Add parallel Print Page Options

Ìpọ́njú àti ìrànlọ́wọ́

33 Ègbé ni fún ọ, ìwọ apanirun,
    ìwọ tí a kò tí ì parun!
Ègbé ni fún ọ, ìwọ ọ̀dàlẹ̀,
    ìwọ tí a kò tí ì dà ọ́!
Nígbà tí o bá dẹ́kun à ń pa ni run;
    a ó pa ìwọ náà run,
nígbà tí o bá dẹ́kun à ń dani,
    a ó da ìwọ náà.

Olúwa ṣàánú fún wa
    àwa ń ṣàfẹ́rí i rẹ.
Máa jẹ́ agbára wa ní òròòwúrọ̀
    ìgbàlà wa ní àsìkò ìpọ́njú.
Ní ìkérara ohùn rẹ, àwọn ènìyàn sá,
    nígbà tí o dìde sókè, àwọn orílẹ̀-èdè fọ́nká.
Ìkógun rẹ, ìwọ orílẹ̀-èdè ni a kórè
    gẹ́gẹ́ bí i ti ọ̀dọ́ eṣú;
    gẹ́gẹ́ bí àkójọpọ̀ eṣú, àwọn ènìyàn wọ ibẹ̀.

A gbé Olúwa ga, nítorí pé ó ń gbé ibi gíga;
    Òun yóò kún Sioni pẹ̀lú ẹ̀tọ́ àti òdodo.
Òun yóò jẹ́ ìpìlẹ̀ tí ó dájú fún àkókò rẹ
    ibùjókòó ìgbàlà kíkún àti ọgbọ́n òun ìmọ̀;
    ìbẹ̀rù Olúwa ni kọ́kọ́rọ́ sí ìṣúra yìí.

Wò ó, àwọn onígboyà ọkùnrin wọn pohùnréré
    ẹkún ní òpópónà;
    àwọn ikọ̀ àlàáfíà sọkún kíkorò.
Àwọn ojú ọ̀nà ńlá ni a ṣá tì,
    kò sí arìnrìn-àjò kankan ní ojú ọ̀nà
A ti ba àdéhùn jẹ́,
    a kẹ́gàn àwọn ẹlẹ́rìí,
    a kò bu ọlá fún ẹnikẹ́ni.
Ilẹ̀ ṣọ̀fọ̀ ó sì ṣòfò dànù,
    ojú ti Lebanoni ó sì sá
Ṣaroni sì dàbí aginjù,
    àti Baṣani òun Karmeli rẹ àwọn èwe wọn.

10 “Ní ìsinsin yìí ni èmi yóò dìde,” ni Olúwa wí.
    “Ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi ga,
    ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi sókè.
11 Ìwọ lóyún ìyàngbò,
    o sì bí koríko;
    èémí yín bí iná tí yóò jẹ yín run.
12 A ó jó àwọn ènìyàn run bí eérú;
    bí igbó ẹ̀gún tí a gé la ó dáná sí wọn.”

13 Ìwọ tí ó wà lọ́nà jíjìn, gbọ́ ohun
    tí mo ti ṣe;
    Ìwọ tí ò ń bẹ nítòsí, jẹ́rìí agbára mi!
14 Ẹ̀rù ba àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ní Sioni;
    ìwárìrì bá àwọn tí kò gba Ọlọ́run gbọ́:
“Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná ajónirun?
    Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná àìnípẹ̀kun?”
15 Ẹni tí ó ń rìn lódodo
    tí ó ń sọ ohun tí ó tọ́,
tí ó kọ èrè tí ó ti ibi ìlọ́nilọ́wọ́gbà wá,
    tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀,
tí ó di etí rẹ̀ sí ọ̀tẹ̀ láti pànìyàn
    tí ó sì di ojú rẹ̀ sí à ti pète ibi
16 Òun náà yóò gbé ní ibi gíga,
    ibi ààbò rẹ̀ yóò jẹ́ òkè ńlá olódi.
A ó mú oúnjẹ fún un,
    omi rẹ̀ yóò sì dájú.

17 Ojú rẹ yóò rí ọba nínú ẹwà rẹ̀
    yóò sì rí ilẹ̀ kan tí ó tẹ́ lọ rẹrẹẹrẹ.
18 Nínú èrò rẹ ìwọ yóò rántí ẹ̀rù rẹ àtẹ̀yìnwá:
    “Níbo ni ọ̀gá àgbà náà wà?
Níbo ni ẹni tí ń gba owó òde wà?
    Níbo ni òṣìṣẹ́ ti ó ń mójútó ilé ìṣọ́ wà?”
19 Ìwọ kì yóò rí àwọn agbéraga ènìyàn mọ́,
    àwọn ènìyàn tí èdè wọn fi ara sin,
    pẹ̀lú ahọ́n tí ó ṣàjèjì tí kò sì yé ni.

