Add parallel Print Page Options

Ọjọ́ ẹ̀san àti ìràpadà Ọlọ́run

63 (A)Ta nì eléyìí tí ó Edomu wá,
    ti òun ti aṣọ àrẹpọ́n láti Bosra wá?
Ta nì eléyìí, tí ó ní ògo nínú aṣọ rẹ̀,
    tí ó ń yan bọ̀ wá nínú ọláńlá agbára rẹ̀?

    “Èmi ni ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ nínú òdodo
    tí ó ní ipa láti gbàlà.”

Èéṣe tí aṣọ yín fi pupa
    gẹ́gẹ́ bí i tàwọn tí ń ṣiṣẹ́ ní ìfúntí?

(B)“Èmi nìkan ti dá tẹ ìfúntí wáìnì;
    láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹnikẹ́ni kò sì wà pẹ̀lú mi.
Mo tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ ní ìbínú mi
    mo sì tẹ̀ wọ́n rẹ́ ní ìrunú mi
ẹ̀jẹ̀ wọn sì fọ́n sí aṣọ mi,
    mo sì da àbàwọ́n sí gbogbo aṣọ mi.
Nítorí ọjọ́ ẹ̀san wà ní ọkàn mi
    àti pé ọdún ìràpadà mi ti dé
Mo wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti ṣe ìrànwọ́.
    Àyà fò mí pé ẹnikẹ́ni kò ṣèrànwọ́;
nítorí náà apá mi ni ó ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún mi
    àti ìrunú mi ni ó gbé mi ró.
Mo tẹ orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀ nínú ìbínú mi;
    nínú ìrunú mi mo jẹ́ kí wọ́n mu
    mo sì da ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ lórí erùpẹ̀.”

Ìyìn àti àdúrà

Èmi yóò sọ nípa àánú Olúwa
    ìṣe rẹ gbogbo tí ó yẹ kí a yìn ín fún,
gẹ́gẹ́ bí ohun tí Olúwa ti ṣe fún wa
    bẹ́ẹ̀ ni, ohun rere gbogbo tí ó ti ṣe
fún ilé Israẹli
    gẹ́gẹ́ bí àánú àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore rẹ̀.
Ó wí pé, “Lóòtítọ́ ènìyàn mi ni wọ́n,
    àwọn ọmọ tí kì yóò jẹ́ òpùrọ́ fún mi”;
    bẹ́ẹ̀ ni, ó sì di Olùgbàlà wọn.
Nínú gbogbo ìpọ́njú wọn, inú òun pẹ̀lú bàjẹ́
    àti angẹli tí ó wà níwájú rẹ̀ gbà wọ́n là.
Nínú ìfẹ́ àti àánú rẹ̀, ó rà wọ́n padà;
    ó gbé wọn sókè ó sì pọ̀n wọ́n
    ní gbogbo ọjọ́ ìgbà n nì.
10 Síbẹ̀síbẹ̀ wọ́n ṣọ̀tẹ̀
    wọ́n sì ba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ nínú jẹ́.
Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà ó sì di ọ̀tá wọn
    òun tìkára rẹ̀ sì bá wọn jà.

11 (C)Lẹ́yìn náà ni àwọn ènìyàn rẹ̀ rántí ọjọ́ ìgbà n nì,
    àwọn ọjọ́ Mose àti àwọn ènìyàn rẹ̀
níbo ni ẹni náà wà tí ó mú wọn la Òkun já,
    pẹ̀lú olùṣọ́-àgùntàn agbo ẹran rẹ̀?
Níbo ni ẹni náà wà tí ó rán
    Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ sáàrín wọn,
12 ta ni ó rán apá ògo ti agbára rẹ̀
    láti wà ní apá ọ̀tún Mose,
ta ni ó pín omi ní yà níwájú wọn,
    láti gba òkìkí ayérayé fún ara rẹ̀,
13 ta ni ó síwájú wọn la àwọn ọ̀gbun nì já?
    Gẹ́gẹ́ bí ẹṣin ni gbangba ìlú wọn tí kò sì kọsẹ̀;
14 gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran tí ó lọ sí pápá oko,
    a fún wọn ní ìsinmi láti ọwọ́ Ẹ̀mí Olúwa.
Báyìí ni ẹ ṣe tọ́ àwọn ènìyàn yín
    láti fún ara yín ní orúkọ kan tí ó lógo.

