Add parallel Print Page Options

Ọ̀rọ̀ Jeremiah

12 Olúwa, olódodo ni ọ́ nígbàkúgbà,
    nígbà tí mo mú ẹjọ́ kan tọ̀ ọ́ wá.
Síbẹ̀ èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀ nípa òdodo rẹ.
    Èéṣe tí ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú fi ń ṣe déédé?
    Èéṣe tí gbogbo àwọn aláìṣòdodo sì ń gbé ní ìrọ̀rùn?
Ó ti gbìn wọ́n, wọ́n sì ti fi egbò múlẹ̀,
    wọ́n dàgbà wọ́n sì so èso.
Gbogbo ìgbà ni ó wà ní ètè wọn,
    o jìnnà sí ọkàn wọn.
Síbẹ̀ o mọ̀ mí ní Olúwa,
    o ti rí mi o sì ti dán èrò mi nípa rẹ wò.
Wọ, wọ́n lọ bí àgùntàn tí a fẹ́ pa.
    Yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ pípa.
Yóò ti pẹ́ tó tí ọ̀gbẹlẹ̀ yóò fi wà,
    tí gbogbo ewéko igbó sì ń rọ?
Nítorí àwọn ènìyàn búburú ni ó ń gbé ibẹ̀.
    Àwọn ẹranko àti àwọn ẹyẹ ti ṣègbé,
pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ènìyàn ń sọ pé,
    “Kò lè rí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wa.”

Ìdáhùn Ọlọ́run

Bí ìwọ bá ń bá ẹlẹ́ṣẹ̀ sáré,
    tí àárẹ̀ sì mú ọ,
báwo ni ìwọ yóò ṣe bá ẹṣin díje?
    Bí ìwọ bá kọsẹ̀ ní ilẹ̀ àlàáfíà,
    bí ìwọ bá ní ìgbẹ́kẹ̀lé,
    kí ni ìwọ ó ṣe nínú ẹkùn odò Jordani?
Àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn
    ìdílé—
ti dà ọ́, kódà wọ́n ti kẹ̀yìn sí ọ
    Wọ́n ti hó lé ọ lórí;
Má ṣe gbà wọ́n gbọ́
    bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ń sọ̀rọ̀ rẹ dáradára.

Èmi yóò kọ ilé mi sílẹ̀,
    èmi yóò fi ìní mi sílẹ̀.
Èmi yóò fi ẹni tí mo fẹ́
    lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.
Ogún mi ti rí sí mi
    bí i kìnnìún nínú igbó.
Ó ń bú ramúramù mọ́ mi;
    nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.
Ogún mi kò ha ti rí sí mi
    bí ẹyẹ kannakánná
tí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ dòyì ka, tí wọ́n sì kọjú ìjà sí i?
    Ẹ lọ, kí ẹ sì kó gbogbo ẹranko igbó jọ,
    ẹ mú wọn wá jẹ.
10 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùṣọ́-àgùntàn ni yóò sì ba ọgbà àjàrà mi jẹ́,
    tí wọn yóò sì tẹ oko mi mọ́lẹ̀;
Wọ́n ó sọ oko dídára mi di
    ibi tí a ń da ìdọ̀tí sí.
11 A ó sọ ọ́ di aṣálẹ̀ ilẹ̀
    tí kò wúlò níwájú mi,
gbogbo ilẹ̀ ni yóò di ahoro
    nítorí kò sí ẹnìkankan tí yóò náání.
12 Gbogbo ibi gíga tí ó wà nínú aṣálẹ̀
    ni àwọn apanirun ti gorí,
nítorí idà Olúwa yóò pa
    láti ìkangun kìn-ín-ní dé ìkangun èkejì ilẹ̀ náà;
    kò sí àlàáfíà fún gbogbo alààyè.
13 Àlìkámà ni wọn yóò gbìn, ṣùgbọ́n ẹ̀gún ni wọn yóò ká,
    wọn yóò fi ara wọn ṣe wàhálà, ṣùgbọ́n òfo ni èrè wọn.
Kí ojú kí ó tì yín nítorí èrè yín,
    nítorí ìbínú gbígbóná Olúwa.

