Add parallel Print Page Options

Ògo Sioni

60 “Dìde, tànmọ́lẹ̀, nítorí ìmọ́lẹ̀ rẹ ti dé,
    ògo Olúwa sì ràdàbò ọ́.
Kíyèsi i, òkùnkùn bo ilẹ̀ ayé
    òkùnkùn biribiri sì wà lórí àwọn ènìyàn,
ṣùgbọ́n Olúwa ràn bò ọ́
    ògo rẹ̀ sì farahàn lórí i rẹ.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá sí ìmọ́lẹ̀ rẹ,
    àti àwọn ọba sí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ rẹ.

“Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wò:
    Gbogbo wọn ṣa ara jọ pọ̀, wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ;
àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò wá láti ọ̀nà jíjìn,
    àwọn ọmọ rẹ obìnrin ni a ó tọ́jú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ.
Nígbà náà ni ìwọ yóò wò tí ojú rẹ yóò máa dán,
    ọkàn rẹ yó fò, yó sì kún fún ayọ̀;
ọrọ̀ inú Òkun ni a ó kò wá sọ́dọ̀ rẹ,
    sí ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá.
(A)Ọ̀wọ́ ìbákasẹ yóò bo gbogbo ilẹ̀ rẹ,
    àwọn ọ̀dọ́ ìbákasẹ Midiani àti Efani.
Àti gbogbo wọn láti Ṣeba yóò wá,
    wọn yóò mú wúrà àti tùràrí lọ́wọ́
    tí wọn yóò sì máa kéde ìyìn Olúwa.
Gbogbo agbo ẹran Kedari ni a ó kójọ sọ́dọ̀ rẹ,
    àwọn àgbò ti Nebaioti yóò sìn ọ́;
wọn yóò jẹ́ ọrẹ ìtẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi,
    bẹ́ẹ̀ ni n ó sì ṣe tẹmpili ògo mi lọ́ṣọ̀ọ́.

“Ta ni àwọn wọ̀nyí tí ń fò lọ bí i kurukuru,
    gẹ́gẹ́ bí àwọn àdàbà sí ìtẹ́ wọn?
Lóòtítọ́ àwọn erékùṣù bojú wò mí;
    ní ìṣíwájú ni àwọn ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi;
mú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn,
    pẹ̀lú fàdákà àti wúrà wọn,
fún ti ọlá Olúwa Ọlọ́run rẹ,
    Ẹni Mímọ́ Israẹli,
    nítorí òun ti fi ohun dídára ṣe ó lọ́ṣọ̀ọ́.

10 “Àwọn àjèjì yóò tún ògiri rẹ mọ
    àwọn ọba wọn yóò sì sìn ọ́.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ní ìbínú ni mo lù ọ́,
    ní àánú èmi yóò ṣe inú rere sí ọ.
11 (B)Gbogbo ẹnu-bodè rẹ ni yóò wà ní ṣíṣí sílẹ̀,
    a kì yóò tì wọ́n ní ọ̀sán àti ní òru,
tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ọkùnrin yóò le è kó
    ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè wá
tí àwọn ọba wọn yóò ṣáájú ní
    ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ìṣẹ́gun.
12 Nítorí pé orílẹ̀-èdè tàbí ilẹ̀ ọba tí kì yóò sìn ọ́ ni yóò parun;
    pátápátá ni yóò sì dahoro.

13 “Ògo Lebanoni yóò wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,
    igi junifa, firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀,
láti bu ọlá fún ilé ìsìn mi;
    àti pé èmi yóò sì ṣe ibi ẹsẹ̀ mi lógo.
14 (C)Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àwọn apọ́nilójú rẹ yóò
    wá foríbalẹ̀ fún ọ;
gbogbo àwọn tí ó ti kẹ́gàn rẹ ni wọn yóò tẹríba níwájú rẹ
    wọn yóò sì pè ọ́ ní ìlú Olúwa,
    Sioni ti Ẹni Mímọ́ Israẹli.

