Add parallel Print Page Options

Ìpọ́njú àti ìrànlọ́wọ́

33 Ègbé ni fún ọ, ìwọ apanirun,
    ìwọ tí a kò tí ì parun!
Ègbé ni fún ọ, ìwọ ọ̀dàlẹ̀,
    ìwọ tí a kò tí ì dà ọ́!
Nígbà tí o bá dẹ́kun à ń pa ni run;
    a ó pa ìwọ náà run,
nígbà tí o bá dẹ́kun à ń dani,
    a ó da ìwọ náà.

Olúwa ṣàánú fún wa
    àwa ń ṣàfẹ́rí i rẹ.
Máa jẹ́ agbára wa ní òròòwúrọ̀
    ìgbàlà wa ní àsìkò ìpọ́njú.
Ní ìkérara ohùn rẹ, àwọn ènìyàn sá,
    nígbà tí o dìde sókè, àwọn orílẹ̀-èdè fọ́nká.
Ìkógun rẹ, ìwọ orílẹ̀-èdè ni a kórè
    gẹ́gẹ́ bí i ti ọ̀dọ́ eṣú;
    gẹ́gẹ́ bí àkójọpọ̀ eṣú, àwọn ènìyàn wọ ibẹ̀.

A gbé Olúwa ga, nítorí pé ó ń gbé ibi gíga;
    Òun yóò kún Sioni pẹ̀lú ẹ̀tọ́ àti òdodo.
Òun yóò jẹ́ ìpìlẹ̀ tí ó dájú fún àkókò rẹ
    ibùjókòó ìgbàlà kíkún àti ọgbọ́n òun ìmọ̀;
    ìbẹ̀rù Olúwa ni kọ́kọ́rọ́ sí ìṣúra yìí.

Wò ó, àwọn onígboyà ọkùnrin wọn pohùnréré
    ẹkún ní òpópónà;
    àwọn ikọ̀ àlàáfíà sọkún kíkorò.
Àwọn ojú ọ̀nà ńlá ni a ṣá tì,
    kò sí arìnrìn-àjò kankan ní ojú ọ̀nà
A ti ba àdéhùn jẹ́,
    a kẹ́gàn àwọn ẹlẹ́rìí,
    a kò bu ọlá fún ẹnikẹ́ni.
Ilẹ̀ ṣọ̀fọ̀ ó sì ṣòfò dànù,
    ojú ti Lebanoni ó sì sá
Ṣaroni sì dàbí aginjù,
    àti Baṣani òun Karmeli rẹ àwọn èwe wọn.

10 “Ní ìsinsin yìí ni èmi yóò dìde,” ni Olúwa wí.
    “Ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi ga,
    ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi sókè.
11 Ìwọ lóyún ìyàngbò,
    o sì bí koríko;
    èémí yín bí iná tí yóò jẹ yín run.
12 A ó jó àwọn ènìyàn run bí eérú;
    bí igbó ẹ̀gún tí a gé la ó dáná sí wọn.”

13 Ìwọ tí ó wà lọ́nà jíjìn, gbọ́ ohun
    tí mo ti ṣe;
    Ìwọ tí ò ń bẹ nítòsí, jẹ́rìí agbára mi!
14 Ẹ̀rù ba àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ní Sioni;
    ìwárìrì bá àwọn tí kò gba Ọlọ́run gbọ́:
“Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná ajónirun?
    Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná àìnípẹ̀kun?”
15 Ẹni tí ó ń rìn lódodo
    tí ó ń sọ ohun tí ó tọ́,
tí ó kọ èrè tí ó ti ibi ìlọ́nilọ́wọ́gbà wá,
    tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀,
tí ó di etí rẹ̀ sí ọ̀tẹ̀ láti pànìyàn
    tí ó sì di ojú rẹ̀ sí à ti pète ibi
16 Òun náà yóò gbé ní ibi gíga,
    ibi ààbò rẹ̀ yóò jẹ́ òkè ńlá olódi.
A ó mú oúnjẹ fún un,
    omi rẹ̀ yóò sì dájú.

17 Ojú rẹ yóò rí ọba nínú ẹwà rẹ̀
    yóò sì rí ilẹ̀ kan tí ó tẹ́ lọ rẹrẹẹrẹ.
18 Nínú èrò rẹ ìwọ yóò rántí ẹ̀rù rẹ àtẹ̀yìnwá:
    “Níbo ni ọ̀gá àgbà náà wà?
Níbo ni ẹni tí ń gba owó òde wà?
    Níbo ni òṣìṣẹ́ ti ó ń mójútó ilé ìṣọ́ wà?”
19 Ìwọ kì yóò rí àwọn agbéraga ènìyàn mọ́,
    àwọn ènìyàn tí èdè wọn fi ara sin,
    pẹ̀lú ahọ́n tí ó ṣàjèjì tí kò sì yé ni.