14 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ní ti gbogbo àwọn aládùúgbò mi búburú tí wọ́n gbẹ́sẹ̀ lé ogún tí mo fún àwọn ènìyàn Israẹli mi, Èmi yóò fà wọ́n tu kúrò lórí ilẹ̀ wọn, èmi yóò fa ìdílé Juda tu kúrò ní àárín wọn. 15 Ṣùgbọ́n tí mo bá fà wọ́n tu tán, Èmi yóò padà yọ́nú sí wọn. Èmi yóò sì padà fún oníkálùkù ní ogún ìní rẹ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ ìní oníkálùkù. 16 Bí wọ́n bá sì kọ ìwà àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì fi orúkọ mi búra wí pé, ‘níwọ̀n bí Olúwa ń bẹ láààyè,’ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ́ àwọn ènìyàn mi láti fi Baali búra, nígbà náà ni a ó gbé wọn ró láàrín àwọn ènìyàn mi. 17 Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kan kò bá gbọ́, Èmi yóò fà á tu pátápátá, èmi yóò sì pa wọ́n run,” ni Olúwa wí.

Jeremiah’s Complaint

12 You are always righteous,(A) Lord,
    when I bring a case(B) before you.
Yet I would speak with you about your justice:(C)
    Why does the way of the wicked prosper?(D)
    Why do all the faithless live at ease?
You have planted(E) them, and they have taken root;
    they grow and bear fruit.(F)
You are always on their lips
    but far from their hearts.(G)
Yet you know me, Lord;
    you see me and test(H) my thoughts about you.
Drag them off like sheep(I) to be butchered!
    Set them apart for the day of slaughter!(J)
How long will the land lie parched(K)
    and the grass in every field be withered?(L)
Because those who live in it are wicked,
    the animals and birds have perished.(M)
Moreover, the people are saying,
    “He will not see what happens to us.”

God’s Answer

“If you have raced with men on foot
    and they have worn you out,
    how can you compete with horses?
If you stumble[a] in safe country,
    how will you manage in the thickets(N) by[b] the Jordan?
Your relatives, members of your own family—
    even they have betrayed you;
    they have raised a loud cry against you.(O)
Do not trust them,
    though they speak well of you.(P)

“I will forsake(Q) my house,
    abandon(R) my inheritance;
I will give the one I love(S)
    into the hands of her enemies.(T)
My inheritance has become to me
    like a lion(U) in the forest.
She roars at me;
    therefore I hate her.(V)
Has not my inheritance become to me
    like a speckled bird of prey
    that other birds of prey surround and attack?
Go and gather all the wild beasts;
    bring them to devour.(W)
10 Many shepherds(X) will ruin my vineyard
    and trample down my field;
they will turn my pleasant field
    into a desolate wasteland.(Y)
11 It will be made a wasteland,(Z)
    parched and desolate before me;(AA)
the whole land will be laid waste
    because there is no one who cares.
12 Over all the barren heights in the desert
    destroyers will swarm,
for the sword(AB) of the Lord(AC) will devour(AD)
    from one end of the land to the other;(AE)
    no one will be safe.(AF)
13 They will sow wheat but reap thorns;
    they will wear themselves out but gain nothing.(AG)
They will bear the shame of their harvest
    because of the Lord’s fierce anger.”(AH)

14 This is what the Lord says: “As for all my wicked neighbors who seize the inheritance(AI) I gave my people Israel, I will uproot(AJ) them from their lands and I will uproot(AK) the people of Judah from among them. 15 But after I uproot them, I will again have compassion(AL) and will bring(AM) each of them back to their own inheritance and their own country. 16 And if they learn(AN) well the ways of my people and swear by my name, saying, ‘As surely as the Lord lives’(AO)—even as they once taught my people to swear by Baal(AP)—then they will be established among my people.(AQ) 17 But if any nation does not listen, I will completely uproot and destroy(AR) it,” declares the Lord.

Footnotes

  1. Jeremiah 12:5 Or you feel secure only
  2. Jeremiah 12:5 Or the flooding of