Add parallel Print Page Options

Ìgbàlà ayérayé fún Sioni

51 “Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ó ń lépa òdodo
    àti ẹ̀yin tí ń wá Olúwa:
Wo àpáta, nínú èyí tí a ti gé yín jáde
    àti ihò òkúta níbi tí a ti gbẹ́ yín jáde;
ẹ wo Abrahamu baba yín,
    àti Sara, ẹni tó bí i yín.
Nígbà tí mo pè é, òun nìkan ni,
    Èmi sì bùkún un, mo sì ṣọ́ ọ di ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Dájúdájú, Olúwa yóò tu Sioni nínú
    yóò sì bojú àánú wo gbogbo ahoro rẹ̀;
Òun yóò sọ gbogbo aṣálẹ̀ rẹ̀ di Edeni,
    àti aṣálẹ̀ rẹ̀ yóò rí bí ọgbà Olúwa.
Ayọ̀ àti inú dídùn ni a ó rí nínú rẹ̀,
    ọpẹ́ àti ariwo orín kíkọ.

“Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ènìyàn mi;
    gbọ́ tèmi, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè mi:
Òfin yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde wá;
    ìdájọ́ mi yóò di ìmọ́lẹ̀ sí àwọn orílẹ̀-èdè.
Òdodo mi ń bọ̀ wá kíkankíkan,
    ìgbàlà mi ń bọ̀ lójú ọ̀nà,
àti apá mi yóò sì mú ìdájọ́ wá
    sí àwọn orílẹ̀-èdè.
Àwọn erékùṣù yóò wò mí
    wọn yóò sì dúró ní ìrètí fún apá mi.
(A)Gbé ojú rẹ sókè sí àwọn ọ̀run,
    wo ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀;
Àwọn ọ̀run yóò pòórá bí èéfín,
    ilẹ̀ yóò sì gbó bí ẹ̀wù
àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò kú gẹ́gẹ́ bí àwọn eṣinṣin.
    Ṣùgbọ́n ìgbàlà mi yóò wà títí láé,
    òdodo mi kì yóò yẹ̀ láé.

“Ẹ gbọ́ mi, ẹ̀yin tí ó mọ ohun òtítọ́,
    ẹ̀yin ènìyàn tí ó ní òfin mi ní àyà yín:
Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹ̀gàn àwọn ènìyàn
    tàbí kí ẹ̀rù èébú wọn já a yín láyà.
Nítorí kòkòrò yóò mú wọn lá bí aṣọ;
    Ìdin yóò sì mú wọn jẹ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Ṣùgbọ́n òdodo mi yóò wà títí ayérayé,
    àti ìgbàlà mi láti ìrandíran.”

Dìde, dìde! Kí o sì wọ ara rẹ ní agbára
    Ìwọ apá Olúwa;
dìde gẹ́gẹ́ bí i ti ọjọ́ ìgbà n nì,
    àti gẹ́gẹ́ bí i ti ìran àtijọ́.
Ìwọ kọ́ lo ké Rahabu sí wẹ́wẹ́
    tí o sì fa ẹ̀mí búburú ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ?
10 Ìwọ kọ́ ni ó gbẹ omi Òkun bí
    àti àwọn omi inú ọ̀gbun,
Tí o sì ṣe ọ̀nà nínú ìsàlẹ̀ Òkun
    tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹni ìràpadà yóò fi le là á kọjá?
11 Àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá.
    Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin kíkọ;
ayọ̀ ayérayé ni yóò sì bo orí wọn.
    Ayọ̀ àti inú dídùn yóò sì bà lé wọn
    ìbànújẹ́ àti ìtìjú yóò sì sá kúrò.

12 “Èmi, àní Èmi, èmi ni ẹni tí ó tù ọ́ nínú.
    Ta ni ọ́ tí o fi ń bẹ̀rù ènìyàn ẹlẹ́ran ara,
    àti ọmọ ènìyàn, tí ó jẹ́ koríko lásán,
13 tí ìwọ sì gbàgbé Olúwa ẹlẹ́dàá rẹ,
    ẹni tí ó ta àwọn ọ̀run
tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀,
    tí ẹ sì ń gbé nínú ìpayà lójoojúmọ́
nítorí ìbínú àwọn aninilára,
    tí wọ́n sì gbẹ́kẹ̀lé ìpanirun?
    Nítorí ibo ni ìbínú àwọn aninilára gbé wà?
14 Àwọn ẹlẹ́wọ̀n tí ń ṣojo la ó dá sílẹ̀ ní àìpẹ́ jọjọ
    wọn kò ní kú sínú túbú wọn,
    bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ṣe aláìní àkàrà.
15 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,
    tí ó ń ru Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí
ìgbì rẹ̀ fi ń pariwo
    Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
16 Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ẹnu rẹ
    mo sì ti fi òjìji ọwọ́ mi bò ọ́
Èmi tí mo tẹ́ àwọn ọ̀run sí ààyè rẹ̀,
    ẹni tí ó fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé lélẹ̀,
àti ẹni tí ó sọ fún Sioni pé,
    ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi.’ ”

Ago ìbínú Olúwa

17 Jí, jí!
    Gbéra nílẹ̀ ìwọ Jerusalẹmu,
ìwọ tí o ti mu láti ọwọ́ Olúwa
    ago ìbínú rẹ̀,
ìwọ tí o ti fà á mu dé gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀
    tí ó n mú kí ènìyàn ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
18 Nínú gbogbo ọmọ tí ó bí
    kò sí ọ̀kankan tí ó lè tọ́ ọ ṣọ́nà
nínú gbogbo ọmọ tí ó tọ́
    kò sí èyí tí ó le fà á lọ́wọ́.
19 Àjálù ìlọ́po ìlọ́po yìí ti dé bá ọ—
    ta ni yóò tù ọ́ nínú?
Ìparun àti ìdahoro, ìyàn àti idà
    ta ni yó pẹ̀tù sí ọ lọ́kàn?
20 Àwọn ọmọkùnrin rẹ ti dákú;
    wọ́n sùn sí oríta gbogbo òpópónà,
gẹ́gẹ́ bí etu tí a dé mọ́nú àwọ̀n.
    Ìbínú Olúwa ti kún inú wọn fọ́fọ́
    àti ìbáwí Ọlọ́run yín.

