi ṣẹlẹ̀ sí mi?”
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ tí o ṣẹ̀
    ni aṣọ rẹ fi fàya
    tí a sì ṣe é ní ìṣekúṣe.
23 Ǹjẹ́ Etiopia le yí àwọ̀ rẹ̀ padà?
    Tàbí ẹkùn lè yí àwọ̀ rẹ̀ padà?
Bí èyí kò ti lè rí bẹ́ẹ̀
    náà ni ẹ̀yin tí ìwà búburú bá ti mọ́ lára kò lè ṣe rere.

24 “N ó fọ́n ọn yín ká bí i ìyàngbò
    tí ẹ̀fúùfù ilẹ̀ aṣálẹ̀ ń fẹ́.
25 Èyí ni ìpín tìrẹ;
    tí mo ti fi sílẹ̀ fún ọ,”
    ni Olúwa wí,
“Nítorí ìwọ ti gbàgbé mi
    o sì gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọlọ́run àjèjì.
26 N ó sí aṣọ lójú rẹ,
    kí ẹ̀sín rẹ le hàn síta—
27 ìwà àgbèrè àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́,
    àìlójútì panṣágà rẹ!
Mo ti rí ìwà ìríra rẹ,
    lórí òkè àti ní pápá.
Ègbé ni fún ọ ìwọ Jerusalẹmu!
    Yóò ti pẹ́ tó tí o ó fi máa wà ní àìmọ́?”

A Linen Belt

13 This is what the Lord said to me: “Go and buy a linen belt and put it around your waist, but do not let it touch water.” So I bought a belt, as the Lord directed, and put it around my waist.

Then the word of the Lord came to me a second time:(A) “Take the belt you bought and are wearing around your waist, and go now to Perath[a](B) and hide it there in a crevice in the rocks.” So I went and hid it at Perath, as the Lord told me.(C)

Many days later the Lord said to me, “Go now to Perath and get the belt I told you to hide there.” So I went to Perath and dug up the belt and took it from the place where I had hidden it, but now it was ruined and completely useless.

Then the word of the Lord came to me: “This is what the Lord says: ‘In the same way I will ruin the pride of Judah and the great pride(D) of Jerusalem. 10 These wicked people, who refuse to listen(E) to my words, who follow the stubbornness of their hearts(F) and go after other gods(G) to serve and worship them,(H) will be like this belt—completely useless!(I) 11 For as a belt is bound around the waist, so I bound all the people of Israel and all the people of Judah to me,’ declares the Lord, ‘to be my people for my renown(J) and praise and honor.(K) But they have not listened.’(L)

Wineskins

12 “Say to them: ‘This is what the Lord, the God of Israel, says: Every wineskin should be filled with wine.’ And if they say to you, ‘Don’t we know that every wineskin should be filled with wine?’ 13 then tell them, ‘This is what the Lord says: I am going to fill with drunkenness(M) all who live in this land, including the kings who sit on David’s throne, the priests, the prophets and all those living in Jerusalem. 14 I will smash them one against the other, parents and children alike, declares the Lord. I will allow no pity(N) or mercy or compassion(O) to keep me from destroying(P) them.’”

Threat of Captivity

15 Hear and pay attention,
    do not be arrogant,
    for the Lord has spoken.(Q)
16 Give glory(R) to the Lord your God
    before he brings the darkness,
before your feet stumble(S)
    on the darkening hills.
You hope for light,
    but he will turn it to utter darkness
    and change it to deep gloom.(T)
17 If you do not listen,(U)
    I will weep in secret
    because of your pride;
my eyes will weep bitterly,
    overflowing with tears,(V)
    because the Lord’s flock(W) will be taken captive.(X)

18 Say to the king(Y) and to the queen mother,(Z)
    “Come down from your thrones,
for your glorious crowns(AA)
    will fall from your heads.”
19 The cities in the Negev will be shut up,
    and there will be no one to open them.
All Judah(AB) will be carried into exile,
    carried completely away.

20 Look up and see
    those who are coming from the north.(AC)
Where is the flock(AD) that was entrusted to you,
    the sheep of which you boasted?
21 What will you say when the Lord sets over you
    those you cultivated as your special allies?(AE)
Will not pain grip you
    like that of a woman in labor?(AF)
22 And if you ask yourself,
    “Why has this happened to me?”(AG)
it is because of your many sins(AH)
    that your skirts have been torn off(AI)
    and your body mistreated.(AJ)
23 Can an Ethiopian[b] change his skin
    or a leopard its spots?
Neither can you do good
    who are accustomed to doing evil.(AK)

24 “I will scatter you like chaff(AL)
    driven by the desert wind.(AM)
25 This is your lot,
    the portion(AN) I have decreed for you,”
declares the Lord,
“because you have forgotten(AO) me
    and trusted in false gods.(AP)
26 I will pull up your skirts over your face
    that your shame may be seen(AQ)
27 your adulteries and lustful neighings,
    your shameless prostitution!(AR)
I have seen your detestable acts
    on the hills and in the fields.(AS)
Woe to you, Jerusalem!
    How long will you be unclean?”(AT)

Footnotes

  1. Jeremiah 13:4 Or possibly to the Euphrates; similarly in verses 5-7
  2. Jeremiah 13:23 Hebrew Cushite (probably a person from the upper Nile region)