15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti kórìíra rẹ, a sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀,
    láìsí ẹnìkan tí ó ń gba ọ̀dọ̀ rẹ kọjá,
Èmi yóò ṣe ọ́ ní ìṣògo ayérayé
    àti ayọ̀ àtìrandíran.
16 Ìwọ yóò mu wàrà gbogbo orílẹ̀-èdè
    a ó sì fun ọ́ ni ọmú àwọn ọba.
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi Olúwa,
    èmi ni Olùgbàlà rẹ,
    Olùdáǹdè rẹ, Alágbára ti Jakọbu.
17 Dípò idẹ, èmi ó mú wúrà wá fún ọ,
    dípò fàdákà èmi ó mú irin wá. Dípò igi yóò mú idẹ wá fún ọ,
àti irin dípò òkúta.
    Èmi yóò fi àlàáfíà ṣe àwọn ìjòyè rẹ
    àti òdodo gẹ́gẹ́ bí alákòóso rẹ.
18 A kì yóò gbọ́ nípa rògbòdìyàn ní ilẹ̀ rẹ mọ́,
    tàbí ìdahoro àti ìparun nínú agbègbè rẹ,
ṣùgbọ́n ìwọ yóò pe ògiri rẹ ní ìgbàlà
    àti àwọn ẹnu-bodè rẹ ní ìyìn.
19 Òòrùn kì yóò sì jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ní ọ̀sán mọ́,
    tàbí kí ìtànṣán òṣùpá tún ràn sí ọ mọ́,
nítorí Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ayérayé,
    àti Ọlọ́run rẹ yóò jẹ́ ògo rẹ.
20 Òòrùn rẹ kì yóò sì wọ̀ mọ́,
    àti òṣùpá rẹ kì yóò sì wọ òòkùn mọ́;
Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ayérayé rẹ,
    àti àwọn ọjọ́ arò rẹ yóò sì dópin.
21 Lẹ́yìn náà ni gbogbo àwọn ènìyàn rẹ yóò di òdodo
    àwọn ni yóò sì jogún ilẹ̀ náà títí ayé.
Àwọn ni irúgbìn tí mo ti gbìn,
    iṣẹ́ ọwọ́ mi,
    láti fi ọláńlá mi hàn.
22 Èyí tí ó kéré jù nínú yín yóò di ẹgbẹ̀rún kan,
    èyí tí ó kéré yóò di orílẹ̀-èdè ńlá.
Èmi ni Olúwa;
    ní àkókò rẹ̀ Èmi yóò ṣe èyí kánkán.”

The Glory of Zion

60 “Arise,(A) shine, for your light(B) has come,
    and the glory(C) of the Lord rises upon you.
See, darkness(D) covers the earth
    and thick darkness(E) is over the peoples,
but the Lord rises upon you
    and his glory appears over you.
Nations(F) will come to your light,(G)
    and kings(H) to the brightness of your dawn.

“Lift up your eyes and look about you:
    All assemble(I) and come to you;
your sons come from afar,(J)
    and your daughters(K) are carried on the hip.(L)
Then you will look and be radiant,(M)
    your heart will throb and swell with joy;(N)
the wealth(O) on the seas will be brought to you,
    to you the riches of the nations will come.
Herds of camels(P) will cover your land,
    young camels of Midian(Q) and Ephah.(R)
And all from Sheba(S) will come,
    bearing gold and incense(T)
    and proclaiming the praise(U) of the Lord.
All Kedar’s(V) flocks will be gathered to you,
    the rams of Nebaioth will serve you;
they will be accepted as offerings(W) on my altar,(X)
    and I will adorn my glorious temple.(Y)

“Who are these(Z) that fly along like clouds,(AA)
    like doves to their nests?
Surely the islands(AB) look to me;
    in the lead are the ships of Tarshish,[a](AC)
bringing(AD) your children from afar,
    with their silver and gold,(AE)
to the honor(AF) of the Lord your God,
    the Holy One(AG) of Israel,
    for he has endowed you with splendor.(AH)

10 “Foreigners(AI) will rebuild your walls,
    and their kings(AJ) will serve you.
Though in anger I struck you,
    in favor(AK) I will show you compassion.(AL)
11 Your gates(AM) will always stand open,
    they will never be shut, day or night,
so that people may bring you the wealth of the nations(AN)
    their kings(AO) led in triumphal procession.
12 For the nation or kingdom that will not serve(AP) you will perish;
    it will be utterly ruined.(AQ)

13 “The glory of Lebanon(AR) will come to you,
    the juniper, the fir and the cypress together,(AS)
to adorn my sanctuary;(AT)
    and I will glorify the place for my feet.(AU)
14 The children of your oppressors(AV) will come bowing before you;
    all who despise you will bow down(AW) at your feet
and will call you the City(AX) of the Lord,
    Zion(AY) of the Holy One(AZ) of Israel.

15 “Although you have been forsaken(BA) and hated,
    with no one traveling(BB) through,
I will make you the everlasting pride(BC)
    and the joy(BD) of all generations.
16 You will drink the milk of nations
    and be nursed(BE) at royal breasts.
Then you will know(BF) that I, the Lord, am your Savior,(BG)
    your Redeemer,(BH) the Mighty One of Jacob.(BI)
17 Instead of bronze I will bring you gold,(BJ)
    and silver in place of iron.
Instead of wood I will bring you bronze,
    and iron in place of stones.
I will make peace(BK) your governor
    and well-being your ruler.(BL)
18 No longer will violence(BM) be heard in your land,
    nor ruin or destruction(BN) within your borders,
but you will call your walls Salvation(BO)
    and your gates Praise.(BP)
19 The sun will no more be your light by day,
    nor will the brightness of the moon shine on you,
for the Lord will be your everlasting light,(BQ)
    and your God will be your glory.(BR)
20 Your sun(BS) will never set again,
    and your moon will wane no more;
the Lord will be your everlasting light,
    and your days of sorrow(BT) will end.
21 Then all your people will be righteous(BU)
    and they will possess(BV) the land forever.
They are the shoot I have planted,(BW)
    the work of my hands,(BX)
    for the display of my splendor.(BY)
22 The least of you will become a thousand,
    the smallest a mighty nation.(BZ)
I am the Lord;
    in its time I will do this swiftly.”(CA)

Footnotes

  1. Isaiah 60:9 Or the trading ships