21 Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́,
    tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì
22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè yín wí nìyìí,
    Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn rẹ̀ mọ́,
“Kíyèsi i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ rẹ
    ago tí ó mú ọ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n;
láti inú ago náà, ẹ̀kún ìbínú mi,
    ni ìwọ kì yóò mu mọ́.
23 Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nilójú rẹ lọ́wọ́,
    àwọn tí ó wí fún ọ pé,
‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lórí rẹ.’
    Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀
    gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lórí i rẹ̀.”

Everlasting Salvation for Zion

51 “Listen(A) to me, you who pursue righteousness(B)
    and who seek(C) the Lord:
Look to the rock(D) from which you were cut
    and to the quarry from which you were hewn;
look to Abraham,(E) your father,
    and to Sarah, who gave you birth.
When I called him he was only one man,
    and I blessed him and made him many.(F)
The Lord will surely comfort(G) Zion(H)
    and will look with compassion on all her ruins;(I)
he will make her deserts like Eden,(J)
    her wastelands(K) like the garden of the Lord.
Joy and gladness(L) will be found in her,
    thanksgiving(M) and the sound of singing.

“Listen to me, my people;(N)
    hear me,(O) my nation:
Instruction(P) will go out from me;
    my justice(Q) will become a light to the nations.(R)
My righteousness draws near speedily,
    my salvation(S) is on the way,(T)
    and my arm(U) will bring justice to the nations.
The islands(V) will look to me
    and wait in hope(W) for my arm.
Lift up your eyes to the heavens,
    look at the earth beneath;
the heavens will vanish like smoke,(X)
    the earth will wear out like a garment(Y)
    and its inhabitants die like flies.
But my salvation(Z) will last forever,(AA)
    my righteousness will never fail.(AB)

“Hear me, you who know what is right,(AC)
    you people who have taken my instruction to heart:(AD)
Do not fear the reproach of mere mortals
    or be terrified by their insults.(AE)
For the moth will eat them up like a garment;(AF)
    the worm(AG) will devour them like wool.
But my righteousness will last forever,(AH)
    my salvation through all generations.”

Awake, awake,(AI) arm(AJ) of the Lord,
    clothe yourself with strength!(AK)
Awake, as in days gone by,
    as in generations of old.(AL)
Was it not you who cut Rahab(AM) to pieces,
    who pierced that monster(AN) through?
10 Was it not you who dried up the sea,(AO)
    the waters of the great deep,(AP)
who made a road in the depths of the sea(AQ)
    so that the redeemed(AR) might cross over?
11 Those the Lord has rescued(AS) will return.
    They will enter Zion with singing;(AT)
    everlasting joy will crown their heads.
Gladness and joy(AU) will overtake them,
    and sorrow and sighing will flee away.(AV)

12 “I, even I, am he who comforts(AW) you.
    Who are you that you fear(AX) mere mortals,(AY)
    human beings who are but grass,(AZ)
13 that you forget(BA) the Lord your Maker,(BB)
    who stretches out the heavens(BC)
    and who lays the foundations of the earth,
that you live in constant terror(BD) every day
    because of the wrath of the oppressor,
    who is bent on destruction?
For where is the wrath of the oppressor?(BE)
14     The cowering prisoners will soon be set free;(BF)
they will not die in their dungeon,
    nor will they lack bread.(BG)
15 For I am the Lord your God,
    who stirs up the sea(BH) so that its waves roar(BI)
    the Lord Almighty(BJ) is his name.
16 I have put my words in your mouth(BK)
    and covered you with the shadow of my hand(BL)
I who set the heavens in place,
    who laid the foundations of the earth,(BM)
    and who say to Zion, ‘You are my people.(BN)’”

The Cup of the Lord’s Wrath

17 Awake, awake!(BO)
    Rise up, Jerusalem,
you who have drunk from the hand of the Lord
    the cup(BP) of his wrath,(BQ)
you who have drained to its dregs(BR)
    the goblet that makes people stagger.(BS)
18 Among all the children(BT) she bore
    there was none to guide her;(BU)
among all the children she reared
    there was none to take her by the hand.(BV)
19 These double calamities(BW) have come upon you—
    who can comfort you?(BX)
ruin and destruction,(BY) famine(BZ) and sword(CA)
    who can[a] console you?
20 Your children have fainted;
    they lie at every street corner,(CB)
    like antelope caught in a net.(CC)
They are filled with the wrath(CD) of the Lord,
    with the rebuke(CE) of your God.

21 Therefore hear this, you afflicted(CF) one,
    made drunk,(CG) but not with wine.
22 This is what your Sovereign Lord says,
    your God, who defends(CH) his people:
“See, I have taken out of your hand
    the cup(CI) that made you stagger;
from that cup, the goblet of my wrath,
    you will never drink again.
23 I will put it into the hands of your tormentors,(CJ)
    who said to you,
    ‘Fall prostrate(CK) that we may walk(CL) on you.’
And you made your back like the ground,
    like a street to be walked on.”(CM)

Footnotes

  1. Isaiah 51:19 Dead Sea Scrolls, Septuagint, Vulgate and Syriac; Masoretic Text / how can I