15 Bojú wolẹ̀ láti ọ̀run kí o sì rí i
    láti ìtẹ́ ògo rẹ, mímọ́ àti ológo.
Níbo ni ìtara àti agbára rẹ wà?
    Ìwà jẹ́ẹ́jẹ́ rẹ àti àánú rẹ ni a
    ti mú kúrò níwájú wa.
16 Ṣùgbọ́n ìwọ ni baba wa,
    bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Abrahamu kò mọ̀ wá
tàbí Israẹli mọ ẹni tí à á ṣe;
    ìwọ, Olúwa ni Baba wa,
    Olùràpadà wa láti ìgbà n nì ni orúkọ rẹ.
17 Èéṣe Olúwa tí o fi jẹ́ kí a ṣáko kúrò ní ojú ọ̀nà rẹ
    tí o sì ṣé àyà wa le tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi bọ̀wọ̀ fún ọ?
Padà nítorí àwọn ìránṣẹ́ rẹ,
    àwọn ẹ̀yà tí ṣe ogún ìní rẹ.
18 Fún ìgbà díẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ fi gba ibi mímọ́ rẹ,
    ṣùgbọ́n nísinsin yìí àwọn ọ̀tá wa ti tẹ ibi mímọ́ rẹ mọ́lẹ̀.
19 Àwa jẹ́ tìrẹ láti ìgbà n nì;
    ṣùgbọ́n ìwọ kò tí ì jẹ ọba lé wọn lórí,
    a kò sì tí ì pè wọ́n mọ́ orúkọ rẹ.

God’s Day of Vengeance and Redemption

63 Who is this coming from Edom,(A)
    from Bozrah,(B) with his garments stained crimson?(C)
Who is this, robed in splendor,
    striding forward in the greatness of his strength?(D)

“It is I, proclaiming victory,
    mighty to save.”(E)

Why are your garments red,
    like those of one treading the winepress?(F)

“I have trodden the winepress(G) alone;
    from the nations no one was with me.
I trampled(H) them in my anger
    and trod them down in my wrath;(I)
their blood spattered my garments,(J)
    and I stained all my clothing.
It was for me the day of vengeance;(K)
    the year for me to redeem had come.
I looked, but there was no one(L) to help,
    I was appalled that no one gave support;
so my own arm(M) achieved salvation for me,
    and my own wrath sustained me.(N)
I trampled(O) the nations in my anger;
    in my wrath I made them drunk(P)
    and poured their blood(Q) on the ground.”

Praise and Prayer

I will tell of the kindnesses(R) of the Lord,
    the deeds for which he is to be praised,
    according to all the Lord has done for us—
yes, the many good things(S)
    he has done for Israel,
    according to his compassion(T) and many kindnesses.
He said, “Surely they are my people,(U)
    children who will be true to me”;
    and so he became their Savior.(V)
In all their distress he too was distressed,
    and the angel(W) of his presence(X) saved them.[a]
In his love and mercy he redeemed(Y) them;
    he lifted them up and carried(Z) them
    all the days of old.(AA)
10 Yet they rebelled(AB)
    and grieved his Holy Spirit.(AC)
So he turned and became their enemy(AD)
    and he himself fought(AE) against them.

11 Then his people recalled[b] the days of old,
    the days of Moses and his people—
where is he who brought them through the sea,(AF)
    with the shepherd of his flock?(AG)
Where is he who set
    his Holy Spirit(AH) among them,
12 who sent his glorious arm(AI) of power
    to be at Moses’ right hand,
who divided the waters(AJ) before them,
    to gain for himself everlasting renown,(AK)
13 who led(AL) them through the depths?(AM)
Like a horse in open country,
    they did not stumble;(AN)
14 like cattle that go down to the plain,
    they were given rest(AO) by the Spirit of the Lord.
This is how you guided your people
    to make for yourself a glorious name.

15 Look down from heaven(AP) and see,
    from your lofty throne,(AQ) holy and glorious.
Where are your zeal(AR) and your might?
    Your tenderness and compassion(AS) are withheld(AT) from us.
16 But you are our Father,(AU)
    though Abraham does not know us
    or Israel acknowledge(AV) us;
you, Lord, are our Father,
    our Redeemer(AW) from of old is your name.
17 Why, Lord, do you make us wander(AX) from your ways
    and harden our hearts(AY) so we do not revere(AZ) you?
Return(BA) for the sake of your servants,
    the tribes that are your inheritance.(BB)
18 For a little while(BC) your people possessed your holy place,
    but now our enemies have trampled(BD) down your sanctuary.(BE)
19 We are yours from of old;
    but you have not ruled over them,
    they have not been called[c] by your name.(BF)

Footnotes

  1. Isaiah 63:9 Or Savior in their distress. / It was no envoy or angel / but his own presence that saved them
  2. Isaiah 63:11 Or But may he recall
  3. Isaiah 63:19 Or We are like those you have never ruled, / like those never called