Add parallel Print Page Options

Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli àti ìgbọ́ràn ìránṣẹ́

50 Ohun tí Olúwa wí nìyìí:

“Níbo ni ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ ìyá rẹ wà
èyí tí mo fi lé e lọ?
    Tàbí èwo nínú àwọn olùyánilówó mi
ni mo tà ọ́ fún?
    Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni a fi tà ọ́;
    nítorí àìṣedéédéé rẹ ni a fi lé ìyá rẹ lọ.
Nígbà tí mo wá, èéṣe tí a kò fi rí ẹnìkan?
    Nígbà tí mo pè, èéṣe tí kò fi sí ẹnìkan láti dáhùn?
Ọwọ́ mi a kúrú láti gbà ọ́?
    Èmi kò ha ní agbára láti gbà ọ́ bí?
Nípa ìbáwí lásán, Èmi gbẹ omi Òkun,
    Èmi yí àwọn odò sí aṣálẹ̀;
àwọn ẹja wọn rà fún àìsí omi
    wọ́n sì kú fún òǹgbẹ.
Èmi fi òkùnkùn bo sánmọ̀
    mo sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ ṣe ìbòrí rẹ̀.”

Olúwa Olódùmarè ti fún mi ni ahọ́n tí a fi iṣẹ́ rán,
    láti mọ àwọn ọ̀rọ̀ tí ó lè gbé àwọn aláàárẹ̀ ró.
O jí mi láràárọ̀,
    o jí etí mi láti gbọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹni tí à ń kọ́.
Olúwa Olódùmarè ti ṣí mi ní etí,
    bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ṣọ̀tẹ̀ rí;
    Èmi kò sì padà sẹ́yìn.
Mo ṣí ẹ̀yìn mi sílẹ̀ fún àwọn tí ó ń nà mí,
    àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ mi fún àwọn tí ń fa irùngbọ̀n mi;
Èmi kò fi ojú mi pamọ́
    kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́yà àti ìyọṣùtì sí.
Nítorí Olúwa Olódùmarè ràn mí lọ́wọ́;
    A kì yóò dójútì mí.
Nítorí náà ni mo ṣe gbé ojú mi ró bí òkúta akọ
    èmi sì mọ pé, ojú kò ní tì mí.
Ẹni tí ó dá mi láre wà nítòsí.
    Ta ni ẹni náà tí yóò fẹ̀sùn kàn mí?
Jẹ́ kí a kojú ara wa!
    Ta ni olùfisùn mi?
    Jẹ́ kí ó kò mí lójú!
Olúwa Olódùmarè ni ó ń ràn mí lọ́wọ́.
    Ta ni ẹni náà tí yóò dá mi lẹ́bi?
Gbogbo wọn yóò gbó bí aṣọ;
    kòkòrò ni yóò sì jẹ wọn run.

10 Ta ni nínú yín tí ó bẹ̀rù Olúwa
    tí ó sì ń gbọ́rọ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lẹ́nu?
Jẹ́ kí ẹni tí ń rìn ní òkùnkùn
    tí kò ní ìmọ́lẹ̀,
kí ó gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa
    kí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.
11 Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gbogbo ẹ̀yin ti ń tanná
    tí ẹ sì ń fi pèsè iná ìléwọ́ fún ara yín,
ẹ lọ, kí ẹ sì máa rìn nínú ìmọ́lẹ̀ iná yín,
    àti nínú ẹta iná tí ẹ ti dá.
Èyí ni yóò jẹ́ tiyín láti ọwọ́ mi wá:
    Ẹ̀yin ó dùbúlẹ̀ nínú ìrora.

Israel’s Sin and the Servant’s Obedience

50 This is what the Lord says:

“Where is your mother’s certificate of divorce(A)
    with which I sent her away?
Or to which of my creditors
    did I sell(B) you?
Because of your sins(C) you were sold;(D)
    because of your transgressions your mother was sent away.
When I came, why was there no one?
    When I called, why was there no one to answer?(E)
Was my arm too short(F) to deliver you?
    Do I lack the strength(G) to rescue you?
By a mere rebuke(H) I dry up the sea,(I)
    I turn rivers into a desert;(J)
their fish rot for lack of water
    and die of thirst.
I clothe the heavens with darkness(K)
    and make sackcloth(L) its covering.”

The Sovereign Lord(M) has given me a well-instructed tongue,(N)
    to know the word that sustains the weary.(O)
He wakens me morning by morning,(P)
    wakens my ear to listen like one being instructed.(Q)
The Sovereign Lord(R) has opened my ears;(S)
    I have not been rebellious,(T)
    I have not turned away.
I offered my back to those who beat(U) me,
    my cheeks to those who pulled out my beard;(V)
I did not hide my face
    from mocking and spitting.(W)
Because the Sovereign Lord(X) helps(Y) me,
    I will not be disgraced.
Therefore have I set my face like flint,(Z)
    and I know I will not be put to shame.(AA)
He who vindicates(AB) me is near.(AC)
    Who then will bring charges against me?(AD)
    Let us face each other!(AE)
Who is my accuser?
    Let him confront me!
It is the Sovereign Lord(AF) who helps(AG) me.
    Who will condemn(AH) me?
They will all wear out like a garment;
    the moths(AI) will eat them up.

10 Who among you fears(AJ) the Lord
    and obeys(AK) the word of his servant?(AL)
Let the one who walks in the dark,
    who has no light,(AM)
trust(AN) in the name of the Lord
    and rely on their God.
11 But now, all you who light fires
    and provide yourselves with flaming torches,(AO)
go, walk in the light of your fires(AP)
    and of the torches you have set ablaze.
This is what you shall receive from my hand:(AQ)
    You will lie down in torment.(AR)