20 Gbójú sókè sí Sioni, ìlú àjọ̀dún wa,
    ojú rẹ yóò rí Jerusalẹmu,
ibùgbé àlàáfíà n nì, àgọ́ tí a kò ní yí padà;
    àwọn òpó rẹ̀ ni a kì yóò fàtu
    tàbí èyíkéyìí nínú okùn rẹ̀ kí já.
21 Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti jẹ́ Alágbára kan fún wa.
    Yóò sì dàbí ibi àwọn odò ńláńlá àti odò kéékèèkéé.
Kì yóò sí ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú tí yóò kọjá lórí i wọn,
    ọkọ̀ ojú omi ńlá ni a kì yóò tù lórí wọn.
22 Nítorí Olúwa ni onídàájọ́ wa,
    Olúwa ni onídàájọ́ wa,
Olúwa òun ni ọba wa;
    òun ni ẹni tí yóò gbà wá là.

23 Gbogbo okùn rẹ ni ó ti dẹ̀:
    Ìgbókùnró kò fìdímúlẹ̀,
wọn kò taṣọ agbọ́kọ̀rìn,
    lẹ́yìn náà, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkógun ni a ó pín
    àní arọ pẹ̀lú yóò ru ìkógun lọ.
24 Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó ń gbé Sioni tí yóò wí pé, “Ara mi kò yá,”
    a ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ jì wọ́n.

33 Woe to thee that spoilest, and thou wast not spoiled; and dealest treacherously, and they dealt not treacherously with thee! when thou shalt cease to spoil, thou shalt be spoiled; and when thou shalt make an end to deal treacherously, they shall deal treacherously with thee.

O Lord, be gracious unto us; we have waited for thee: be thou their arm every morning, our salvation also in the time of trouble.

At the noise of the tumult the people fled; at the lifting up of thyself the nations were scattered.

And your spoil shall be gathered like the gathering of the caterpiller: as the running to and fro of locusts shall he run upon them.

The Lord is exalted; for he dwelleth on high: he hath filled Zion with judgment and righteousness.

And wisdom and knowledge shall be the stability of thy times, and strength of salvation: the fear of the Lord is his treasure.

Behold, their valiant ones shall cry without: the ambassadors of peace shall weep bitterly.

The highways lie waste, the wayfaring man ceaseth: he hath broken the covenant, he hath despised the cities, he regardeth no man.

The earth mourneth and languisheth: Lebanon is ashamed and hewn down: Sharon is like a wilderness; and Bashan and Carmel shake off their fruits.

10 Now will I rise, saith the Lord; now will I be exalted; now will I lift up myself.

11 Ye shall conceive chaff, ye shall bring forth stubble: your breath, as fire, shall devour you.

12 And the people shall be as the burnings of lime: as thorns cut up shall they be burned in the fire.

13 Hear, ye that are far off, what I have done; and, ye that are near, acknowledge my might.

14 The sinners in Zion are afraid; fearfulness hath surprised the hypocrites. Who among us shall dwell with the devouring fire? who among us shall dwell with everlasting burnings?

15 He that walketh righteously, and speaketh uprightly; he that despiseth the gain of oppressions, that shaketh his hands from holding of bribes, that stoppeth his ears from hearing of blood, and shutteth his eyes from seeing evil;

16 He shall dwell on high: his place of defence shall be the munitions of rocks: bread shall be given him; his waters shall be sure.

17 Thine eyes shall see the king in his beauty: they shall behold the land that is very far off.

18 Thine heart shall meditate terror. Where is the scribe? where is the receiver? where is he that counted the towers?

19 Thou shalt not see a fierce people, a people of a deeper speech than thou canst perceive; of a stammering tongue, that thou canst not understand.

20 Look upon Zion, the city of our solemnities: thine eyes shall see Jerusalem a quiet habitation, a tabernacle that shall not be taken down; not one of the stakes thereof shall ever be removed, neither shall any of the cords thereof be broken.

21 But there the glorious Lord will be unto us a place of broad rivers and streams; wherein shall go no galley with oars, neither shall gallant ship pass thereby.

22 For the Lord is our judge, the Lord is our lawgiver, the Lord is our king; he will save us.

23 Thy tacklings are loosed; they could not well strengthen their mast, they could not spread the sail: then is the prey of a great spoil divided; the lame take the prey.

24 And the inhabitant shall not say, I am sick: the people that dwell therein shall be forgiven their iniquity.