20 Gbójú sókè sí Sioni, ìlú àjọ̀dún wa,
    ojú rẹ yóò rí Jerusalẹmu,
ibùgbé àlàáfíà n nì, àgọ́ tí a kò ní yí padà;
    àwọn òpó rẹ̀ ni a kì yóò fàtu
    tàbí èyíkéyìí nínú okùn rẹ̀ kí já.
21 Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti jẹ́ Alágbára kan fún wa.
    Yóò sì dàbí ibi àwọn odò ńláńlá àti odò kéékèèkéé.
Kì yóò sí ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú tí yóò kọjá lórí i wọn,
    ọkọ̀ ojú omi ńlá ni a kì yóò tù lórí wọn.
22 Nítorí Olúwa ni onídàájọ́ wa,
    Olúwa ni onídàájọ́ wa,
Olúwa òun ni ọba wa;
    òun ni ẹni tí yóò gbà wá là.

23 Gbogbo okùn rẹ ni ó ti dẹ̀:
    Ìgbókùnró kò fìdímúlẹ̀,
wọn kò taṣọ agbọ́kọ̀rìn,
    lẹ́yìn náà, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkógun ni a ó pín
    àní arọ pẹ̀lú yóò ru ìkógun lọ.
24 Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó ń gbé Sioni tí yóò wí pé, “Ara mi kò yá,”
    a ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ jì wọ́n.

Distress and Help

33 Woe(A) to you, destroyer,
    you who have not been destroyed!
Woe to you, betrayer,
    you who have not been betrayed!
When you stop destroying,
    you will be destroyed;(B)
when you stop betraying,
    you will be betrayed.(C)

Lord, be gracious(D) to us;
    we long for you.
Be our strength(E) every morning,
    our salvation(F) in time of distress.(G)
At the uproar of your army,(H) the peoples flee;(I)
    when you rise up,(J) the nations scatter.
Your plunder,(K) O nations, is harvested(L) as by young locusts;(M)
    like a swarm of locusts people pounce on it.

The Lord is exalted,(N) for he dwells on high;(O)
    he will fill Zion with his justice(P) and righteousness.(Q)
He will be the sure foundation for your times,
    a rich store of salvation(R) and wisdom and knowledge;
    the fear(S) of the Lord is the key to this treasure.[a](T)

Look, their brave men(U) cry aloud in the streets;
    the envoys(V) of peace weep bitterly.
The highways are deserted,
    no travelers(W) are on the roads.(X)
The treaty is broken,(Y)
    its witnesses[b] are despised,
    no one is respected.
The land dries up(Z) and wastes away,
    Lebanon(AA) is ashamed and withers;(AB)
Sharon(AC) is like the Arabah,
    and Bashan(AD) and Carmel(AE) drop their leaves.

10 “Now will I arise,(AF)” says the Lord.
    “Now will I be exalted;(AG)
    now will I be lifted up.
11 You conceive(AH) chaff,
    you give birth(AI) to straw;
    your breath is a fire(AJ) that consumes you.
12 The peoples will be burned to ashes;(AK)
    like cut thornbushes(AL) they will be set ablaze.(AM)

13 You who are far away,(AN) hear(AO) what I have done;
    you who are near, acknowledge my power!
14 The sinners(AP) in Zion are terrified;
    trembling(AQ) grips the godless:
“Who of us can dwell with the consuming fire?(AR)
    Who of us can dwell with everlasting burning?”
15 Those who walk righteously(AS)
    and speak what is right,(AT)
who reject gain from extortion(AU)
    and keep their hands from accepting bribes,(AV)
who stop their ears against plots of murder
    and shut their eyes(AW) against contemplating evil—
16 they are the ones who will dwell on the heights,(AX)
    whose refuge(AY) will be the mountain fortress.(AZ)
Their bread will be supplied,
    and water will not fail(BA) them.

17 Your eyes will see the king(BB) in his beauty(BC)
    and view a land that stretches afar.(BD)
18 In your thoughts you will ponder the former terror:(BE)
    “Where is that chief officer?
Where is the one who took the revenue?
    Where is the officer in charge of the towers?(BF)
19 You will see those arrogant people(BG) no more,
    people whose speech is obscure,
    whose language is strange and incomprehensible.(BH)

20 Look on Zion,(BI) the city of our festivals;
    your eyes will see Jerusalem,
    a peaceful abode,(BJ) a tent(BK) that will not be moved;(BL)
its stakes will never be pulled up,
    nor any of its ropes broken.
21 There the Lord will be our Mighty(BM) One.
    It will be like a place of broad rivers and streams.(BN)
No galley with oars will ride them,
    no mighty ship(BO) will sail them.
22 For the Lord is our judge,(BP)
    the Lord is our lawgiver,(BQ)
the Lord is our king;(BR)
    it is he who will save(BS) us.

23 Your rigging hangs loose:
    The mast is not held secure,
    the sail is not spread.
Then an abundance of spoils will be divided
    and even the lame(BT) will carry off plunder.(BU)
24 No one living in Zion will say, “I am ill”;(BV)
    and the sins of those who dwell there will be forgiven.(BW)

Footnotes

  1. Isaiah 33:6 Or is a treasure from him
  2. Isaiah 33:8 Dead Sea Scrolls; Masoretic Text / the cities