Add parallel Print Page Options

Ìdájọ́ Ọlọ́run lòdì sí àwọn orílẹ̀-èdè

34 (A)Súnmọ́ tòsí,
    ẹ̀yin orílẹ̀-èdè láti gbọ́,
tẹ́tí sílẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn
    jẹ́ kí ayé gbọ́,
àti ẹ̀kún rẹ̀,
    ayé àti ohun gbogbo tí ó ti inú rẹ̀ jáde.
Nítorí ìbínú Olúwa ń bẹ
    lára gbogbo orílẹ̀-èdè,
àti ìrunú rẹ̀ lórí gbogbo ogun wọn:
    o ti fi wọ́n fún pípa,
Àwọn ti a pa nínú wọn
    ni a ó sì jù sóde,
òórùn wọn yóò ti inú òkú wọn jáde,
    àwọn òkè ńlá yóò sì yọ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ wọn
(B)Gbogbo àwọn ogun ọ̀run ni yóò di yíyọ́,
    a ó sì ká àwọn ọ̀run jọ bí i tákàdá,
gbogbo ogun wọn yóò si ṣubú lulẹ̀,
    bí ewé ti n bọ́ kúrò lára àjàrà,
    àti bí i bíbọ́ èso lára igi ọ̀pọ̀tọ́.

Nítorí ti a rẹ idà mi ní ọ̀run,
    kíyèsi í, yóò sọ̀kalẹ̀ wá sórí Edomu,
    sórí àwọn ènìyàn tí mo ti parun fún ìdájọ́.
Idà Olúwa kún fún ẹ̀jẹ̀
    a mú un sanra fún ọ̀rá,
àti fún ẹ̀jẹ̀ ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́,
    fún ọ̀rá ìwé àgbò—
nítorí Olúwa ni ìrúbọ kan ní Bosra,
    àti ìpakúpa ńlá kan ní ilẹ̀ Edomu.
Àti àwọn àgbáǹréré yóò
    ba wọn sọ̀kalẹ̀ wá,
àti àwọn ẹgbọrọ màlúù
    pẹ̀lú àwọn akọ màlúù,
ilé wọn ni a ó fi ẹ̀jẹ̀ rin,
    a ó sì fi ọ̀rá sọ ekuru wọn di ọlọ́ràá.

Nítorí ọjọ́ ẹ̀san Olúwa ni,
    àti ọdún ìsanpadà,
    nítorí ọ̀ràn Sioni.
(C)Odò rẹ̀ ni a ó sì sọ di ọ̀dà,
    àti eruku rẹ̀ di imí-ọjọ́,
    ilẹ̀ rẹ̀ yóò sì di ọ̀dà tí ń jóná.
10 A kì yóò pa á ní òru tàbí ní ọ̀sán,
    èéfín rẹ̀ yóò gòkè láéláé:
yóò dahoro láti ìran dé ìran,
    kò sí ẹnìkan tí yóò là á kọjá láé
àti láéláé.
11 Òwìwí aginjù, àti àkàlà ni yóò ni ín,
    àti òwìwí àti ẹyẹ ìwò ni yóò máa gbé inú rẹ̀.
Ọlọ́run yóò sì na sórí Edomu
    okùn ìwọ̀n ìparun
    àti òkúta òfo.
12 Ní ti àwọn ìjòyè rẹ̀
    ẹnìkan kì yóò sí níbẹ̀
tiwọn ó pè wá sí ìjọba,
    gbogbo àwọn olórí i rẹ̀ yóò sì di asán.
13 Ẹ̀gún yóò sì hù jáde
    nínú àwọn ààfin rẹ̀ wọ̀nyí,
ẹ̀gún ọ̀gán nínú ìlú olódi rẹ̀.
    Yóò jẹ́ ibùgbé àwọn akátá
    àti àgbàlá fún àwọn òwìwí.
14 Àwọn ẹranko ijù àti àwọn ìkookò ni yóò pàdé,
àti ewúrẹ́ igbó kan yóò máa kọ sí èkejì rẹ̀,
    iwin yóò máa gbé ibẹ̀ pẹ̀lú,
    yóò sì rí ibi ìsinmi fún ara rẹ̀.
15 Òwìwí yóò tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ síbẹ̀,
    yóò yé, yóò sì pa,
yóò sì kójọ lábẹ́ òjìji rẹ̀:
    àwọn gúnnugún yóò péjọ síbẹ̀ pẹ̀lú,
    olúkúlùkù pẹ̀lú ẹnìkejì rẹ̀.

