Add parallel Print Page Options

Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda, Àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.

Ìpè Jeremiah

Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,

(A)Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n,
    kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀.
    Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.

Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”

Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.” (B)Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.

Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ 10 (C)Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.

11 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé:

“Kí ni o rí Jeremiah?”

Mo sì dáhùn wí pé “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”

12 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”

13 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.

14 Olúwa, sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà. 15 Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí.

Àwọn ọba wọn yóò wá
    gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé
Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo
    àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn
    ìlú Juda.
16 Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi
    nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀,
nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn
    àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.

17 “Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn. 18 Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà. 19 Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.

The words of Jeremiah son of Hilkiah, one of the priests at Anathoth(A) in the territory of Benjamin. The word of the Lord came(B) to him in the thirteenth year of the reign of Josiah(C) son of Amon king of Judah, and through the reign of Jehoiakim(D) son of Josiah king of Judah, down to the fifth month of the eleventh year of Zedekiah(E) son of Josiah king of Judah, when the people of Jerusalem went into exile.(F)

The Call of Jeremiah

The word of the Lord came to me, saying,

“Before I formed you in the womb(G) I knew[a](H) you,
    before you were born(I) I set you apart;(J)
    I appointed you as a prophet to the nations.(K)

“Alas, Sovereign Lord,” I said, “I do not know how to speak;(L) I am too young.”(M)

But the Lord said to me, “Do not say, ‘I am too young.’ You must go to everyone I send you to and say whatever I command you. Do not be afraid(N) of them, for I am with you(O) and will rescue(P) you,” declares the Lord.(Q)

Then the Lord reached out his hand and touched(R) my mouth and said to me, “I have put my words in your mouth.(S) 10 See, today I appoint you over nations(T) and kingdoms to uproot(U) and tear down, to destroy and overthrow, to build and to plant.”(V)

11 The word of the Lord came to me: “What do you see, Jeremiah?”(W)

“I see the branch of an almond tree,” I replied.

12 The Lord said to me, “You have seen correctly, for I am watching[b](X) to see that my word is fulfilled.”

13 The word of the Lord came to me again: “What do you see?”(Y)

“I see a pot that is boiling,” I answered. “It is tilting toward us from the north.”

14 The Lord said to me, “From the north(Z) disaster will be poured out on all who live in the land. 15 I am about to summon all the peoples of the northern kingdoms,” declares the Lord.

“Their kings will come and set up their thrones
    in the entrance of the gates of Jerusalem;
they will come against all her surrounding walls
    and against all the towns of Judah.(AA)
16 I will pronounce my judgments(AB) on my people
    because of their wickedness(AC) in forsaking me,(AD)
in burning incense to other gods(AE)
    and in worshiping(AF) what their hands have made.(AG)

17 “Get yourself ready! Stand up and say(AH) to them whatever I command you. Do not be terrified(AI) by them, or I will terrify you before them. 18 Today I have made you(AJ) a fortified city, an iron pillar and a bronze wall to stand against the whole land—against the kings of Judah, its officials, its priests and the people of the land. 19 They will fight against you but will not overcome(AK) you, for I am with you(AL) and will rescue(AM) you,” declares the Lord.

Footnotes

  1. Jeremiah 1:5 Or chose
  2. Jeremiah 1:12 The Hebrew for watching sounds like the Hebrew for almond tree.