16 Ẹ wá a nínú ìwé Olúwa, ẹ sì kà á:

Ọ̀kan nínú ìwọ̀nyí kì yóò yẹ̀,
    kò sí ọ̀kan tí yóò fẹ́ èkejì rẹ̀ kù:
nítorí Olúwa ti pàṣẹ
    ẹnu rẹ̀ ló sì fi kó wọn jọ
    Ẹ̀mí rẹ̀ ló sì fi tò wọ́n jọ.
17 Ó ti di ìbò fún wọn,
    ọwọ́ rẹ̀ sì ti pín in fún wọn
nípa títa okùn,
    wọn ó jogún rẹ̀ láéláé,
láti ìran dé ìran
    ni wọn ó máa gbé inú rẹ̀.

Judgment Against the Nations

34 Come near, you nations, and listen;(A)
    pay attention, you peoples!(B)
Let the earth(C) hear, and all that is in it,
    the world, and all that comes out of it!(D)
The Lord is angry with all nations;
    his wrath(E) is on all their armies.
He will totally destroy[a](F) them,
    he will give them over to slaughter.(G)
Their slain(H) will be thrown out,
    their dead bodies(I) will stink;(J)
    the mountains will be soaked with their blood.(K)
All the stars in the sky will be dissolved(L)
    and the heavens rolled up(M) like a scroll;
all the starry host will fall(N)
    like withered(O) leaves from the vine,
    like shriveled figs from the fig tree.

My sword(P) has drunk its fill in the heavens;
    see, it descends in judgment on Edom,(Q)
    the people I have totally destroyed.(R)
The sword(S) of the Lord is bathed in blood,
    it is covered with fat—
the blood of lambs and goats,
    fat from the kidneys of rams.
For the Lord has a sacrifice(T) in Bozrah(U)
    and a great slaughter(V) in the land of Edom.
And the wild oxen(W) will fall with them,
    the bull calves and the great bulls.(X)
Their land will be drenched with blood,(Y)
    and the dust will be soaked with fat.

For the Lord has a day(Z) of vengeance,(AA)
    a year of retribution,(AB) to uphold Zion’s cause.
Edom’s streams will be turned into pitch,
    her dust into burning sulfur;(AC)
    her land will become blazing pitch!
10 It will not be quenched(AD) night or day;
    its smoke will rise forever.(AE)
From generation to generation(AF) it will lie desolate;(AG)
    no one will ever pass through it again.
11 The desert owl[b](AH) and screech owl[c] will possess it;
    the great owl[d] and the raven(AI) will nest there.
God will stretch out over Edom(AJ)
    the measuring line of chaos(AK)
    and the plumb line(AL) of desolation.
12 Her nobles will have nothing there to be called a kingdom,
    all her princes(AM) will vanish(AN) away.
13 Thorns(AO) will overrun her citadels,
    nettles and brambles her strongholds.(AP)
She will become a haunt for jackals,(AQ)
    a home for owls.(AR)
14 Desert creatures(AS) will meet with hyenas,(AT)
    and wild goats will bleat to each other;
there the night creatures(AU) will also lie down
    and find for themselves places of rest.
15 The owl will nest there and lay eggs,
    she will hatch them, and care for her young
    under the shadow of her wings;(AV)
there also the falcons(AW) will gather,
    each with its mate.

16 Look in the scroll(AX) of the Lord and read:

None of these will be missing,(AY)
    not one will lack her mate.
For it is his mouth(AZ) that has given the order,(BA)
    and his Spirit will gather them together.
17 He allots their portions;(BB)
    his hand distributes them by measure.
They will possess it forever
    and dwell there from generation to generation.(BC)

Footnotes

  1. Isaiah 34:2 The Hebrew term refers to the irrevocable giving over of things or persons to the Lord, often by totally destroying them; also in verse 5.
  2. Isaiah 34:11 The precise identification of these birds is uncertain.
  3. Isaiah 34:11 The precise identification of these birds is uncertain.
  4. Isaiah 34:11 The precise identification of these birds is uncertain.